< Exodus 18 >

1 Jetro, àlùfáà Midiani, àna Mose, gbọ́ gbogbo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe fún Mose àti fún Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀, àti bí Olúwa ti mú àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Ejibiti wá.
A gdy teść Mojżesza Jetro, kapłan Midianitów, usłyszał o wszystkim, co Bóg uczynił dla Mojżesza i swego ludu Izraela, że PAN wyprowadził Izraela z Egiptu;
2 Nígbà náà ni Jetro mu aya Mose tí í ṣe Sippora padà lọ sọ́dọ̀ rẹ (nítorí ó ti dá a padà sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ tẹ́lẹ̀),
Wtedy Jetro, teść Mojżesza, wziął żonę Mojżesza Seforę, którą ten wcześniej odesłał;
3 Òun àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ méjèèjì. Orúkọ àkọ́bí ń jẹ́ Gerṣomu; nítorí Mose wí pé, “Èmi ń ṣe àlejò ni ilẹ̀ àjèjì.”
Oraz jej dwóch synów, z których jednemu było na imię Gerszom, bo [Mojżesz] powiedział: Jestem przybyszem w cudzej ziemi;
4 Èkejì ń jẹ́ Elieseri; ó wí pé, “Ọlọ́run baba mi ni alátìlẹ́yìn mi, ó sì gbà mí là kúrò lọ́wọ́ idà Farao.”
Drugi zaś miał na imię Eliezer, bo [mówił]: Bóg mego ojca był moją pomocą i wybawił mnie od miecza faraona.
5 Jetro, àna Mose, òun àti aya àti àwọn ọmọ Mose tọ̀ ọ́ wá nínú aginjù tí ó tẹ̀dó sí, nítòsí òkè Ọlọ́run.
Jetro, teść Mojżesza, przybył wraz z jego synami i żoną do Mojżesza na pustynię, gdzie obozował przy górze Boga.
6 Jetro sì ti ránṣẹ́ sí Mose pé, “Èmi Jetro, àna rẹ, ni mo ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, èmi àti aya àti àwọn ọmọkùnrin rẹ méjèèjì.”
I kazał powiedzieć Mojżeszowi: Ja, twój teść Jetro, idę do ciebie wraz z twoją żoną i z oboma jej synami.
7 Mose sì jáde lọ pàdé àna rẹ̀, ó tẹríba fún un, ó sì fi ẹnu kò ó ni ẹnu. Wọ́n sì béèrè àlàáfíà ara wọn, wọ́n sì wọ inú àgọ́ lọ.
Mojżesz wyszedł więc swemu teściowi naprzeciw, pokłonił się i ucałował go. Potem wypytywali się wzajemnie o powodzenie i weszli do namiotu.
8 Mose sọ fún àna rẹ̀ nípa ohun gbogbo ti Olúwa tí ṣe sí Farao àti àwọn ará Ejibiti nítorí Israẹli. Ó sọ nípa gbogbo ìṣòro tí wọn bá pàdé ní ọ̀nà wọn àti bí Olúwa ti gbà wọ́n là.
Mojżesz opowiedział swemu teściowi wszystko, co PAN uczynił faraonowi i Egipcjanom ze względu na Izraela, o całym trudzie, który ich spotkał w drodze, i [jak] PAN ich wybawił.
9 Inú Jetro dùn láti gbọ́ gbogbo ohun rere ti Olúwa ṣe fún Israẹli, ẹni tí ó mú wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Jetro cieszył się ze wszelkiego dobra, które PAN uczynił Izraelowi, że wybawił go z ręki Egipcjan.
10 Jetro sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa, ẹni tí ó gba yín là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti àti lọ́wọ́ Farao, ẹni tí ó sì gba àwọn ènìyàn là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti.
I Jetro powiedział: Niech będzie błogosławiony PAN, który was wybawił z ręki Egipcjan i z ręki faraona i który wybawił lud z niewoli egipskiej.
11 Mo mọ nísinsin yìí pé Olúwa tóbi ju gbogbo àwọn òrìṣà lọ; nítorí ti ó gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìgbéraga àti ìkà àwọn ará Ejibiti.”
Teraz wiem, że PAN jest większy od wszystkich bogów, bo gdy oni zuchwale powstawali przeciwko niemu, [to od tego poginęli].
12 Jetro, àna Mose, mú ẹbọ sísun àti ẹbọ wá fún Ọlọ́run. Aaroni àti gbogbo àgbàgbà Israẹli sì wá láti bá àna Mose jẹun ní iwájú Ọlọ́run.
Potem Jetro, teść Mojżesza, wziął całopalenie i ofiary dla Boga. Przyszedł też Aaron i wszyscy starsi Izraela, aby jeść chleb z teściem Mojżesza przed Bogiem.
13 Ní ọjọ́ kejì, Mose jókòó láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀; àwọn ènìyàn sì dúró ti Mose fún ìdájọ́ wọn láti òwúrọ̀ títí di ìrọ̀lẹ́.
Nazajutrz Mojżesz usiadł, aby sądzić lud. I lud stał przed Mojżeszem od rana aż do wieczora.
14 Nígbà tí àna Mose rí bí àkókò ti èyí ń gba ti pọ̀ tó àti ti àwọn ènìyàn ti ń dúró pẹ́ tó, ó wí pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ń ṣe sí àwọn ènìyàn? Èéṣe ti ìwọ nìkan jókòó gẹ́gẹ́ bí adájọ́, nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí dúró yí ọ ká láti òwúrọ̀ di ìrọ̀lẹ́?”
Gdy teść Mojżesza zobaczył wszystko, co on czynił dla ludu, powiedział: Cóż to jest, co ty czynisz dla ludu? Dlaczego ty siedzisz sam, a cały lud stoi przed tobą od rana aż do wieczora?
15 Mose dá a lóhùn pé, “Nítorí àwọn ènìyàn ń tọ̀ mí wá láti mọ́ ìfẹ́ Ọlọ́run.
Wtedy Mojżesz odpowiedział swemu teściowi: Bo lud przychodzi do mnie, aby się radzić Boga.
16 Nígbà tí wọ́n bá ní ẹjọ́, wọn a mú un tọ̀ mí wá, èmi a sì ṣe ìdájọ́ láàrín ẹnìkínní àti ẹnìkejì, èmi a sì máa mú wọn mọ òfin àti ìlànà Ọlọ́run.”
Gdy mają [jakąś] sprawę, przychodzą do mnie, a ja rozsądzam między nimi i oznajmiam ustawy Boga i jego prawa.
17 Àna Mose dá a lóhùn pé, “Ohun tí o ń ṣe yìí kò dára.
Teść Mojżesza powiedział do niego: Niedobra to rzecz, którą czynisz.
18 Ìwọ àti àwọn ènìyàn ti ń tọ̀ ọ́ wá yìí yóò dá ara yín ní agara; iṣẹ́ yìí pọ̀jù fún ọ, ìwọ nìkan kò lè dá a ṣe.
Zamęczycie się i ty, i ten lud, który [jest] z tobą, bo ta sprawa jest zbyt ciężka dla ciebie. Sam jej nie podołasz.
19 Nísinsin yìí, fetísílẹ̀ sí mi, èmi yóò sì gbà ọ́ ni ìmọ̀ràn, Ọlọ́run yóò sì wà pẹ̀lú rẹ. Ìwọ gbọdọ̀ jẹ́ aṣojú àwọn ènìyàn wọ̀nyí níwájú Ọlọ́run, ìwọ yóò sì mú èdè-àìyedè wá sí iwájú rẹ̀.
[Dlatego] posłuchaj teraz mego głosu, poradzę ci, a Bóg będzie z tobą. Wstawiaj się za ludem przed Bogiem i zanoś sprawy Bogu;
20 Kọ́ wọn ní òfin àti ìlànà Ọlọ́run, fi ọ̀nà igbe ayé ìwà-bí-Ọlọ́run hàn wọ́n àti iṣẹ́ tí wọn yóò máa ṣe.
Nauczaj go też ustaw i praw, wskazuj im drogę, którą mają chodzić, i czyny, które mają spełniać.
21 Ṣa àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n nínú gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn tó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti wọ́n jẹ́ olóòtítọ́, tí wọ́n kórìíra ìrẹ́jẹ; yàn wọ́n ṣe olórí, lórí ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún, ọgọ́rùn-ún ọgọ́rùn-ún, àádọ́ta-dọ́ta àti mẹ́wàá mẹ́wàá.
Upatrz też sobie wśród całego ludu mężczyzn dzielnych i bojących się Boga, mężczyzn prawdomównych, którzy nienawidzą chciwości, i ustanów ich przełożonymi nad tysiącem, nad setką, nad pięćdziesiątką i nad dziesiątką.
22 Jẹ́ kí wọn ó máa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn ni gbogbo ìgbà, ṣùgbọ́n jẹ́ kí wọn mú ẹjọ́ tí ó bá nira fún wọn láti dá tọ̀ ọ́ wá; kí wọn kí ó máa dá ẹjọ́ kéékèèké. Èyí ni yóò mú iṣẹ́ rẹ rọrùn, wọn yóò sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ lórí ìdájọ́ ṣíṣe.
Niech oni sądzą lud w każdym czasie. A gdy będzie ważniejsza sprawa, zaniosą ją do ciebie, ale każdą mniej ważną sprawę sami będą sądzić. W ten sposób ulżysz sobie, gdy poniosą [ciężar] z tobą.
23 Bí ìwọ bá ṣe èyí, bí Ọlọ́run bá sì fi àṣẹ sí i fún ọ bẹ́ẹ̀, àárẹ̀ kò sì ní tètè mu ọ, àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò sì padà lọ ilé wọn ni àlàáfíà.”
Jeśli tak uczynisz, a Bóg tak ci nakaże, wytrwasz i cały ten lud będzie wracać na swoje miejsce w pokoju.
24 Mose fetísílẹ̀ sí àna rẹ̀, ó sì ṣe ohun gbogbo tí ó wí fún un.
Mojżesz usłuchał więc rady swego teścia i uczynił wszystko, jak mu powiedział.
25 Mose sì yan àwọn ènìyàn tí wọ́n kún ojú òsùwọ̀n nínú gbogbo Israẹli; ó sì fi wọ́n jẹ olórí àwọn ènìyàn, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá.
I Mojżesz wybrał z całego Izraela dzielnych mężczyzn, i ustanowił ich przełożonymi nad ludem, nad tysiącem, nad setką, nad pięćdziesiątką i nad dziesiątką;
26 Wọ́n sì ń ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn ní ìgbà gbogbo. Wọ́n sì ń mú ẹjọ́ tó le tọ Mose wá; ṣùgbọ́n wọ́n ń dá ẹjọ́ tí kò le fúnra wọn.
I sądzili lud w każdym czasie. Trudne sprawy zanosili do Mojżesza, a każdą drobniejszą sprawę sami sądzili.
27 Mose sì jẹ́ kí àna rẹ̀ lọ ní ọ̀nà rẹ̀, Jetro sì padà sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Potem Mojżesz odprawił swego teścia, który odszedł do swej ziemi.

< Exodus 18 >