< Exodus 2 >

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Ke pacl se inge sie mukul ke sruf lal Levi el payukyak sin sie mutan in sruf sacna,
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
ac mutan sac el oswela tulik mukul se. Ke el liye lah tulik na wowo se, el okanulla malem tolu.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
Na ke el tia ku in sifil okanulla, el orala fotoh se ke ah, na el itangla ke mwe fulful in tia wohn. El filiya tulik sac loac ac usla filiya inmasrlon ah sisken infacl uh.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Tulik mutan se wien tulik sac el tu loes kutu lukel in liye lah mea ac sikyak nu sel.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Na acn se natul tokosra tufoki in yihyih ke infacl soko ah, ac mutan kulansap lal tuelik sisken infacl ah. Na el liyauk fotoh sac inmasrlon ac ah, ac el sap sie mutan kulansap lal in som use.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
Fisrak sac ikasla ac liyauk tulik mukul srisrik se. Tulik sac tung, na el pakomutal ac fahk, “Tulik srisrik Hebrew se pa nge.”
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Na tulik mutan se wien tulik sac siyuk, “Mea, nga ac tia som konauk sie mutan Hebrew ah in katiti tulik se inge?”
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
El topuk, “Wona.” Ouinge tulik mutan sac som solama nina na kien tulik sac.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Fisrak sac fahk nu sin nina sac, “Eis tulik se inge ac liyalang, ac nga fah moli nu sum.” Ouinge el us tulik sac ac liyalang.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
Tok, ke tulik sac matula, nina sac el usalla nu yurin acn natul tokosra, su nutella oana ma na natul. El fahk mu, “Nga fah sang inel ‘Moses’ mweyen nga ololak liki inkof uh.”
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ke Moses el matula, el som mutwata yurin mwet lal mwet Hebrew, ac el liye lupan orekma upa ma itukyang elos in oru. El liye pac ke sie mwet Egypt el uni sie mwet Hebrew wial ah.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
Moses el ngetot ngetma in suk lah oasr mwet liyal, na ke wangin, el uniya mwet Egypt sac ac pikinya manol in puk uh.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Len tok ah, el folokla ac liye ke sie mwet Hebrew uni sie pac. Na Moses el fahk nu sel, “Efu kom ku uni mwet Hebrew wiom?”
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Mwet sac topuk ac fahk, “Su oru tuh kom in mwet leum ac mwet nununku facsr? Mea, kom ac uniyuwi oana ke kom uniya mwet Egypt sac?” Ke Moses el akilen lah mwet uh etu tari ma se el orala, na el sangeng.
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Ke pacl se tokosra el lohngak, el suk in unilya Moses. Tusruktu Moses el kaingla ac som muta in acn Midian. Sie len ah, ke Moses el muta pe lufin kof se,
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
na acn itkosr natul Jethro, mwet tol lun Midian, tuku in ut kof ac oayapa nwek mwe nim kof nimen sheep ac nani nutin papa tumaltal ah.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Na oasr kutu mwet liyaung sheep ac nani tuku lusak acn natul Jethro ah. Moses el tuyak ac kasru acn ekasr ah, ac el sang kof nimen kosro nutin papa tumaltal ah.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
Ke elos folokla nu yurin papa sac, el siyuk selos, “Komtak ku sa folok misenge?”
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
Elos topuk, “Mwet Egypt se kasrekut ke kutu pac mwet liyaung sheep aklokoalokye kut, ac el oayapa ut kof lasr ac kiteya pac kosro natusr ah.”
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
El siyuk seltal, “El aya? Komtal ku tia usalu? Fahla solalma elan wi kut mongo.”
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Ouinge Moses el sulela elan mutana we. Na Jethro el esalang Zipporah, acn natul, in mutan kial.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
Zipporah el oswela wen se, ac Moses el fahk, “Nga mwetsac se nu fin facl se inge, ouinge nga fah sang inel Gershom.”
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Tukun yac pus, tokosra lun acn Egypt el misa, tusruktu mwet Israel srakna yohk akkohs nu selos, ac elos sasaolana ke orekma upa lalos. Elos wowoyak ac suk kasru sin God.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Ac God El lohng pusren sasao lalos ac El esam wuleang lal yorol Abraham, Isaac, ac Jacob.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
El liye ac etu ouiyen keok lun mwet Israel, ac El kena kasrelos.

< Exodus 2 >