< Exodus 19 >
1 Ní oṣù kẹta tí àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, ni ọjọ́ náà gan an ni wọ́n dé aginjù Sinai.
Israillar Misir zeminidin qiⱪip, dǝl üqinqi eyining baxlanƣan küni Sinay qɵligǝ yetip kǝldi.
2 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n gbéra kúrò ní Refidimu, wọ́n wọ ijù Sinai, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀, níbẹ̀ ni Israẹli sì dó sí ní iwájú òkè ńlá.
Ular Rǝfidimdin qiⱪip, Sinay qɵligǝ yetip kelip, qɵldǝ qedir tikti; Israil xu yǝrdǝ, taƣning udulida tohtap qedir tikti.
3 Mose sì gòkè tọ Ọlọ́run lọ. Olúwa sì ké pè é láti orí òkè náà wá pé, “Èyí ni ìwọ yóò sọ fún ilé Jakọbu àti ohun tí ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Israẹli:
Musa Hudaning aldiƣa qiⱪiwidi, Pǝrwǝrdigar taƣdin uningƣa hitab ⱪilip mundaⱪ dedi: — Sǝn Yaⱪupning jǝmǝtigǝ sɵz ⱪilip, Israillarƣa munu hǝwǝrni yǝtküzgin: —
4 ‘Ẹ̀yin ti rí ohun tí mo ti ṣe sí àwọn ará Ejibiti, àti bí mo ti gbé e yín ní apá ìyẹ́ idì.
«Mening misirliⱪlarƣa nemǝ ⱪilƣinimni, xundaⱪla Mǝn silǝrni huddi bürküt balilirini ⱪanatliriƣa mindürüp elip yürgǝndǝk, Ɵz ⱪeximƣa elip kǝlginimni ɵzünglar kɵrdünglar.
5 Nísinsin yìí, bí ẹ̀yin bá ṣe ìgbọ́ràn sí mi dé ojú àmì, tí ẹ sì pa májẹ̀mú mi mọ́, nígbà náà ni ẹ̀yin ó jẹ́ ìṣúra fún mi ju gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù lọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ayé ni tèmi.
Əmdi silǝr dǝrⱨǝⱪiⱪǝt Mening sɵzümni anglap, ǝⱨdǝmni tutsanglar, undaⱪta barliⱪ ǝllǝrning arisida Manga has bir gɵⱨǝr bolisilǝr — qünki pütkül yǝr Meningkidur —
6 Ẹ̀yin yóò sì máa jẹ́ ilẹ̀ ọba àwọn àlùfáà fún mi, orílẹ̀-èdè mímọ́.’ Ìwọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ ti ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Israẹli.”
wǝ silǝr Manga kaⱨinlardin tǝrkib tapⱪan has bir padixaⱨliⱪ wǝ muⱪǝddǝs bir ⱪowm bolisilǝr». Mana bu sǝn Israillarƣa deyixing kerǝk bolƣan sɵzlǝrdur, — dedi.
7 Mose sì tọ àwọn ènìyàn wá, ó sí pe àwọn àgbàgbà láàrín àwọn ènìyàn jọ. Ó sì gbé gbogbo ọ̀rọ̀ ti Olúwa pàṣẹ fún un láti sọ ní iwájú wọn.
Xuning bilǝn Musa yenip kelip, hǝlⱪning aⱪsaⱪallirini qaⱪirtip, Pǝrwǝrdigar uningƣa buyruƣan xu sɵzlǝrning ⱨǝmmisini ularƣa yǝtküzdi.
8 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì pa ohùn wọn pọ̀ wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa yóò ṣe ohun gbogbo ti Olúwa wí.” Mose sì mú ìdáhùn wọn padà tọ Olúwa lọ.
Hǝlⱪning ⱨǝmmisi bir eƣizdin: — Pǝrwǝrdigar buyruƣanning ⱨǝmmisigǝ qoⱪum ǝmǝl ⱪilimiz! — dǝp jawab bǝrdi. Andin Musa hǝlⱪning jawab sɵzlirini Pǝrwǝrdigarning ⱪexiƣa berip yǝtküzdi.
9 Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò tọ̀ ọ́ wá nínú ìkùùkuu ṣíṣú dudu, kí àwọn ènìyàn lè gbọ́ ohùn mi nígbà ti mo bá ń bá ọ sọ̀rọ̀, kí wọn kí ó lè máa gbà ọ́ gbọ́.” Nígbà náà ni Mose sọ ohun tí àwọn ènìyàn wí fún Olúwa.
Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Mana, Mǝn sanga sɵz ⱪilƣinimda hǝlⱪ awazimni anglisun, ⱨǝmixǝ sanga ixǝnsun dǝp, yeningƣa ⱪara bulutning ⱪarangƣuluⱪi iqidǝ kelimǝn, dǝp eytti. Musamu hǝlⱪning degǝnlirini Pǝrwǝrdigarƣa anglatti.
10 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Tọ àwọn ènìyàn lọ kí o sì yà wọ́n sí mímọ́ ni òní àti ni ọ̀la. Jẹ́ kí wọn kí ó fọ aṣọ wọn.
Pǝrwǝrdigar Musaƣa yǝnǝ: — Sǝn hǝlⱪning ⱪexiƣa berip, bügün wǝ ǝtǝ ularni pak-muⱪǝddǝs ⱪilip, kiyim-keqǝklirini yudurƣin.
11 Kí wọn kí ó sì múra di ọjọ́ kẹta, nítorí ni ọjọ́ náà ni Olúwa yóò sọ̀kalẹ̀ sí orí òkè Sinai ni ojú gbogbo àwọn ènìyàn.
Ular üqinqi künigǝ tǝyyar tursun; qünki üqinqi küni barliⱪ hǝlⱪning kɵz aldida Pǝrwǝrdigar Sinay teƣiƣa qüxidu.
12 Kí ìwọ kí ó ṣe ààlà fún àwọn ènìyàn, kí ìwọ kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ kíyèsí ara yín, kí ẹ má ṣe gun orí òkè lọ, kí ẹ má tilẹ̀ fi ọwọ́ ba etí rẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkè náà, ó dájú, pípa ni a ó pa á.
Sǝn hǝlⱪ üqün [taƣning] ǝtrapiƣa bir pasil ⱪilip, ularƣa: «Silǝr eⱨtiyat ⱪilinglar, taƣⱪa qiⱪmanglar yaki uning etikigǝ tegip kǝtmǝnglar. Kimki taƣⱪa tǝgsǝ ɵltürülmǝy ⱪalmaydu;
13 A ó sọ ọ́ ní òkúta tàbí kí a ta á ní ọfà, ọwọ́kọ́wọ́ kò gbọdọ̀ kàn án. Ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko, òun kì yóò wà láààyè.’ Nígbà ti ìpè bá dún nìkan ni kí wọn ó gun òkè wá.”
Uningƣa ⱨǝtta birǝr ⱪoli tegip kǝtsimu, qalma-kesǝk ⱪilip ɵltürülsun yaki oⱪ etip ɵltürülsun. Mǝyli ⱨaywan yaki insan bolsun, xundaⱪ ⱪilsa, tirik ⱪaldurulmisun» — dǝp eytⱪin. Lekin Kanay uzun qelinsa, ular taƣning tüwigǝ qiⱪsun, dedi.
14 Mose sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn, ó yà wọ́n sí mímọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn.
Musa taƣdin qüxüp hǝlⱪning ⱪexiƣa berip, hǝlⱪni Hudaƣa atap muⱪǝddǝs ⱪildi; ular kiyim-keqǝklirini yudi.
15 Ó sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ múra sílẹ̀ di ọjọ́ kẹta; ẹ má ṣe bá aya yín lòpọ̀.”
Andin Musa hǝlⱪⱪǝ: — Üqinqi künigǝ tǝyyar turunglar; ⱨeqkim ayali bilǝn yeⱪinqiliⱪ ⱪilmisun, dedi.
16 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kẹta, àrá àti mọ̀nàmọ́ná sì wà pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó ṣú dudu ní orí òkè, ìpè ńlá sì dún kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn tí ó wà ni ibùdó wárìrì.
Üqinqi küni bolƣanda, tang yoruxi bilǝn xundaⱪ boldiki, güldürmamilar güldürlǝp, qaⱪmaⱪ qeⱪip, taƣ üstidǝ ⱪoyuⱪ bir parqǝ bulut pǝyda boldi, zor ⱪattiⱪ qelinƣan kanayning awazi anglandi. Buni kɵrüp qedirgaⱨdiki pütkül hǝlⱪ ⱪorⱪunqidin titrǝp kǝtti.
17 Mose sì kó àwọn ènìyàn tí ó jáde láti ibùdó wá pàdé Ọlọ́run, wọ́n dúró nítòsí òkè.
Musa hǝlⱪni Hudaning aldida ⱨazir boluxⱪa qedirgaⱨdin elip qiⱪti. Ular kelip taƣning tüwidǝ ɵrǝ turdi.
18 Èéfín sì bo òkè Sinai nítorí Olúwa sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ nínú iná. Èéfín náà sì ń ru sókè bí èéfín iná ìléru, gbogbo òkè náà sì mì tìtì.
Pǝrwǝrdigar Sinay teƣiƣa otta qüxüp kǝlgini üqün is-tütǝk pütkül taƣni ⱪaplidi; is-tütǝk humdandin ɵrligǝn is-tütǝktǝk üstigǝ ɵrlǝp qiⱪti. Pütkül taƣ ⱪattiⱪ tǝwrinixkǝ baxlidi.
19 Ohùn ìpè sì ń rinlẹ̀ dòdò. Mose sọ̀rọ̀, Ọlọ́run sì fi àrá dá a lóhùn.
Kanay awazi barƣanseri küqiyip intayin ⱪattiⱪ qiⱪti. Musa sɵz ⱪiliwidi, Huda anglap ünlük awaz bilǝn jawab bǝrdi.
20 Olúwa sọ̀kalẹ̀ sí orí òkè Sinai, o sì pe Mose wá sí orí òkè náà. Mose sì gun orí òkè.
Pǝrwǝrdigar Ɵzi Sinay teƣiƣa, taƣning qoⱪⱪisiƣa qüxti; andin Pǝrwǝrdigar Musani taƣning qoⱪⱪisiƣa qaⱪiriwidi, Musa taƣⱪa qiⱪti.
21 Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀, kí ó sì kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn, kí wọn má ṣe fi tipátipá wá ọ̀nà láti wo Olúwa, bí wọn bá ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ wọn yóò ṣègbé.
Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Sǝn qüxüp halayiⱪni agaⱨlandurup: Ular «Pǝrwǝrdigarni kɵrimiz» dǝp pasildin bɵsüp ɵtmisun; undaⱪ ⱪilsa, ulardin kɵp adǝm ⱨalak bolidu, dǝp eytⱪin.
22 Kódà àwọn àlùfáà tí ó ń wá síwájú Olúwa gbọdọ̀ ya ara wọn sí mímọ́ bí bẹ́ẹ̀ kọ́. Olúwa yóò kọlù wọ́n.”
Pǝrwǝrdigarƣa yeⱪin kelǝlǝydiƣan kaⱨinlarmu ɵzlirini manga atap muⱪǝddǝs ⱪilsun; bolmisa, Pǝrwǝrdigar [sepilni] bɵskǝndǝk ularƣa ⱨalakǝt yǝtküzidu, — dedi.
23 Mose wí fún Olúwa pé, “Àwọn ènìyàn kì yóò lè wá sí orí òkè Sinai, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ti kìlọ̀ fún wa pé, ‘Ṣe ààlà yí òkè ká, kí o sì yà á sí mímọ́.’”
Musa Pǝrwǝrdigarƣa: — Halayiⱪning Sinay teƣiƣa qiⱪixi mumkin ǝmǝs; qünki Sǝn Ɵzüng bizgǝ ⱪattiⱪ agaⱨlandurdung: taƣni «muⱪǝddǝs» dǝp ⱪarap, uning ǝtrapiƣa pasillarni bekitinglar, dǝp ǝmr ⱪilding, — dedi.
24 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, mú Aaroni gòkè wá pẹ̀lú rẹ. Ṣùgbọ́n kí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn má ṣe fi tipátipá gòkè tọ Olúwa. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò kọlù wọ́n.”
Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Mang, sǝn qüxüp kǝtkin. Andin sǝn Ⱨarunni elip, billǝ qiⱪⱪin; lekin kaⱨinlar wǝ hǝlⱪ bolsa Pǝrwǝrdigarning ⱪexiƣa barayli dǝp pasildin bɵsüp ɵtmisun; bolmisa, [Pǝrwǝrdigar sepilni] bɵskǝndǝk ularning üstigǝ qüxidu, — dedi.
25 Mose sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ènìyàn lọ. Ó sì sọ ohun tí Olúwa wí fún wọn.
Xuning bilǝn Musa hǝlⱪning ⱪexiƣa qüxüp, ularƣa bu sɵzni yǝtküzdi.