< Exodus 19 >

1 Ní oṣù kẹta tí àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, ni ọjọ́ náà gan an ni wọ́n dé aginjù Sinai.
Israeli vahe'mo'zama Isipima atre'zama atiramiza e'nazana, 3 ikamofo ese knare ka'ma kokampi Sainai ehanati'naze.
2 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n gbéra kúrò ní Refidimu, wọ́n wọ ijù Sinai, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀, níbẹ̀ ni Israẹli sì dó sí ní iwájú òkè ńlá.
Zamagrama Refitimi kuma'ma netre'za Sainai ka'ma kokampi e'za Sainai agonamofo agafi seli nozamia emegi'naze.
3 Mose sì gòkè tọ Ọlọ́run lọ. Olúwa sì ké pè é láti orí òkè náà wá pé, “Èyí ni ìwọ yóò sọ fún ilé Jakọbu àti ohun tí ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Israẹli:
Hagi Mosese'a Anumzamofo ome kenaku agonafi mrerigeno, Ra Anumzamo'a agonafinti anage huno hu'ne, Menina amanage hunka Jekopu nagamofona Israeli vahe'mokizmia zamasamio,
4 ‘Ẹ̀yin ti rí ohun tí mo ti ṣe sí àwọn ará Ejibiti, àti bí mo ti gbé e yín ní apá ìyẹ́ idì.
Nagrama Isipi vahe'mofoma navu'nava'ma hunezmante'na tumpa namamo mofavre'a agekonare avrenteno avreno eaza hu'na, tamavre'na e'noazana tamagra'a ke'naze.
5 Nísinsin yìí, bí ẹ̀yin bá ṣe ìgbọ́ràn sí mi dé ojú àmì, tí ẹ sì pa májẹ̀mú mi mọ́, nígbà náà ni ẹ̀yin ó jẹ́ ìṣúra fún mi ju gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù lọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ayé ni tèmi.
Hagi menima tamagra ke'nima nentahitma, huvempama hu'noake'ma tamage hutma amage'ma ante'nuta, maka mopane mopane vahepintira tamagrake Nagri vahera manigahaze. Na'ankure maka mopa Nagri mopa me'ne.
6 Ẹ̀yin yóò sì máa jẹ́ ilẹ̀ ọba àwọn àlùfáà fún mi, orílẹ̀-èdè mímọ́.’ Ìwọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ ti ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Tamagra Nagrini'a pristi eri'za eri vahe mani'netma, ruotage hu'neni'a kuma vahe manigahaze huno hu'ne hunka Israeli vahera zmasamigahane.
7 Mose sì tọ àwọn ènìyàn wá, ó sí pe àwọn àgbàgbà láàrín àwọn ènìyàn jọ. Ó sì gbé gbogbo ọ̀rọ̀ ti Olúwa pàṣẹ fún un láti sọ ní iwájú wọn.
Ana hutegeno Mosese'a agonafinti eramino, Israeli kva vahe'zaga eme zamagihu atru huno, Anumzamo'ma ome zamasamio huno hunte'nea nanekea zamasami'ne.
8 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì pa ohùn wọn pọ̀ wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa yóò ṣe ohun gbogbo ti Olúwa wí.” Mose sì mú ìdáhùn wọn padà tọ Olúwa lọ.
Hige'za maka vahe'mo'za kenona hu'za, Ra Anumzamo'ma hugantegenka eme hana kea maka amage antegahune hu'za hazageno, Mosese'a anankea erino Ra Anumzamofonte vu'ne.
9 Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò tọ̀ ọ́ wá nínú ìkùùkuu ṣíṣú dudu, kí àwọn ènìyàn lè gbọ́ ohùn mi nígbà ti mo bá ń bá ọ sọ̀rọ̀, kí wọn kí ó lè máa gbà ọ́ gbọ́.” Nígbà náà ni Mose sọ ohun tí àwọn ènìyàn wí fún Olúwa.
Ra Anumzamo'a anage huno Mosesena asmi'ne, Antahio, Nagra hampogino antrako hu'ne'nia hampompi e'na kagranena keaga eme nehanuge'za, nentahi'za kagrama hana kerera maka knafina zamentintia huvava hugahaze. Anante Mosese'a Israeli vahe'mokizmi nanekea Ra Anumzamofona asami'ne.
10 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Tọ àwọn ènìyàn lọ kí o sì yà wọ́n sí mímọ́ ni òní àti ni ọ̀la. Jẹ́ kí wọn kí ó fọ aṣọ wọn.
Higeno Ra Anumzamo'a mago'ene Mosesena asamino, Menine okinena zamagra zamazeri ruotage nehu'za, kukena zimia sesehu agru nehu'za,
11 Kí wọn kí ó sì múra di ọjọ́ kẹta, nítorí ni ọjọ́ náà ni Olúwa yóò sọ̀kalẹ̀ sí orí òkè Sinai ni ojú gbogbo àwọn ènìyàn.
nampa 3 knarera retro hiho, na'ankure e'i ana knarera Ra Anumzamo'a maka vahe'mokizmi zmavuga Sainai agonafi eramigahie.
12 Kí ìwọ kí ó ṣe ààlà fún àwọn ènìyàn, kí ìwọ kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ kíyèsí ara yín, kí ẹ má ṣe gun orí òkè lọ, kí ẹ má tilẹ̀ fi ọwọ́ ba etí rẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkè náà, ó dájú, pípa ni a ó pa á.
Hagi kagra avame'za agonamofo agafina anteganeginka anage huo, tamagra kva hu'netma agonafina agatereta ovutma, ana avame'zantema uravao huno avako huge, agonafima mrerige'ma hanimofona ahe frigahaze.
13 A ó sọ ọ́ ní òkúta tàbí kí a ta á ní ọfà, ọwọ́kọ́wọ́ kò gbọdọ̀ kàn án. Ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko, òun kì yóò wà láààyè.’ Nígbà ti ìpè bá dún nìkan ni kí wọn ó gun òkè wá.”
Tamazanura avako hutma anamofona ahe ofrita, have knonu matevutma ahefrige, kevereti aheho. Vahe'mozafi afu'zagamo'zama anama hanazana frigahaze. Hagi mememofo pazivenu'ma za'zate'ma ufemaresageta, agonarega mrerigahaze.
14 Mose sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn, ó yà wọ́n sí mímọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn.
Anante Mosese'a agona atreno uramino zamazeri ruotage nehige'za, kukena zamia sese hu'naze.
15 Ó sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ múra sílẹ̀ di ọjọ́ kẹta; ẹ má ṣe bá aya yín lòpọ̀.”
Mosese'a anage huno zamasami'ne, Nampa 3 knama esigu retro hutma nemanitma, a'netaminena omaseho.
16 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kẹta, àrá àti mọ̀nàmọ́ná sì wà pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó ṣú dudu ní orí òkè, ìpè ńlá sì dún kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn tí ó wà ni ibùdó wárìrì.
Hagi nampa 3knama eanknamofo nanterana, monage nehigeno kopsinamo'a trage huno enevigeno, antrako hu'nea hampomo ana agona refitegeno, ufenkrafa nehigeno, nomaki'za maka mani'naza vahe'mokizmia tusi'a zmahirahitene.
17 Mose sì kó àwọn ènìyàn tí ó jáde láti ibùdó wá pàdé Ọlọ́run, wọ́n dúró nítòsí òkè.
Anante Ra Anumzamofo ome kehogu Mosese'a kumazmifinti zmavare fegi'a atreno zamavreno vige'za, agonamofo agiafi oti'naze.
18 Èéfín sì bo òkè Sinai nítorí Olúwa sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ nínú iná. Èéfín náà sì ń ru sókè bí èéfín iná ìléru, gbogbo òkè náà sì mì tìtì.
Hagi Sainai agonamofona toki'mo'a miko refitevagare'ne. Na'ankure Ra Anumzamo'a tusi'a tevefi eramino emani'negeno, tuki'mo'a tusi'a tevefinti'ma nehiaza huno kamogamo nehigeno, tusi'a imi erino ana agona eri tore'vare hu'ne.
19 Ohùn ìpè sì ń rinlẹ̀ dòdò. Mose sọ̀rọ̀, Ọlọ́run sì fi àrá dá a lóhùn.
Hanki ufemofo agerumo'ma rura huno nevigeno'a, Mosese'ma kema nehigeno, Anumzamo'a monagema hiaza huno kenona'a humi'ne.
20 Olúwa sọ̀kalẹ̀ sí orí òkè Sinai, o sì pe Mose wá sí orí òkè náà. Mose sì gun orí òkè.
Ra Anumzamo'a Sainai agona morusate eneramino, Mosesena ke higeno mareri'ne.
21 Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀, kí ó sì kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn, kí wọn má ṣe fi tipátipá wá ọ̀nà láti wo Olúwa, bí wọn bá ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ wọn yóò ṣègbé.
Anantera Ra Anumzamo'a Mosesena anage huno asami'ne, uraminka vahe'mokizmia kore ke huzmantege'za, avame'zama tafinte'za kagi'naza zana agatere'za emreoriho. Anama hanaza vahe'mo'za frigahaze.
22 Kódà àwọn àlùfáà tí ó ń wá síwájú Olúwa gbọdọ̀ ya ara wọn sí mímọ́ bí bẹ́ẹ̀ kọ́. Olúwa yóò kọlù wọ́n.”
Hagi pristi vahe'mo'zama Ra Anumzamo'nare'ma erava'oma hunaku'ma hanu'za, zamagra'a zamazeri ruotage nehu'za zamazeri agru hiho. Ana'ma osnage'na Nagra zamazeri haviza hugahie.
23 Mose wí fún Olúwa pé, “Àwọn ènìyàn kì yóò lè wá sí orí òkè Sinai, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ti kìlọ̀ fún wa pé, ‘Ṣe ààlà yí òkè ká, kí o sì yà á sí mímọ́.’”
Mosese'a anage huno Ra Anumzamofona asami'ne, vahe'mo'za ama agonafina omegahaze. Na'ankure Kagra ko nasaminke'na avame'za ante'nogenka ana avame'zamofona agateretma emreoriho hunka hunagru hunte'nane.
24 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, mú Aaroni gòkè wá pẹ̀lú rẹ. Ṣùgbọ́n kí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn má ṣe fi tipátipá gòkè tọ Olúwa. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò kọlù wọ́n.”
Hagi Ra Anumzamo'a anage huno Mosesena asami'ne, Uraminka Aronina ome avrenka eno. Hianagi zmatrege'za pristi vahe'ene, mago'a vahe'mo'za avame'zana agatere'za agonafina Nagritega omeho. Hagi anama hanage'na, Nagra zamazeri haviza hugahue.
25 Mose sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ènìyàn lọ. Ó sì sọ ohun tí Olúwa wí fún wọn.
Mosese'a uramino ana vahetamina, Ra Anumzamo'ma huntea kea ome zamsami'ne.

< Exodus 19 >