< Exodus 17 >
1 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli si gbéra láti jáde kúrò láti aginjù Sini wọ́n ń lọ láti ibi kan de ibi kan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ. Wọ́n pàgọ́ sí Refidimu, ṣùgbọ́n kò sí omi fún àwọn ènìyàn láti mú.
All the congregation of the children of Israel [God prevails] traveled from the wilderness of Cin [Clay], by their journeys, according to Adonai’s order, and encamped in Rephidim; but there was no water for the people to drink.
2 Àwọn ènìyàn sì sọ̀ fún Mose, wọ́n wí pé, “Fún wa ni omi mu.” Mose dá wọn lóhùn wí pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń bá mi jà? Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán Olúwa wò?”
Therefore the people quarreled with Moses [Drawn out], and said, “Give us water to drink.” Moses [Drawn out] said to them, “Why do you quarrel with me? Why do you test Adonai?”
3 Ṣùgbọ́n òǹgbẹ ń gbẹ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń kùn sí Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde kúrò ní Ejibiti láti mú kí òǹgbẹ pa àwa, àwọn ọmọ wa àti ohun ọ̀sìn wa ku fún òǹgbẹ.”
The people were thirsty for water there; and the people murmured against Moses [Drawn out], and said, “Why have you brought us up out of Egypt [Abode of slavery], to kill us, our children, and our livestock with thirst?”
4 Nígbà náà ni Mose gbé ohùn rẹ̀ sókè sí Olúwa pé, “Kí ni kí èmi kí ó ṣe fún àwọn ènìyàn yìí? Wọ́n múra tan láti sọ mi ni òkúta.”
Moses [Drawn out] cried to Adonai, saying, “What shall I do with these people? They are almost ready to stone me.”
5 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Máa lọ síwájú àwọn ènìyàn, mú nínú àwọn àgbàgbà Israẹli pẹ̀lú rẹ, mú ọ̀pá tí ìwọ fi lu odò Naili lọ́wọ́ kí ó sì máa lọ.
Adonai said to Moses [Drawn out], “Walk on before the people, and take the elders of Israel [God prevails] with you, and take the rod in your hand with which you struck the Nile, and go.
6 Èmi yóò dúró ni ibẹ̀ dè ọ ni orí àpáta ni Horebu. Ìwọ ó sì lu àpáta, omi yóò sì jáde nínú rẹ̀ fún àwọn ènìyàn láti mu.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀ ni iwájú àwọn àgbàgbà Israẹli.
Behold, I will stand before you there on the rock in Horeb [Desert]. You shall strike the rock, and water will come out of it, that the people may drink.” Moses [Drawn out] did so in the sight of the elders of Israel [God prevails].
7 Ó sì sọ orúkọ ibẹ̀ ni Massa àti Meriba, nítorí àwọn ọmọ Israẹli sọ̀, wọ́n sì dán Olúwa wò, wọ́n wí pé, “Ǹjẹ́ Olúwa ń bẹ láàrín wa tàbí kò sí?”
He called the name of the place Massah [Testing], and Meribah [Quarreling], because the children of Israel [God prevails] quarreled, and because they tested Adonai, saying, “Is Adonai among us, or not?”
8 Àwọn ara Amaleki jáde, wọ́n sì dìde ogun sí àwọn ọmọ Israẹli ni Refidimu.
Then Amalek [Man who licks up] came and fought with Israel [God prevails] in Rephidim.
9 Mose sì sọ fún Joṣua pé, “Yàn lára àwọn ọkùnrin fún wa, kí wọn ó sì jáde lọ bá àwọn ará Amaleki jà. Ní ọ̀la, èmi yóò dúró ni orí òkè pẹ̀lú ọ̀pá Ọlọ́run ní ọwọ́ mi.”
Moses [Drawn out] said to Joshua [Yah Salvation], “Choose men for us, and go out, fight with Amalek [Man who licks up]. Tomorrow I will stand on the top of the hill with God’s rod in my hand.”
10 Joṣua ṣe bí Mose ti wí fún un, ó sì bá àwọn ará Amaleki jagun; nígbà tí Mose, Aaroni àti Huri lọ sí orí òkè náà.
So Joshua [Yah Salvation] did as Moses [Drawn out] had told him, and fought with Amalek [Man who licks up]; and Moses [Drawn out], Aaron [Light-bringer], and Hur went up to the top of the hill.
11 Níwọ́n ìgbà tí Mose bá gbé apá rẹ̀ sókè, Israẹli n borí ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá sì rẹ apá rẹ̀ sílẹ̀, Amaleki a sì borí.
When Moses [Drawn out] held up his hand, Israel [God prevails] prevailed. When he let down his hand, Amalek [Man who licks up] prevailed.
12 Ṣùgbọ́n apá ń ro Mose, wọ́n mú òkúta, wọ́n sì fi sí abẹ́ rẹ̀, ó sì jókòó lé òkúta náà; Aaroni àti Huri sì mu ní apá rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àti èkejì ni apá òsì; apá rẹ̀ méjèèjì sì dúró gangan títí di ìgbà ti oòrùn wọ.
But Moses [Drawn out]’ hands were heavy; and they took a stone, and put it under him, and he sat on it. Aaron [Light-bringer] and Hur held up his hands, the one on the one side, and the other on the other side. His hands were steady until sunset.
13 Joṣua sì fi ojú idà ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki.
Joshua [Yah Salvation] defeated Amalek [Man who licks up] and his people with the edge of the sword.
14 Olúwa sì sọ fun Mose pé. “Kọ èyí sì inú ìwé fún ìrántí, kí o sì sọ fún Joṣua pẹ̀lú; nítorí èmi yóò pa ìrántí Amaleki run pátápátá kúrò lábẹ́ ọ̀run.”
Adonai said to Moses [Drawn out], “Write this for a memorial in a book, and rehearse it in the ears of Joshua [Yah Salvation]: that I will utterly blot out the memory of Amalek [Man who licks up] from under the sky.”
15 Mose sì tẹ́ pẹpẹ kan, ó sì sọ orúkọ pẹpẹ náà ní Olúwa ni Àsíá mi.
Moses [Drawn out] built an altar, and called its name Adonai our Banner.
16 Ó wí pé, “A gbé ọwọ́ sókè sí ìtẹ́ Olúwa. Olúwa yóò bá Amaleki jagun láti ìran dé ìran.”
He said, “Yah has sworn: ‘Adonai will have war with Amalek [Man who licks up] from generation to generation.’”