< Exodus 17 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli si gbéra láti jáde kúrò láti aginjù Sini wọ́n ń lọ láti ibi kan de ibi kan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ. Wọ́n pàgọ́ sí Refidimu, ṣùgbọ́n kò sí omi fún àwọn ènìyàn láti mú.
And they set out all [the] congregation of [the] people of Israel from [the] wilderness of Sin to journeyings their on [the] mouth of Yahweh and they encamped at Rephidim and there not [was] water to drink the people.
2 Àwọn ènìyàn sì sọ̀ fún Mose, wọ́n wí pé, “Fún wa ni omi mu.” Mose dá wọn lóhùn wí pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń bá mi jà? Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán Olúwa wò?”
And it quarreled the people with Moses and they said give to us water so we may drink and he said to them Moses why? are you quarreling! with me why? are you putting to [the] test! Yahweh.
3 Ṣùgbọ́n òǹgbẹ ń gbẹ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń kùn sí Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde kúrò ní Ejibiti láti mú kí òǹgbẹ pa àwa, àwọn ọmọ wa àti ohun ọ̀sìn wa ku fún òǹgbẹ.”
And it was thirsty there the people for water and it grumbled the people on Moses and it said why? this did you bring up us from Egypt to put to death me and children my and livestock my by thirst.
4 Nígbà náà ni Mose gbé ohùn rẹ̀ sókè sí Olúwa pé, “Kí ni kí èmi kí ó ṣe fún àwọn ènìyàn yìí? Wọ́n múra tan láti sọ mi ni òkúta.”
And he cried out Moses to Yahweh saying what? will I do to the people this yet a little and they will stone me.
5 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Máa lọ síwájú àwọn ènìyàn, mú nínú àwọn àgbàgbà Israẹli pẹ̀lú rẹ, mú ọ̀pá tí ìwọ fi lu odò Naili lọ́wọ́ kí ó sì máa lọ.
And he said Yahweh to Moses pass on before the people and take with you some of [the] elders of Israel and staff your which you struck with it the River take in hand your and you will go.
6 Èmi yóò dúró ni ibẹ̀ dè ọ ni orí àpáta ni Horebu. Ìwọ ó sì lu àpáta, omi yóò sì jáde nínú rẹ̀ fún àwọn ènìyàn láti mu.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀ ni iwájú àwọn àgbàgbà Israẹli.
Here I [will be] standing before you there - on the rock at Horeb and you will strike the rock and they will come out from it waters and it will drink the people and he did so Moses to [the] eyes of [the] elders of Israel.
7 Ó sì sọ orúkọ ibẹ̀ ni Massa àti Meriba, nítorí àwọn ọmọ Israẹli sọ̀, wọ́n sì dán Olúwa wò, wọ́n wí pé, “Ǹjẹ́ Olúwa ń bẹ láàrín wa tàbí kò sí?”
And he called [the] name of the place Massah and Meribah on [the] quarrel of - [the] people of Israel and because put to [the] test they Yahweh saying ¿ [is] there Yahweh in midst our or? not.
8 Àwọn ara Amaleki jáde, wọ́n sì dìde ogun sí àwọn ọmọ Israẹli ni Refidimu.
And it came Amalek and it joined battle with Israel at Rephidim.
9 Mose sì sọ fún Joṣua pé, “Yàn lára àwọn ọkùnrin fún wa, kí wọn ó sì jáde lọ bá àwọn ará Amaleki jà. Ní ọ̀la, èmi yóò dúró ni orí òkè pẹ̀lú ọ̀pá Ọlọ́run ní ọwọ́ mi.”
And he said Moses to Joshua choose for us men and go out fight against Amalek tomorrow I [will be] standing on [the] top of the hill and [the] staff of God [will be] in hand my.
10 Joṣua ṣe bí Mose ti wí fún un, ó sì bá àwọn ará Amaleki jagun; nígbà tí Mose, Aaroni àti Huri lọ sí orí òkè náà.
And he did Joshua just as he had said to him Moses by fighting against Amalek and Moses Aaron and Hur they went up [the] top of the hill.
11 Níwọ́n ìgbà tí Mose bá gbé apá rẹ̀ sókè, Israẹli n borí ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá sì rẹ apá rẹ̀ sílẹ̀, Amaleki a sì borí.
And it was just when he lifted up Moses hand his and it prevailed Israel and just when he gave rest hand his and it prevailed Amalek.
12 Ṣùgbọ́n apá ń ro Mose, wọ́n mú òkúta, wọ́n sì fi sí abẹ́ rẹ̀, ó sì jókòó lé òkúta náà; Aaroni àti Huri sì mu ní apá rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àti èkejì ni apá òsì; apá rẹ̀ méjèèjì sì dúró gangan títí di ìgbà ti oòrùn wọ.
And [the] hands of Moses [were] heavy and they took a stone and they put [it] under him and he sat on it and Aaron and Hur they supported hands his from this one and from this one and it was hands his [were] steadiness until went the sun.
13 Joṣua sì fi ojú idà ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki.
And he defeated Joshua Amalek and people its to [the] mouth of [the] sword.
14 Olúwa sì sọ fun Mose pé. “Kọ èyí sì inú ìwé fún ìrántí, kí o sì sọ fún Joṣua pẹ̀lú; nítorí èmi yóò pa ìrántí Amaleki run pátápátá kúrò lábẹ́ ọ̀run.”
And he said Yahweh to Moses write this reminder in the book and put [it] in [the] ears of Joshua for certainly I will wipe out [the] remembrance of Amalek from under the heavens.
15 Mose sì tẹ́ pẹpẹ kan, ó sì sọ orúkọ pẹpẹ náà ní Olúwa ni Àsíá mi.
And he built Moses an altar and he called name its Yahweh - [is] standard my.
16 Ó wí pé, “A gbé ọwọ́ sókè sí ìtẹ́ Olúwa. Olúwa yóò bá Amaleki jagun láti ìran dé ìran.”
And he said that a hand on [the] throne of Yahweh war [will belong] to Yahweh with Amalek from generation generation.

< Exodus 17 >