< Exodus 2 >

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Aftir these thingis a man of `the hows of Leuy yede out, and took a wijf of his kyn,
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
which conseyuede, and childide a sone. And sche seiy hym wel farynge, and hidde him bi thre monethis.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
And whanne sche myyte not hele, thanne sche took a `leep of segge, and bawmede it with tar and pitch, and puttide the yong child with ynne, and puttide hym forth in a `place of spier of the brenke of the flood,
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
the while his sistir stood afer, and bihelde the bifalling of the thing.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Lo! forsothe the douytir of Farao cam doun to be waischun in the flood, and hir damysels walkiden bi the brenke of the flood. And whanne sche hadde seyn a leep in the `place of spier, sche sente oon of hir seruauntessis,
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
and sche openyde the leep brouyt to hir, and seiy a litil child wepynge ther ynne. And sche hadde mercy on the child, and seide, It is of the yonge children of Ebrews.
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
To whom the `sister of the child seide, Wolt thou that Y go, and clepe to thee an Ebrew womman, that may nurische the yong child?
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
She answeride, Go thou. The damysel yede, and clepide the `modir of the child.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
To whom `the douytir of Farao spak, and seide, Take thou this child, and nurische to me; Y schal yyue to thee thi mede. The womman took, and nurischide the child, and bitook hym woxun to `the douytir of Farao,
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
whom sche purchaside `in to the place of sone; and sche clepide his name Moises, and seide, For Y took hym fro the watir.
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
In tho daies, aftir that Moises encreesside, he yede out to hise britheren, and seiy the turment of hem, and a man Egipcian smytynge `oon of Ebrews, hise britheren.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
And whanne he hadde biholdun hidur and thidir, and hadde seyn, that no man was present, he killide the Egipcian, and hidde in soond.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
And he yede out in another dai, and seiy tweyne Ebrews chidynge, and he seide to hym that dide wrong, Whi smytist thou thi brother?
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Which answeride, Who ordeynede thee prince, ether iuge on vs? Whether thou wolt sle me, as thou killidist yisterdai the Egipcian? Moises dredde, and seide, Hou is this word maad opun?
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
And Farao herde this word, and souyte to sle Moyses, which fledde fro his siyt, and dwellide in the lond of Madian, and sat bisidis a pit.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
Forsothe seuene douytris weren to the preest of Madian, that camen to drawe watir; and whanne the trouyis weren fillid, thei coueitiden to watere `the flockis of her fadir.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Scheepherdis camen aboue, and dreuen hem awei; and Moises roos, and defendide the dameselis; and he watride `the scheep of hem.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
And whanne thei hadden turned ayen to Jetro, her fadir, he seide to hem, Whi camen ye swiftliere than ye weren wont?
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
Thei answeriden, A man of Egipt delyuerede vs fro the hond of scheepherdis; ferthermore and he drow watir with vs, and yaf drynk to the scheep.
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
And he seide, Where is that man? whi leften ye the man? clepe ye hym, that he ete breed.
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Therfor Moises swoor, that he wolde dwelle with Jetro; and he took a wijf, Sefora, `the douyter of Jetro.
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
And sche childide a sone to hym, whom he clepide Gersan, and seide, Y was a comelyng in an alyen lond. Forsothe sche childide an othir sone, whom he clepide Eliezer, and seide, For God of my fadir is myn helpere, and delyuerede me fro the hond of Farao.
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Forsothe aftir myche tyme the kyng of Egipt diede, and the sones of Israel inwardli weiliden for werkis, and crieden, and the cry of hem for werkis stiede to God.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
And he herde the weilyng of hem, and he hadde mynde of the boond of pees, which he hadde maad with Abraham, Ysaac, and Jacob; and he bihelde the sones of Israel,
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
and knewe hem.

< Exodus 2 >