< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
Hae loknawk boih Sithaw mah thuih;
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
kai loe misong ah na ohhaih, Izip prae thung hoi nangcae zaehoikung, Angraeng Sithaw ah ka oh.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
Ka hmaa ah Sithaw kalah tawn hmah.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Van ranui ah kaom krang maw, to tih ai boeh loe long tlim ah kaom krang maw, to tih ai boeh loe tui thungah kaom hmuen hoi kanghmong, kawbaktih krang doeh sah hmah;
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
nihcae hmaa ah akuep o hmah loe, bok o hmah; na Angraeng Sithaw, Kai loe ut panoek Sithaw ah ka oh moe, kai hnuma ampanawk ih zaehaih pongah, a caanawk adung thumto hoi palito karoek to thuitaekkung ah ka oh.
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
Toe kai palung moe, ka thuih ih lok pazui kaminawk loe a caanawk ih adung sangto pong kapop adung khoek to amlunghaih patuekkung ah ka oh.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Avang ai ah na Angraeng Sithaw ih ahmin to patoh hmah; anih ih ahmin tidoeh na ai ah patoh rumram kami loe, Angraeng mah anih to khen sut mak ai.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
Sabbath ni to ciimsak hanah pakuem poe ah.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
Ni tarukto thung toksah ah, na tok to sah boih ah.
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
Toe ni sarihto naah loe, na Angraeng Sithaw ih Sabbath niah oh; to niah loe tih tok doeh sah hmah; nangmah doeh, na capa doeh, na canu doeh, na tamna nongpa doeh, na tamna nongpata doeh, na tawnh ih moinawk hoi na khongkha thungah kaom angvin doeh toksak o han om ai;
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
Angraeng mah ni tarukto thung van hoi long, tuipui hoi a thungah kaom hmuennawk boih to sak moe, ni sarihto naah loe anghak; to pongah Angraeng mah Sabbath ni to tahamhoihaih paek moe, ciimcaisak.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Nam no hoi nam pa khingya ah; to tih nahaeloe Angraeng Sithaw mah paek ih, prae thungah hinglung na sawk tih.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Kami hum hmah.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Zu sava laep ah nongpa nongpata zaehaih sah hmah.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Paqu hmah.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Na imtaeng kami nuiah amsawn hnukung ah angdoe hmah.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
Na imtaeng kami ih im to khit hmah; na imtaeng kami ih zu to khit hmah, to tih ai boeh loe anih ih tamna nongpa, to tih ai boeh loe anih ih tamna nongpata, anih ih maitaw doeh, anih ih laa hrang doeh, na imtaeng kami ih kawbaktih hmuen doeh khit hmah, tiah lok a paek.
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
Khopazih tuen, tangphrapuekhaih hoi mongkah lok to kaminawk mah thaih o, mae thung hoi tacawt hmaikhue to a hnuk o naah, angnawn o moe, kangthla ah angdoet o.
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
Mosi khaeah, Kaicae khae lok na thui ah, kang tahngaih pae o han; Sithaw mah kaicae khaeah lokthui hmah nasoe, ka dueh o moeng tih, tiah a naa o.
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
Mosi mah kaminawk khaeah, Zii o hmah; mikhmai ah anih zithaih na tawnh o moe, zaehaih na sak o han ai ah, nangcae tanoek han ih Sithaw angzoh tathuk boeh, tiah a naa.
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
Kaminawk loe kangthla ah angdoet o, toe Mosi loe Sithaw ohhaih kathah parai tamai kamnum ohhaih bangah a caeh.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
To naah Angraeng mah Mosi khaeah, Israel kaminawk khaeah, Kai mah van hoiah kang thuih ih lok to na hnuk o boeh, tiah thui paeh, tiah a naa.
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Kai nang bok o naah, nangmacae hanah sui sithaw doeh, sum kanglung sithaw doeh sah o hmah.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
Kai hanah long hoiah hmaicam mae to sah ah loe, to long hmaicam nuiah hmai angbawnhaih, angdaeh angbawnhaih to tuu hoi maitaw taenawk hoiah sah ah; kai ih ahmin pakoehhaih ahmuen kruekah, nang khaeah kang zoh moe, tahamhoihaih kang paek han.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
Kai hanah thlung hmaicam to na sak nahaeloe, thuk ih thlung kangphaek nuiah hmaicam to sah hmah; thlung kangphaek thukhaih sum to na phok tahang naah, hmaicam to nam hnongsak ah oh boeh.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Bangkrai ah na ohhaih amtueng han ai ah, hmaicam ranui ah dawhhaih thlak to sah hmah, tiah a naa.

< Exodus 20 >