< Exodus 2 >
1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Na rĩrĩ, mũndũ ũmwe wa nyũmba ya Lawi nĩahikirie mũtumia wa mũhĩrĩga wa Alawii,
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
nake akĩgĩa nda, agĩciara kahĩĩ. Rĩrĩa onire kaarĩ kaana gathaka-rĩ, agĩkahitha nyũmba mĩeri ĩtatũ.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
No rĩrĩa aaremirwo nĩgũkahitha rĩngĩ-rĩ, agĩgathondekera gĩkabũ gĩa ithanjĩ na agĩgĩthinga na rami. Agĩcooka agĩkomia kaana kau thĩinĩ wakĩo, agĩkahitha mathanjĩ-inĩ kũu hũgũrũrũ-inĩ cia Nili.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Mwarĩ wa nyina na kaana kau aarũgamaga haraaya nĩguo one ũndũ ũrĩa ũngĩgakora.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Na rĩrĩ, mwarĩ wa Firaũni agĩikũrũka Nili nĩguo agethambe, nacio ndungata ciake ciaceerangaga kũu hũgũrũrũ-inĩ cia rũũĩ rũu. Nake akĩona gĩkabũ kĩu kũu ithanjĩ-inĩ, na agĩtũma ngombo yake ya mũirĩtu ĩkĩgĩĩre.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
Agĩkunũra gĩkabũ kĩu na akĩona kaana kau. Agĩkaiguĩra tha tondũ nĩkarĩraga. Nake akiuga atĩrĩ, “Gaka nĩ kaana kamwe ga twana twa Ahibirania.”
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Nake mwarĩ wa nyina na kaana kau akĩũria mwarĩ wa Firaũni atĩrĩ, “Ngacarie mũtumia ũmwe Mũhibirania akũrerere kaana gaka?”
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
Nake agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ, thiĩ.” Nake mũirĩtu ũcio agĩthiĩ, akĩgĩĩra nyina wa kaana kau.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Mwarĩ wa Firaũni akĩmwĩra atĩrĩ, “Oya kaana gaka ũkanderere, nĩndĩrĩkũrĩhaga.” Nĩ ũndũ ũcio mũtumia ũcio akĩoya kaana kau agĩkarera.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
Rĩrĩa kaana kau gaakũrire-rĩ, agĩgatwarĩra mwarĩ wa Firaũni nako gagĩtuĩka ta mũriũ. Agĩgeeta Musa, akiuga atĩrĩ, “Nĩ tondũ ndakarutire maaĩ-inĩ.”
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Thuutha wa Musa gũtuĩka mũndũ mũgima-rĩ, mũthenya ũmwe nĩathiire gũceera harĩa andũ ao maarĩ, nake akĩmabaara makĩrutithio wĩra na hinya. Ningĩ akĩona Mũmisiri akĩhũũra Mũhibirania, ũmwe wa andũ ake mwene.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
Nake acũthĩrĩria mĩena yothe na ndone mũndũ-rĩ, akĩũraga Mũmisiri ũcio, na akĩmũthika mũthanga-inĩ.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Mũthenya ũyũ ũngĩ akiumagara na akĩona Ahibirania eerĩ makĩrũa. Akĩũria ũrĩa wogitanĩte atĩrĩ, “Ũraringa Mũhibirania wanyu nĩkĩ?”
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Nake mũndũ ũcio akĩmũũria atĩrĩ, “Nũũ wagũtuire mwathi na mũtuithania wa maciira maitũ? Anga nĩũreciiria kũnjũraga o ta ũrĩa ũrooragire Mũmisiri?” Nake Musa agĩĩtigĩra na agĩĩciiria atĩrĩ, “Ũrĩa ndĩrekire no nginya ũkorwo nĩũmenyekete.”
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Rĩrĩa Firaũni aiguire ũhoro ũcio, akĩgeria kũũragithia Musa, nowe Musa akĩũrĩra Firaũni agĩthiĩ gũtũũra Midiani, kũrĩa aikarire thĩ hakuhĩ na gĩthima.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
Na rĩrĩ, Jethero mũthĩnjĩri-ngai wa Midiani aarĩ na airĩtu ake mũgwanja, nao magĩũka gũtaha maaĩ na kũiyũria mĩharatĩ manyuithie rũũru rwa mbũri rwa ithe wao.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Arĩithi amwe nĩmookire na makĩingata airĩtu acio, no Musa agĩũkĩra, akĩmateithũra na akĩhe ũhiũ wao maaĩ.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
Rĩrĩa airĩtu acio maainũkire kũrĩ ithe wao Reueli-rĩ, akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũma mũcooke narua ũguo ũmũthĩ?”
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
Makĩmũcookeria atĩrĩ, “Mũmisiri ũmwe nĩatũteithũrire kũrĩ arĩithi; o na nĩwe ũtũtahĩire maaĩ na atũheera mbũri ciitũ maaĩ.”
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
Jethero akĩmooria atĩrĩ, “Na akĩrĩ kũ?” “Mũmũtigire nĩkĩ? Thiĩi mũmwĩte, oke arĩĩanĩre na ithuĩ.”
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Nake Musa agĩĩtĩkĩra gũikara kwa mũndũ ũcio, nake akĩmũhe mwarĩ wetagwo Zipora amũhikie.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
Zipora agĩciara kaana ga kahĩĩ, nake Musa agĩgeeta Gerishomu, tondũ oigire atĩrĩ, “Nduĩkĩte mũgeni bũrũri wene.”
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Thuutha wa ihinda iraaya-rĩ, mũthamaki wa bũrũri wa Misiri nĩakuire. Andũ a Isiraeli magĩcaaya nĩ ũndũ wa ũkombo, na makĩrĩrĩra Ngai; nakĩo kĩrĩro kĩao atĩ mateithio nĩ ũndũ wa ũkombo gĩgĩkinyĩra Ngai.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Nake Ngai akĩigua gũcaaya kwao nake akĩririkana kĩrĩkanĩro gĩake na Iburahĩmu, na Isaaka na Jakubu.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Ngai akĩona gũtangĩka kwa andũ a Isiraeli, nake akĩrũmbũiya ũhoro wao.