< Exodus 18 >

1 Jetro, àlùfáà Midiani, àna Mose, gbọ́ gbogbo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe fún Mose àti fún Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀, àti bí Olúwa ti mú àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Ejibiti wá.
And Jethro, priest of Midian, father-in-law of Moses, heard all that God had done for Moses, and for Israel his people, —in that Yahweh had brought forth Israel out of Egypt.
2 Nígbà náà ni Jetro mu aya Mose tí í ṣe Sippora padà lọ sọ́dọ̀ rẹ (nítorí ó ti dá a padà sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ tẹ́lẹ̀),
So Jethro, Moses father-in-law, took Zipporah, Moses wife, —after she had been sent home;
3 Òun àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ méjèèjì. Orúkọ àkọ́bí ń jẹ́ Gerṣomu; nítorí Mose wí pé, “Èmi ń ṣe àlejò ni ilẹ̀ àjèjì.”
and her two sons, —of whom, the name of the one, was Gershom, for, said he, A sojourner, am I in a strange land,
4 Èkejì ń jẹ́ Elieseri; ó wí pé, “Ọlọ́run baba mi ni alátìlẹ́yìn mi, ó sì gbà mí là kúrò lọ́wọ́ idà Farao.”
and, the name of the other, Eliezer, for the God of my father, was my help, and delivered me from the sword of Pharaoh.
5 Jetro, àna Mose, òun àti aya àti àwọn ọmọ Mose tọ̀ ọ́ wá nínú aginjù tí ó tẹ̀dó sí, nítòsí òkè Ọlọ́run.
And Jethro, Moses father-in-law, came in, with his two sons and his wife, unto Moses, —into the desert where, he, was encamping, the mountain of God;
6 Jetro sì ti ránṣẹ́ sí Mose pé, “Èmi Jetro, àna rẹ, ni mo ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, èmi àti aya àti àwọn ọmọkùnrin rẹ méjèèjì.”
and said unto Moses, I, thy father-in-law, Jethro, am coming in unto thee, —and thy wife, and her two sons, with her.
7 Mose sì jáde lọ pàdé àna rẹ̀, ó tẹríba fún un, ó sì fi ẹnu kò ó ni ẹnu. Wọ́n sì béèrè àlàáfíà ara wọn, wọ́n sì wọ inú àgọ́ lọ.
So Moses went forth to meet his father-in-law, and bowed himself down to him and kissed him, and they asked each other of their welfare, —and came into the tent.
8 Mose sọ fún àna rẹ̀ nípa ohun gbogbo ti Olúwa tí ṣe sí Farao àti àwọn ará Ejibiti nítorí Israẹli. Ó sọ nípa gbogbo ìṣòro tí wọn bá pàdé ní ọ̀nà wọn àti bí Olúwa ti gbà wọ́n là.
Then Moses recounted to his father-in-law, all that Yahweh had done to Pharaoh and to the Egyptians, for Israel’s sake, —all the hardship which had befallen them by the way, and how Yahweh had delivered them.
9 Inú Jetro dùn láti gbọ́ gbogbo ohun rere ti Olúwa ṣe fún Israẹli, ẹni tí ó mú wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Then did Jethro rejoice, for all the good which Yahweh had done to Israel, —whom he had delivered out of the hand of the Egyptians.
10 Jetro sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa, ẹni tí ó gba yín là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti àti lọ́wọ́ Farao, ẹni tí ó sì gba àwọn ènìyàn là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti.
And Jethro said—Blessed be Yahweh, who hath delivered you out of the hand of the Egyptians and out of the hand of Pharaoh, —Who hath delivered the people from under the hand of the Egyptians:
11 Mo mọ nísinsin yìí pé Olúwa tóbi ju gbogbo àwọn òrìṣà lọ; nítorí ti ó gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìgbéraga àti ìkà àwọn ará Ejibiti.”
Now, I know, that, greater, is Yahweh than all the gods, —Even in the thing wherein they were arrogant over them.
12 Jetro, àna Mose, mú ẹbọ sísun àti ẹbọ wá fún Ọlọ́run. Aaroni àti gbogbo àgbàgbà Israẹli sì wá láti bá àna Mose jẹun ní iwájú Ọlọ́run.
Then took Jethro father-in-law of Moses, an ascending-offering and sacrifices to God, —and Aaron and all the elders of Israel came in to eat bread with the father-in-law of Moses before God.
13 Ní ọjọ́ kejì, Mose jókòó láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀; àwọn ènìyàn sì dúró ti Mose fún ìdájọ́ wọn láti òwúrọ̀ títí di ìrọ̀lẹ́.
Now it came to pass on the morrow, that Moses sat, to judge the people, —and the people stood by Moses, from the morning, until the evening.
14 Nígbà tí àna Mose rí bí àkókò ti èyí ń gba ti pọ̀ tó àti ti àwọn ènìyàn ti ń dúró pẹ́ tó, ó wí pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ń ṣe sí àwọn ènìyàn? Èéṣe ti ìwọ nìkan jókòó gẹ́gẹ́ bí adájọ́, nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí dúró yí ọ ká láti òwúrọ̀ di ìrọ̀lẹ́?”
And when Moses father-in-law saw all that he, was doing for the people, he said—What is this thing which, thou, art doing for the people? Wherefore art, thou, sitting alone, with all the people, stationed by thee, from morning until evening?
15 Mose dá a lóhùn pé, “Nítorí àwọn ènìyàn ń tọ̀ mí wá láti mọ́ ìfẹ́ Ọlọ́run.
And Moses said to his father-in-law, —Because the people come in unto me to seek God:
16 Nígbà tí wọ́n bá ní ẹjọ́, wọn a mú un tọ̀ mí wá, èmi a sì ṣe ìdájọ́ láàrín ẹnìkínní àti ẹnìkejì, èmi a sì máa mú wọn mọ òfin àti ìlànà Ọlọ́run.”
When they have a matter, they come in unto me, then do I judge between a man and his neighbour, —and make known the statutes of God and his laws.
17 Àna Mose dá a lóhùn pé, “Ohun tí o ń ṣe yìí kò dára.
Then said Moses’ father-in-law unto him, —Not good, is the thing that thou art doing.
18 Ìwọ àti àwọn ènìyàn ti ń tọ̀ ọ́ wá yìí yóò dá ara yín ní agara; iṣẹ́ yìí pọ̀jù fún ọ, ìwọ nìkan kò lè dá a ṣe.
Thou wilt get quite worn out, both thou and this people that is with thee, —for the thing is too heavy for thee, thou canst not do it, alone.
19 Nísinsin yìí, fetísílẹ̀ sí mi, èmi yóò sì gbà ọ́ ni ìmọ̀ràn, Ọlọ́run yóò sì wà pẹ̀lú rẹ. Ìwọ gbọdọ̀ jẹ́ aṣojú àwọn ènìyàn wọ̀nyí níwájú Ọlọ́run, ìwọ yóò sì mú èdè-àìyedè wá sí iwájú rẹ̀.
Now, hearken thou to my voice—let me counsel thee, and may God be with thee: Be, thou, for the people, in front of God, so shalt, thou, bring the matters unto God;
20 Kọ́ wọn ní òfin àti ìlànà Ọlọ́run, fi ọ̀nà igbe ayé ìwà-bí-Ọlọ́run hàn wọ́n àti iṣẹ́ tí wọn yóò máa ṣe.
and shalt cause to shine upon them, the statutes and the laws, —and make known to them the way wherein they should go, and the work they should do.
21 Ṣa àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n nínú gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn tó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti wọ́n jẹ́ olóòtítọ́, tí wọ́n kórìíra ìrẹ́jẹ; yàn wọ́n ṣe olórí, lórí ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún, ọgọ́rùn-ún ọgọ́rùn-ún, àádọ́ta-dọ́ta àti mẹ́wàá mẹ́wàá.
Thou thyself, therefore shalt look out, from among all the people—men of ability, reverers of God, men of fidelity, haters of extortion, —and place them over [them] as rulers of thousands, rulers of hundreds, rulers of fifties, and rulers of tens.
22 Jẹ́ kí wọn ó máa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn ni gbogbo ìgbà, ṣùgbọ́n jẹ́ kí wọn mú ẹjọ́ tí ó bá nira fún wọn láti dá tọ̀ ọ́ wá; kí wọn kí ó máa dá ẹjọ́ kéékèèké. Èyí ni yóò mú iṣẹ́ rẹ rọrùn, wọn yóò sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ lórí ìdájọ́ ṣíṣe.
So shall they judge the people at any time, and it shall be, all the great matters, shall they bring in unto thee, but all the small matters, shall, they themselves, judge, —so, lighten thou the burden for thyself, and let them bear it with thee.
23 Bí ìwọ bá ṣe èyí, bí Ọlọ́run bá sì fi àṣẹ sí i fún ọ bẹ́ẹ̀, àárẹ̀ kò sì ní tètè mu ọ, àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò sì padà lọ ilé wọn ni àlàáfíà.”
If, this thing, thou wilt do, and God shall command thee, then shalt thou be able to endure, —yea, moreover, all this people, shall go in, unto their dwellings, contented.
24 Mose fetísílẹ̀ sí àna rẹ̀, ó sì ṣe ohun gbogbo tí ó wí fún un.
So Moses hearkened to the voice of his father-in-law, and did all that he had said;
25 Mose sì yan àwọn ènìyàn tí wọ́n kún ojú òsùwọ̀n nínú gbogbo Israẹli; ó sì fi wọ́n jẹ olórí àwọn ènìyàn, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá.
and Moses chose men of ability out of all Israel, and set them to be heads over the people, —rulers of thousands, rulers of hundreds, rulers of fifties, and rulers of tens.
26 Wọ́n sì ń ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn ní ìgbà gbogbo. Wọ́n sì ń mú ẹjọ́ tó le tọ Mose wá; ṣùgbọ́n wọ́n ń dá ẹjọ́ tí kò le fúnra wọn.
And they shall judge the people, at any time, —the hard matters, shall they bring in unto Moses, but all the small matters, shall, they themselves, judge.
27 Mose sì jẹ́ kí àna rẹ̀ lọ ní ọ̀nà rẹ̀, Jetro sì padà sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
And Moses sent forth his father-in-law, —and he went his way by himself unto his own land.

< Exodus 18 >