< Exodus 17 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli si gbéra láti jáde kúrò láti aginjù Sini wọ́n ń lọ láti ibi kan de ibi kan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ. Wọ́n pàgọ́ sí Refidimu, ṣùgbọ́n kò sí omi fún àwọn ènìyàn láti mú.
Toute la congrégation des enfants d'Israël partit du désert de Sin, selon l'ordre de l'Éternel, et campa à Rephidim; mais il n'y avait pas d'eau à boire pour le peuple.
2 Àwọn ènìyàn sì sọ̀ fún Mose, wọ́n wí pé, “Fún wa ni omi mu.” Mose dá wọn lóhùn wí pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń bá mi jà? Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán Olúwa wò?”
Le peuple se querella avec Moïse, et dit: « Donne-nous de l'eau à boire. » Moïse leur dit: « Pourquoi vous disputez-vous avec moi? Pourquoi mettez-vous Yahvé à l'épreuve? »
3 Ṣùgbọ́n òǹgbẹ ń gbẹ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń kùn sí Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde kúrò ní Ejibiti láti mú kí òǹgbẹ pa àwa, àwọn ọmọ wa àti ohun ọ̀sìn wa ku fún òǹgbẹ.”
Le peuple avait soif d'eau à cet endroit; alors le peuple murmura contre Moïse et dit: « Pourquoi nous as-tu fait sortir d'Égypte, pour nous faire mourir de soif, nous, nos enfants et notre bétail? »
4 Nígbà náà ni Mose gbé ohùn rẹ̀ sókè sí Olúwa pé, “Kí ni kí èmi kí ó ṣe fún àwọn ènìyàn yìí? Wọ́n múra tan láti sọ mi ni òkúta.”
Moïse cria à Yahvé en disant: « Que dois-je faire de ce peuple? Ils sont presque prêts à me lapider. »
5 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Máa lọ síwájú àwọn ènìyàn, mú nínú àwọn àgbàgbà Israẹli pẹ̀lú rẹ, mú ọ̀pá tí ìwọ fi lu odò Naili lọ́wọ́ kí ó sì máa lọ.
Yahvé dit à Moïse: « Avance devant le peuple, prends avec toi les anciens d'Israël, prends dans ta main le bâton avec lequel tu as frappé le Nil, et pars.
6 Èmi yóò dúró ni ibẹ̀ dè ọ ni orí àpáta ni Horebu. Ìwọ ó sì lu àpáta, omi yóò sì jáde nínú rẹ̀ fún àwọn ènìyàn láti mu.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀ ni iwájú àwọn àgbàgbà Israẹli.
Voici, je me tiendrai devant toi, là, sur le rocher de l'Horeb. Tu frapperas le rocher, et il en sortira de l'eau que le peuple pourra boire. » Moïse fit ainsi, sous les yeux des anciens d'Israël.
7 Ó sì sọ orúkọ ibẹ̀ ni Massa àti Meriba, nítorí àwọn ọmọ Israẹli sọ̀, wọ́n sì dán Olúwa wò, wọ́n wí pé, “Ǹjẹ́ Olúwa ń bẹ láàrín wa tàbí kò sí?”
Il donna à ce lieu le nom de Massa et de Meriba, parce que les enfants d'Israël se disputaient et qu'ils mettaient Yahvé à l'épreuve, en disant: « Yahvé est-il au milieu de nous, ou non? »
8 Àwọn ara Amaleki jáde, wọ́n sì dìde ogun sí àwọn ọmọ Israẹli ni Refidimu.
Amalek vint combattre Israël à Rephidim.
9 Mose sì sọ fún Joṣua pé, “Yàn lára àwọn ọkùnrin fún wa, kí wọn ó sì jáde lọ bá àwọn ará Amaleki jà. Ní ọ̀la, èmi yóò dúró ni orí òkè pẹ̀lú ọ̀pá Ọlọ́run ní ọwọ́ mi.”
Moïse dit à Josué: « Choisis des hommes pour nous, et va combattre Amalek. Demain, je me tiendrai sur le sommet de la colline, la verge de Dieu dans ma main. »
10 Joṣua ṣe bí Mose ti wí fún un, ó sì bá àwọn ará Amaleki jagun; nígbà tí Mose, Aaroni àti Huri lọ sí orí òkè náà.
Josué fit ce que Moïse lui avait dit et combattit Amalek. Moïse, Aaron et Hur montèrent au sommet de la colline.
11 Níwọ́n ìgbà tí Mose bá gbé apá rẹ̀ sókè, Israẹli n borí ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá sì rẹ apá rẹ̀ sílẹ̀, Amaleki a sì borí.
Lorsque Moïse leva la main, Israël l'emporta. Quand il baissa la main, Amalek l'emporta.
12 Ṣùgbọ́n apá ń ro Mose, wọ́n mú òkúta, wọ́n sì fi sí abẹ́ rẹ̀, ó sì jókòó lé òkúta náà; Aaroni àti Huri sì mu ní apá rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àti èkejì ni apá òsì; apá rẹ̀ méjèèjì sì dúró gangan títí di ìgbà ti oòrùn wọ.
Mais les mains de Moïse étaient lourdes; on prit donc une pierre, on la mit sous lui, et il s'assit dessus. Aaron et Hur soutenaient ses mains, l'un d'un côté, l'autre de l'autre. Ses mains restèrent stables jusqu'au coucher du soleil.
13 Joṣua sì fi ojú idà ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki.
Josué vainquit Amalek et son peuple au fil de l'épée.
14 Olúwa sì sọ fun Mose pé. “Kọ èyí sì inú ìwé fún ìrántí, kí o sì sọ fún Joṣua pẹ̀lú; nítorí èmi yóò pa ìrántí Amaleki run pátápátá kúrò lábẹ́ ọ̀run.”
Yahvé dit à Moïse: « Ecris ceci dans un livre, comme souvenir, et répète-le aux oreilles de Josué: j'effacerai la mémoire d'Amalek de dessous le ciel. »
15 Mose sì tẹ́ pẹpẹ kan, ó sì sọ orúkọ pẹpẹ náà ní Olúwa ni Àsíá mi.
Moïse bâtit un autel et l'appela « Yahvé notre bannière ».
16 Ó wí pé, “A gbé ọwọ́ sókè sí ìtẹ́ Olúwa. Olúwa yóò bá Amaleki jagun láti ìran dé ìran.”
Il dit: « L'Éternel l'a juré: l'Éternel fera la guerre à Amalek de génération en génération. »

< Exodus 17 >