< Exodus 2 >

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
Og en Mand af Levis Hus gik hen og tog en Levi Datter til Ægte,
2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
og Kvinden blev frugtsommelig og fødte en Søn. Da hun så, at det var en dejlig Dreng, skjulte hun ham i tre Måneder;
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
og da hun ikke længer kunde holde ham skjult, tog hun en Kiste af Papyrusrør, tættede den med Jordbeg og Tjære, lagde drengen i den og satte den hen mellem Sivene ved Nilens Bred.
4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
Og hans Søster stillede sig noget derfra for at se, hvad der vilde ske med ham.
5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
Da kom Faraos Datter ned til Nilen for at bade, og imedens gik hendes Jomfruer ved Flodens Bred. Så fik hun Øje på Kisten mellem Sivene og sendte sin Pige hen for at hente den.
6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
Og da hun åbnede den, så hun Barnet, og se, det var et Drengebarn, der græd. Da ynkedes hun over det og sagde: "Det må være et af Hebræernes Drengebørn!"
7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
Hans Søster sagde nu til Faraos Datter: "Skal jeg gå hen og hente dig en Amme blandt Hebræerkvinderne til at amme Barnet for dig?"
8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
Faraos Datter svarede hende: "Ja, gør det!" Så gik Pigen hen og hentede Barnets Moder.
9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
Og Faraos Datter sagde til hende: "Tag dette Barn med dig og am ham for mig, jeg skal nok give dig din Løn derfor!" Og Kvinden tog Barnet og ammede ham.
10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
Men da Drengen var blevet stor, bragte hun ham til Faraos Datter, og denne antog ham som sin Søn og gav ham Navnet Moses; "thi," sagde hun, "jeg har trukket ham op af Vandet."
11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
På den Tid gik Moses, som imidlertid var blevet voksen, ud til sine Landsmænd og så på deres Trællearbejde. Og han så en Ægypter slå en Hebræer, en af hans Landsmænd, ihjel.
12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
Da så han sig om til alle Sider, og efter at have forvisset sig om, at der ingen var i Nærheden, slog han Ægypteren ihjel og gravede ham ned i Sandet.
13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
Da han den næste Dag igen gik derud, så han to Hebræere i Slagsmål med hinanden. Da sagde han til ham, der havde Uret: "Hvorfor slår du din Landsmand?"
14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
Han svarede: "Hvem har sat dig til Herre og Dommer over os? Vil du måske slå mig ihjel, ligesom du slog Ægypteren ihjel?" Og Moses blev bange og tænkte: "Så er det dog blevet bekendt!"
15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
Da Farao fik Nys derom, søgte han at komme Moses til Livs, men Moses flygtede for Farao og tyede til Midjans Land, og der satte han sig ved en Brønd.
16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
Præsten i Midjan havde syv Døtre; de kom nu hen og øste Vand og fyldte Trugene for at vande deres Faders Småkvæg.
17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
Da kom Hyrderne og vilde jage dem bort, men Moses stod op og hjalp dem og vandede deres Småkvæg.
18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
Da de nu kom hjem til deres Fader Reuel, sagde han: "Hvorfor kommer I så tidligt hjem i Dag?"
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
De svarede: "Der var en Ægypter, som hjalp os over for Hyrderne, ja han øste også Vand for os og vandede Småkvæget."
20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
Da sagde han til sine Døtre: "Hvor er han da? Hvorfor har I ladet Manden blive derude? Byd ham ind, at han kan få noget at spise!"
21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
Så bestemte Moses sig til at tage Ophold hos Manden, og han gav Moses sin Datter Zippora til Ægte,
22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
og hun fødte en Søn, som han kaldte Gersom; "thi," sagde han, "jeg er blevet Gæst i et fremmed Land."
23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
Således gik der lang Tid hen, og imidlertid døde Ægypterkongen. Men Israeliterne stønnede og klagede under deres Trældom, og deres Skrig over Trældommen nåede op til Gud.
24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
Da hørte Gud deres Jamren, og Gud ihukom sin Pagt med Abraham, Isak og Jakob,
25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.
og Gud så til Israeliterne, og Gud kendtes ved dem.

< Exodus 2 >