< Exodus 17 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli si gbéra láti jáde kúrò láti aginjù Sini wọ́n ń lọ láti ibi kan de ibi kan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ. Wọ́n pàgọ́ sí Refidimu, ṣùgbọ́n kò sí omi fún àwọn ènìyàn láti mú.
Tedy když se odebralo všecko shromáždění synů Izraelských z pouště Sin, po stanovištích svých vedlé rozkazu Hospodinova, položili se v Rafidim, kdež nebylo vod, kteréž by lid píti mohl.
2 Àwọn ènìyàn sì sọ̀ fún Mose, wọ́n wí pé, “Fún wa ni omi mu.” Mose dá wọn lóhùn wí pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń bá mi jà? Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán Olúwa wò?”
Protož domlouval se lid na Mojžíše, pravě: Dejte nám vody, abychom pili. Jimž odpověděl Mojžíš: Proč se na mne domlouváte? Proč pokoušíte Hospodina?
3 Ṣùgbọ́n òǹgbẹ ń gbẹ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń kùn sí Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde kúrò ní Ejibiti láti mú kí òǹgbẹ pa àwa, àwọn ọmọ wa àti ohun ọ̀sìn wa ku fún òǹgbẹ.”
I žíznil tu lid pro nedostatek vod, a reptal na Mojžíše a mluvil: Proč jsi vyvedl nás z Egypta, abys mne s syny i dobytky mými žízní zmořil?
4 Nígbà náà ni Mose gbé ohùn rẹ̀ sókè sí Olúwa pé, “Kí ni kí èmi kí ó ṣe fún àwọn ènìyàn yìí? Wọ́n múra tan láti sọ mi ni òkúta.”
Tedy volal Mojžíš k Hospodinu, řka: Což mám činiti s tím lidem? Však již tudíž ukamenují mne.
5 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Máa lọ síwájú àwọn ènìyàn, mú nínú àwọn àgbàgbà Israẹli pẹ̀lú rẹ, mú ọ̀pá tí ìwọ fi lu odò Naili lọ́wọ́ kí ó sì máa lọ.
I řekl Hospodin Mojžíšovi: Jdiž před lidem, pojma s sebou některé z starších Izraelských; hůl také svou kterouž jsi udeřil v vodu, vezmi do ruky své a jdi.
6 Èmi yóò dúró ni ibẹ̀ dè ọ ni orí àpáta ni Horebu. Ìwọ ó sì lu àpáta, omi yóò sì jáde nínú rẹ̀ fún àwọn ènìyàn láti mu.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀ ni iwájú àwọn àgbàgbà Israẹli.
Aj, já státi budu před tebou tam na skále, na Orébě; i udeříš v skálu, a vyjdou z ní vody, kteréž bude píti lid. I učinil tak Mojžíš před očima starších Izraelských.
7 Ó sì sọ orúkọ ibẹ̀ ni Massa àti Meriba, nítorí àwọn ọmọ Israẹli sọ̀, wọ́n sì dán Olúwa wò, wọ́n wí pé, “Ǹjẹ́ Olúwa ń bẹ láàrín wa tàbí kò sí?”
A dal jméno místu tomu Massah a Meribah, pro reptání synů Izraelských, a že pokoušeli Hospodina, řkouce: Jest-li Hospodin u prostřed nás, či není?
8 Àwọn ara Amaleki jáde, wọ́n sì dìde ogun sí àwọn ọmọ Israẹli ni Refidimu.
Přitáhl pak Amalech, a bojoval s Izraelem v Rafidim.
9 Mose sì sọ fún Joṣua pé, “Yàn lára àwọn ọkùnrin fún wa, kí wọn ó sì jáde lọ bá àwọn ará Amaleki jà. Ní ọ̀la, èmi yóò dúró ni orí òkè pẹ̀lú ọ̀pá Ọlọ́run ní ọwọ́ mi.”
I řekl Mojžíš k Jozue: Vybeř nám některé muže, a vytáhna, bojuj s Amalechem; já zítra státi budu na vrchu hory, a hůl Boží v ruce své míti budu.
10 Joṣua ṣe bí Mose ti wí fún un, ó sì bá àwọn ará Amaleki jagun; nígbà tí Mose, Aaroni àti Huri lọ sí orí òkè náà.
Tedy Jozue udělal tak, jakž mu poručil Mojžíš, a bojoval s Amalechem; Mojžíš pak, Aron a Hur vstoupili na vrch hory.
11 Níwọ́n ìgbà tí Mose bá gbé apá rẹ̀ sókè, Israẹli n borí ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá sì rẹ apá rẹ̀ sílẹ̀, Amaleki a sì borí.
A dokudž Mojžíš vzhůru držel ruce své, vítězil Izrael; ale jakž opouštěl ruku svou, přemáhal Amalech.
12 Ṣùgbọ́n apá ń ro Mose, wọ́n mú òkúta, wọ́n sì fi sí abẹ́ rẹ̀, ó sì jókòó lé òkúta náà; Aaroni àti Huri sì mu ní apá rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àti èkejì ni apá òsì; apá rẹ̀ méjèèjì sì dúró gangan títí di ìgbà ti oòrùn wọ.
Ale že ruce Mojžíšovy byly obtíženy, protož vzavše kámen, podložili pod něho, a on sedl na něm; Aron pak a Hur podpírali ruce jeho, jeden z jedné, druhý z druhé strany. I byly obě ruce jeho vztažené až do západu slunce.
13 Joṣua sì fi ojú idà ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki.
A tak porazil Jozue Amalecha i lid jeho mečem.
14 Olúwa sì sọ fun Mose pé. “Kọ èyí sì inú ìwé fún ìrántí, kí o sì sọ fún Joṣua pẹ̀lú; nítorí èmi yóò pa ìrántí Amaleki run pátápátá kúrò lábẹ́ ọ̀run.”
Mluvil potom Hospodin k Mojžíšovi: Vpiš to do knih na památku, a pilně to vkládej v uši Jozue, že do konce vyhladím památku Amalechovu všudy pod nebem.
15 Mose sì tẹ́ pẹpẹ kan, ó sì sọ orúkọ pẹpẹ náà ní Olúwa ni Àsíá mi.
Tedy vzdělal Mojžíš oltář a nazval jméno jeho: Hospodin korouhev má.
16 Ó wí pé, “A gbé ọwọ́ sókè sí ìtẹ́ Olúwa. Olúwa yóò bá Amaleki jagun láti ìran dé ìran.”
Nebo řekl: Tak má jmenován býti, proto že ruka nad trůnem Hospodinovým osvědčuje boj Hospodinův proti Amalechovi od národu až do národu.

< Exodus 17 >