< Exodus 2 >
1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Niin eräs mies, joka oli Leevin sukua, meni ja nai leeviläisen neidon.
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
Ja vaimo tuli raskaaksi ja synnytti pojan. Ja kun hän näki, että se oli ihana lapsi, salasi hän sitä kolme kuukautta.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
Mutta kun hän ei voinut sitä enää salata, otti hän kaisla-arkun, siveli sen maapihkalla ja piellä, pani lapsen siihen ja laski sen kaislikkoon Niilivirran rantaan.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Ja lapsen sisar asettui taammaksi nähdäksensä, mitä hänelle tapahtuisi.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Silloin faraon tytär tuli alas peseytymään virrassa, ja hänen seuranaisensa kävelivät virran rannalla; ja kun hän näki arkun kaislikossa, lähetti hän palvelijattarensa ja otatti sen ylös.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
Ja kun hän avasi sen, näki hän lapsen; ja katso, siinä oli poikanen, joka itki. Niin hänen tuli sitä sääli, ja hän sanoi: "Tämä on hebrealaisten lapsia".
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Niin lapsen sisar sanoi faraon tyttärelle: "Menenkö kutsumaan sinulle hebrealaisen imettäjän, joka voi imettää sen lapsen sinulle?"
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
Faraon tytär vastasi hänelle: "Mene!" Niin tyttö meni ja kutsui lapsen äidin.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Ja faraon tytär sanoi hänelle: "Ota tämä lapsi ja imetä se minulle, niin minä maksan sinulle siitä palkan". Ja vaimo otti lapsen ja imetti sen.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
Mutta kun lapsi oli kasvanut, toi hän sen faraon tyttärelle, ja tämä otti sen pojaksensa ja antoi hänelle nimen Mooses, sillä hän sanoi: "Minä olen vetänyt hänet ylös vedestä".
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ja tapahtui niihin aikoihin, kun Mooses oli kasvanut suureksi, että hän meni veljiensä luo ja näki heidän raskaan työnsä. Ja hän näki egyptiläisen miehen lyövän hebrealaista miestä, erästä hänen veljistään.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
Silloin hän katseli ympärillensä joka taholle, ja kun hän näki, ettei ketään ollut läheisyydessä, löi hän egyptiläisen kuoliaaksi ja kätki hänet hiekkaan.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Ja hän meni toisena päivänä ulos ja näki kaksi hebrealaista miestä tappelemassa keskenään; ja hän sanoi syylliselle: "Miksi lyöt toveriasi?"
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Tämä vastasi: "Kuka on asettanut sinut meidän päämieheksemme ja tuomariksemme? Aiotko tappaa minutkin, niinkuin tapoit egyptiläisen?" Silloin Mooses peljästyi ja ajatteli: "Se on siis tullut ilmi".
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Ja kun farao sai kuulla tästä tapahtumasta, etsi hän Moosesta tappaaksensa hänet. Mutta Mooses lähti faraota pakoon ja pysähtyi Midianin maahan ja istahti eräälle kaivolle.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
Ja Midianin papilla oli seitsemän tytärtä; nämä tulivat vettä ammentamaan ja täyttivät vesikaukalot, juottaakseen isänsä lampaita.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Mutta paimenet tulivat ja ajoivat heidät pois. Silloin Mooses nousi ja auttoi heitä ja juotti heidän lampaansa.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
Ja kun he tulivat isänsä Reguelin luo, kysyi hän: "Kuinka te tänä päivänä niin pian jouduitte?"
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
He vastasivat: "Egyptiläinen mies auttoi meitä paimenten käsistä, ammensipa vielä vettäkin meille ja juotti lampaat".
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
Ja hän sanoi tyttärillensä: "Missä hän on? Miksi te niin jätitte miehen? Kutsukaa hänet aterioimaan meidän kanssamme."
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Ja Mooses suostui asumaan sen miehen luona, ja hän antoi Moosekselle tyttärensä Sipporan vaimoksi.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
Tämä synnytti pojan, ja Mooses antoi hänelle nimen Geersom; sillä hän sanoi: "Minä olen muukalainen vieraalla maalla".
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Ja kun oli kulunut pitkä aika, kuoli Egyptin kuningas. Ja israelilaiset huokailivat orjuuttansa ja valittivat; ja heidän huutonsa heidän orjuutensa tähden nousi Jumalan tykö.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Ja Jumala kuuli heidän vaikeroimisensa, ja Jumala muisti liittonsa Aabrahamin, Iisakin ja Jaakobin kanssa.
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
Ja Jumala katsoi israelilaisten puoleen, ja Jumala piti heistä huolta.