< Exodus 2 >

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Și un bărbat din casa lui Levi a mers și a luat de soție o fiică a lui Levi.
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
Și femeia a rămas însărcinată și a născut un fiu; și când ea l-a văzut că era frumos, l-a ascuns trei luni.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
Și când nu l-a mai putut ascunde, a luat pentru el o arcă din papură și a uns-o cu bitum și cu smoală și a pus copilul în ea; și a pus arca între trestiile de lângă malul râului.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Și sora lui a stat departe, pentru a vedea ce i se va face.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Și fiica lui Faraon a coborât să se spele la râu; și servitoarele ei umblau pe malul râului; și când a văzut arca printre trestii și-a trimis servitoarea să o aducă.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
Și când a deschis-o, a văzut copilul; și, iată, pruncul plângea. Iar ea a avut milă de el și a spus: Acesta este unul dintre copiii evreilor.
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Atunci sora lui a spus fiicei Faraonului: Să merg și să îți chem o doică dintre femeile evreice, ca să alăpteze copilul pentru tine?
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
Și fiica lui Faraon i-a spus: Du-te. Și fata a mers și a chemat pe mama copilului.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Și fiica lui Faraon i-a spus: Ia acest copil și alăptează-l pentru mine și îți voi da plățile tale. Și femeia a luat copilul și l-a alăptat.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
Și copilul a crescut și ea l-a adus la fiica lui Faraon și el a devenit fiul ei. Iar ea i-a pus numele Moise; și a spus: Pentru că l-am scos din apă.
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Și s-a întâmplat, în acele zile, când Moise era mare, că a ieșit la frații săi și a privit la poverile lor; și a văzut un egiptean lovind un evreu, pe unul dintre frații săi.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
Și s-a uitat încoace și încolo și când a văzut că nu era niciun bărbat, a ucis pe egiptean și l-a ascuns în nisip.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Și când a ieșit a doua zi, iată, doi bărbați dintre evrei se luptau între ei; și a spus celui ce a greșit: Pentru ce lovești pe aproapele tău?
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Iar el a spus: Cine te-a făcut prinț și judecător peste noi? Vrei să mă ucizi așa cum l-ai ucis pe egiptean? Și Moise s-a temut și a spus: Cu adevărat acest lucru este cunoscut.
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Și când Faraon a auzit acest lucru, a căutat să-l ucidă pe Moise. Dar Moise a fugit de la fața lui Faraon și a locuit în țara lui Madian; și a șezut jos lângă o fântână.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
Și preotul din Madian avea șapte fiice; și ele au venit și au scos apă și au umplut jgheaburile ca să adape turma tatălui lor.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Și păstorii au venit și le-au alungat; dar Moise s-a ridicat și le-a ajutat și le-a adăpat turma.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
Și când ele au venit la Reuel, tatăl lor, el a spus: Cum de ați venit așa devreme astăzi?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
Iar ele au spus: Un egiptean ne-a scăpat din mâna păstorilor și de asemenea a scos apă îndeajuns pentru noi și a adăpat turma.
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
Iar el a spus fiicelor sale: Și el, unde este? Pentru ce l-ați lăsat acolo pe bărbatul acela? Chemați-l, ca să mănânce pâine.
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Și Moise s-a mulțumit să locuiască la omul acela; iar el i-a dat lui Moise pe Sefora, fiica sa.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
Și ea i-a născut un fiu, iar el i-a pus numele Gherșom, pentru că a spus: Sunt străin într-o țară străină.
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Și s-a întâmplat, în decursul timpului, că împăratul Egiptului a murit; și copiii lui Israel oftau din cauza robiei și au strigat și strigătul lor a urcat sus la Dumnezeu din cauza robiei.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Și Dumnezeu a auzit geamătul lor și Dumnezeu și-a adus aminte de legământul său cu Avraam, cu Isaac și cu Iacob.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
Și Dumnezeu a privit peste copiii lui Israel și Dumnezeu a luat cunoștință de starea lor.

< Exodus 2 >