< Exodus 2 >
1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Ie amy zao, nañenga ty anak’ ampela’ i Levy t’indaty boak’ añ’ anjomba’ i Levy.
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
Niareñe i rakembay, nitoly ana-dahy, le nioni’e te soa i ajajamenay vaho naeta’e telo volañe.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
Aa ie tsy nahafañetak’ aze ka, le nangala’e vakoa-vinda naho nipakora’e mozòtse naho lite-laka vaho najo’e ao i anak’ ajajay vaho natsorofo’e am-binda añolon-drano ey.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Nijohañe ey ty zoke’e ampela nisamba ze hanoañe aze.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Nizotso mb’an-tsaka mb’eo amy zao ty anak’ ampela’ i Parò hiandro, le nijelanjelañe añ’olotse ey o somondrara’eo. Aa naho nitrea’e añate-vinda ao i vakoay le nirahe’e hangalak’ aze ty mpitoro’e ampela,
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
vaho sinoka’e le nahaisake i anak’ ajajay. Nitañy i ajajamenay vaho niferenaiña’e, ami’ty hoe: Toe anan-te-Evre toke.
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Le hoe i rahavave’ey amy ana’ i Paròy, Akore t’ie añitrifako mpampinono amo rakemba nte-Evreo hampinono i ajajay?
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
Akia, hoe i anak’ ampela’ i Paròy; aa le nimb’eo i ajajampelay nitoka ty rene’ i ajajay.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Hoe i ana’ i Paròy ama’e, Endeso ty ajaja toy le ampinonò ho ahiko vaho ho tambezeko irehe. Aa le nendese’ i rakembay i anak’ ajajay vaho nampinonoe’e.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
itombo i ajajay le nendese’e mb’amy anak’ampela’ i Paròy añe vaho rinambe’e ho ana-dahi’e. Natao’e Mosè ty añara’e amy ty hoe, Tinariko boak’an-drano.
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ie te indraik’ andro naho fa niañoñ’ ay t’i Mosè, le niakatse mb’ am’ ondati’eo nahaoniñe ty nijinia’iareo naho nioni’e ty nte-Mitsraime namofoke ty nte-Evre, raik’ amo longo’eo.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
Nijilojilo mb’ etia mb’ eroy, aa ie tsy nahatrea ondaty, le nañohofa’e loza i nte-Mitsraimey vaho naeta’e am-paseñe ao.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Ie niakatse mb’eo naho loak’ andro le nanjo ty nte-Evre roe nifandrapake ty aly, le hoe re ami’ty aman-kakeo, Ino ty andafà’o o longo’oo?
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Le hoe re. Ia ty nañoriñ’ azo ho mpifehe naho mpizaka anay? Hañe-doza amako ka hao irehe manahake i namonoa’o i nte-Mitsraimeiy? Nihembañ’ amy zao t’i Mosè nitsakore ty hoe, Toe nirendreke i rahay.
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Jinanji’ i Parò, le nipay ty hañe-doza amy Mosè. Le nibioñe ami’ty tarehe’ i Parò t’i Mosè, noly mb’an-tane Midiane añe vaho niambesatse am-bovoñe eo.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
Aman-anak’ ampela fito ty mpisoro’ i Midiane. Nimb’ eo iereo nitari-drano nañatsake o dabaogao hampinomeñe ty lia-rain-drae’e.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Pok’eo amy zao o mpiarak’ añondrio nanao soike iareo. Niongake t’i Mosè le rinomba’e le nampinome’e i lia-rai’iareoy.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
Ie nimpoly mb’an-drae’e Reoele mb’eo le hoe re, Ino ty nampasika ty fimpoli’ areo androany?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
Hoe iereo, Nañolots’ anay amo mpiarak’ añondrio ty nte-Mitsraime vaho nitariha’e rano mbore nampinome’e i lia-raikey.
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
Hoe re amo anak’ ampela’eo, Aia re? Ino ty nienga’ areo indatiy? Ambarao hikama.
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Niantofa’ i Mosè t’ie holy amy ‘ndatiy vaho natolo’e amy Mosè t’i Tsiporàe anak’ ampela’e ho vali’e.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
Nahatoly ana-dahy ho aze re vaho natao’e Geresòme, ami’ty hoe, Renetane iraho mañialo an-tanen’ ambahiny.
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Ie roñoñe añe, nihomake i mpanjaka’ i Mitsraimey naho nampiselekaiñe o ana’ Israeleo i fandrohizañey, le nirohadrohake vaho nionjoñe mb’ aman’ Añahare boak’ amy fitromahañey ty fitoreo’ iareo.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Jinanjin’ Añahare ty toreo’ iareo vaho nitiahin’ Añahare i fañìna’e amy Avrahame naho am’ Ietsàke vaho am’ Iakòbey.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
Nivazohon’ Añahare o ana’ Israeleo vaho nihaoñen’ Andrianañahare.