< Exodus 2 >

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Ana knafina mago Livae nagapinti ne'mo'a, mago ara Livae nagapinti erigeno,
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
amu'ene huno ne' mofavre ksenteno, keana hiranto mofavre fore'ma higeno, 3'a ikamofo agu'afi frakino antegeno mani'ne.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
Hianagi ana mofavre'mo ra huno 3'a ikama higeno mago'ane frakintega'ma nosuno'a, ekaeka ku tro huno, kolta fukinuti renkanireteno, ana mofavrea ana ekaekapi anteteno erino Naeli tinkenafi me'nea uha trazampi ome frakino ante'ne.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Ana mofavremofo nesaro'a agrite'ma fore haniaza kenaku ogantu'a mani'ne.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Fero mofa'mo ti frenaku, eri'za mofa'nene Naeli tinte erami'za, ana tinkenare nevu'za ekaekara uha trazampi me'negeno negeno, eri'za mofa'a huntegeno omerino eme ami'ne.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
Ana mofa'mo'ma ekaekama erinagino keana, ana mofavremo'a zavitegeno, asuntagi nenteno anage hu'ne, Ama Hibru vahe'mokizmi mofavre.
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Anante ana mofavremofo nesaro'a, Fero mofara antahigeno, Knare vu'na mago Hibru ara ome avre'na anenkeno mofavrea kegava krigantegahifi?
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
Higeno Fero mofa'mo'a anage huno hu'ne, Vunka kema hanaza hunka ome avrenka eno huno huntegeno, ana mofa'mo'a vuno ana mofavremofo nerera ome avreno e'ne.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Fero mofa'mo'a amanage huno ana ara asmi'ne, Ama mofavrea avrenka ome kegava krinante'nege'na, miza segantaneno, higeno ana mofavrea avreno kegava krinte'ne.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
Ana mofavre'mo'ma rama higeno avreno Fero mofate vigeno, Fero mofa'mofo zage mofavre'aza higeno, timpinti avre fegu'a atre'noe nehuno Mosese'e huno agi'a antemi'ne.
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Hagi ana knafina Mosese'ma nena huteno, mago zupa vahe'amo'zama tusiza hu'za kazokzo eri'zama enerizarega nevuno keana, mago Hibru nera, Isipi ne'mo nehegeno ome negeno,
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
omege emegema hiana mago vahera omani'negeno keteno, ana Isipi nera ahe frino ksepampi asente'ne.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Anante knazupa Mosese'a nevuno keana tare Hibru ne'tremoke zanagra zanagra ha' nehakeno ome neznageno, hazenkema agafama hu'nea nera antahigeno, Na'a higenka negafuna nehane?
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Hianagi ana ne'mo'a ke'nona'a huno, Iza kvati'a maninenka refko hurantegahane huno kazeriotine? Kagra Isipi ne'ma ahe fri'nanaza hunka nahe frinaku nehano? Higeno Mosese'a koro nehuno antahintahima hiana, vahe'ma ahe fri'noa zana hago e'ama hige'za antahi'naze hu'ne.
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Fero'ma ana kema nentahino, Mosesena ahe frinaku hianagi, Mosese'a atreno freno Midiani kumatega umaninaku vu'ne. Vuno mago tinkerire umani'nege'za,
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
mago Midiani pristi ne'mo'a 7ni'a mofa'ne zmante'neanki'za, nezmafa sipisipine meme afu'tmimo'zama tima nesnagu tinkerire neazageno,
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
ruga'a sipisipi afu kva vahe'mo'za eme zmahenati trazageno, Mosese'a otino ana mofa'nea ome zamaza huno nezmafa sipisipi afutamine, meme afutamina ana tina afi zamige'za netageno,
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
ana mofa'nemo'za nezmafa Ruelinte (Jetro) uhanatizageno anage huno zmantahigene, nahigeta menina hantaka huta aze? hige'za,
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
ruga'a sipisipi kva vahe'mo'zama tahemanenatiza vahera, mago Isipi ne'mo taza huno zmahenenatino, sipisipiti'anena taza huno tina afizmi'ne.
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
Anante Rueli'a (Jetro) zmantahigeno, ina ana nera mani'ne? Nahigeta atreta e'naze? Ome kehinkeno kave emeneno, hige'za ome avre'za azageno,
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Mosese'a zmagranema manisigu mago arimpa higeno Rueli'a (Jetro) mago mofa'a, Zipora amigeno a' eri'ne.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
Zipora'a amu'ene huno ne' mofavre ksentegeno, Mosese'a rurega ne'mo'na kraga emani'nogu agi'a Gesomu'e hu'na ante'mue.
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Za'za kna evutegeno Isipi kini nera fri'ne. Hianagi Israeli vahe'mo'za tusi'a knazama eri'za kazokzo eri'za eneri'za, Anumzamofontega zavi krafa hu'naze. Ana zavi krafa zimimo'a Anumzamofo avure marerigeno,
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Anumzamo'a ana zavi krafazamia antahinezamino, Abrahane, Aisakine, Jekopunema huvempa huno huhagerafi'nea kegu agesa antahi'ne.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
Anumzamo'a Israeli vahera nezmageno, knazampima mani'nazazana keno antahino hu'ne.

< Exodus 2 >