< Exodus 2 >

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
І пішов один муж з дому Левія, і взяв собі за жінку дочку Левієву.
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
І завагітніла та жінка, та й сина вродила. І побачила його, що він гарний, та й ховала його три місяці.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
Та не могла його більше ховати. І взяла йому папірусову скриньку, і виасфальтувала її асфальтом та смолою, і положила до неї дитину, та й поклала в очереті на бе́резі Річки.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
А сестра його стояла здалека, щоб довідатися, що йому станеться.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
І зійшла фараонова дочка купатися на Річку, а служниці її ходили понад Річкою. І побачила вона ту скриньку серед очерету, — і послала невільницю свою, щоб узяла її.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
І відчинила, та й побачила дитину, — ось хлопчик плаче. І вона змилосе́рдилася над ним, та й сказала: „Це з єврейських дітей!“
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
І сказала сестра його до фараонової дочки: „Чи не піти й не покликати тобі жінку-мамку з єврейок, і вона годуватиме тобі дитину?“
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
І сказала їй дочка фараонова: „Іди“. І пішла та дівчина, і покликала матір дитини.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
А дочка фараонова сказала до неї: „На́ тобі цю дитину, та й годуй її для мене. А я дам тобі заплату“. І взяла та жінка дитину, і годувала її.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
І підросло те дитя, і вона привела його до фараонової дочки, — і він став їй за сина. І вона назвала йому ймення Мойсей, і сказала: „бо з води я витягла його“.
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
І сталося за тих днів, і підріс Мойсей. І вийшов він до братів своїх, та й приглядався до їхніх терпінь. І побачив він єги́птянина, що бив єврея з братів його.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
І озирнувся він туди та сюди, і побачив, що ніко́го нема, — та й убив єгиптянина, і заховав його в пісок.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
І вийшов він другого дня, — аж ось сва́ряться двоє євреїв. І сказав він несправедливому: „Нащо ти б'єш свого ближнього?“
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
А той відказав: „Хто тебе настановив за начальника та за суддю над нами? Чи ти думаєш убити мене, як ти вбив був єгиптянина?“І злякався Мойсей та й сказав собі: „Справді, та справа стала відо́ма!“
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
І почув фараон про цю справу, та й шукав, щоб убити Мойсея. І втік Мойсей від фараонового лиця, й оселився в країні Мідіян.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
А в мідіянського жерця було сім дочок. І прийшли вони, і витягали воду, і напо́внили корита, щоб напоїти ота́ру свого батька.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
І прийшли пастухи й відігнали їх. І встав Мойсей, та й оборонив їх, і напоїв їхню отару.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
І прибули́ вони до Реуїла, свого батька, а той поспитав: „Чого ви сьогодні так скоро прийшли?“
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
А ті відказали: „Якийсь єгиптянин оборонив нас від руки пастухів, а також навіть натягав нам води й напоїв отару“.
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
І сказав він до своїх дочок: „А де він? Чому ви покинули того чоловіка? Покличте його, і нехай він з'їсть хліба“.
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
І погодився Мойсей сидіти з тим чоловіком, а той видав за Мойсея дочку свою Ціппору.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
І породила вона сина, а він назвав ім'я йому: Ґершом, бо сказав: „Я став приходьком у чужому краї“.
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
І сталося по довгих днях, — і вмер цар Єгипту. А Ізраїлеві сини стогнали від тієї роботи та кричали. І їхній зойк через ту роботу донісся до Бога.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
І почув Бог їхній стогін. І згадав Бог Свого заповіта з Авраамом, Ісаком та Яковом.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
І Бог бачив синів Ізраїлевих, і Бог зглянувся над ними.

< Exodus 2 >