< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
Eka Nyasaye nowuoyo kowacho niya,
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
“An e Jehova Nyasaye ma Nyasachu mane ogolou e piny Misri, ka uwuok e piny mane unie wasumbini.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
“Kik ubed gi nyiseche mamoko e nyima.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Kik ulos nyasaye milamo maket gi kido moro amora e polo malo kata e piny mwalo, kata e bwo pi.
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
Kik ukulrunegi piny; bende kik ulamgi; nimar An, Jehova Nyasaye ma Nyasachu, An Nyasaye ma janyiego, kendo akumo nyithindo nikech richo mar wuonegi chakre tiengʼ mar adek nyaka tiengʼ mar angʼwen mar jogo mamon koda,
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
to anyiso hera ni tienge gana gi gana mar jogo mohera kendo morito chikena.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Kik uti gi nying Jehova Nyasaye ma Nyasachu e yo ma ok owinjore, nimar Jehova Nyasaye ok nongʼwon ne ngʼato angʼata matiyo gi nyinge e yo marach.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
Rituru chiengʼ Sabato kendo ukete obed maler.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
Tiuru kuom ndalo auchiel kendo uti tijeu duto,
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
to chiengʼ mar abiriyo en Sabato ne Jehova Nyasaye ma Nyasachu. Chiengʼno ok unutim tich moro amora, bed ni un kata yawuotu kata nyiu kata jotiju machwo kata jotiju mamon kata jambu kata jodak manie dieru.
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
Nimar kuom ndalo auchiel Jehova Nyasaye nochweyo polo gi piny, gi nembe kaachiel gi gik moko duto manie igi, to noyweyo chiengʼ mar abiriyo. Kuom mano Jehova Nyasaye nogwedho chiengʼ Sabato mi okete maler.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Luor wuonu gi minu mondo udagi amingʼa e piny ma Jehova Nyasaye ma Nyasachu miyou.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Kik ineki.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Kik iterri.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Kik ikwal.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Kik ihang wach ne wadu.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
Kik igomb od wadu. Kik igomb chi wadu kata jatije ma wuowi kata jatije ma nyako, kata rwadhe kata pundane kata gire moro amora.”
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
Kane oganda oneno mil polo gi mor polo kendo owinjo ywak turumbete mi gineno ka got otimo iro, luoro nomakogi. Negisudo gichien
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
mi giwachone Musa niya, “Wuo kodwa in iwuon to wabiro winjo. Kik iwe Nyasaye wuo kodwa nono to wabiro tho.”
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
Musa nowacho ne oganda niya, “Kik ubed maluor. Nyasaye osebiro mondo otemu mondo omi usik kuluore kendo mondo kik utim richo.”
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
Ogandano nochungʼ gichien ka Musa to ne ochomo bor polo kama Nyasaye ne nitie.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Nyis jo-Israel kama: ‘Useneno un uwegi ni asewuoyo kodu ka aa e polo.
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Kik ulos nyiseche manono mondo opiem koda; bende kik ulos nyiseche mag kido mag fedha kata dhahabu.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
“‘Losnauru kendo mar misango mochwe gi lowo kendo timieuru misenginiu miwangʼo pep kod mag lalruok gi rombeu gi dieu kod dhou. Kinde moro amora ma amiyo nyinga oyudo duongʼ, to anabi iru mi agwedhu.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
Ka ulosona kendo mar misango mar kite, to kik ugere gi kite mopa, nimar ubiro miyo kendono bedo mogak ka utiyoe gi gige payo kite.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Kendo kik udhi e kendona mar misango ka uwuotho e kuonde motingʼore ma iidhogo malo, dipo ka dugu onenorene.’

< Exodus 20 >