< Exodus 16 >

1 Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Andin Israillarning pütkül jamaiti Élimdin yolgha atlandi; Misir zéminidin chiqip, ikkinchi éyining on beshinchi künide Élim bilen Sinayning otturisidiki Sin chölige yétip keldi.
2 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
Emma Israillarning pütkül jamaiti chölde Musa bilen Harunning yaman gépini qilip ghotuldashqili turdi.
3 Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
Israillar ulargha: — Perwerdigarning qoli bizni Misir yurtidila öltürüwetken bolsa bolmasmidi! Shu yerde biz gösh qaynawatqan qazanlarni chöridep olturup, toyghudek nan yémigenmiduq? Lékin siler bu jamaetning hemmisini achliq bilen öltürmekchi bolup bizni bu chölge élip keldinglar! — déyishti.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
Buning bilen Perwerdigar Musagha: — Mana, Men asmandin silerge nan yaghdurimen; shuning bilen xelq her küni chiqip, bir künlük lazimliqini yighiwalsun. Bu teriqide Men ularning Méning qanun-emrlirimde mangidighan-mangmaydighanliqini sinaymen.
5 Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
Her heptining altinchi küni shundaq boliduki, ular yighiwalghanlirini teyyarlisun; u bashqa künlerde érishidighinidin bir hesse köp bolidu, — dédi.
6 Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
Andin Musa bilen Harun barliq Israillargha: — Bügün axsham silerni Misir zéminidin élip chiqquchining Perwerdigar ikenlikini bilisiler we
7 Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
ete siler Perwerdigarning shan-sheripini körisiler; chünki U silerning Uning yaman gépini qilip ghotuldashqininglarni anglidi; bizge kelsek, siler yaman gépimizni qilip ghotuldighudek biz kim iduq? — dédi.
8 Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
Musa yene: Perwerdigar bügün axsham silerge yégili gösh bérip, ete etigende toyghudek nan bergende [buni bilisiler]; chünki Perwerdigar siler Uning yaman gépini qilip ghotuldighininglarni anglidi. Emdi biz néme iduq? Silerning ghotuldashqininglar bizlerge qaritilghan emes, belki Perwerdigargha qaritilghandur, — dédi.
9 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
Andin Musa Harun’gha: — Sen Israillarning pütkül jamaitige: «Perwerdigarning aldigha kélinglar; chünki U yaman gep bilen ghotuldashqininglarni anglidi», dep éytqin, — dédi.
10 Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
Shundaq boldiki, Harun Israillarning pütkül jamaitige sözlep turghinida, ular chöl terepke qariwidi, mana, Perwerdigarning julasi bulutta ayan boldi.
11 Olúwa sọ fún Mose pé,
Shuning bilen Perwerdigar Musagha mundaq dédi: —
12 “Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
— Men Israillarning yaman gep qilip ghotuldashqinini anglidim; emdi ulargha: «Gugumda siler gösh yeysiler we etigende nandin toyunisiler, shuning bilen siler Méning Perwerdigar Xudayinglar ikenlikimni bilip yétisiler» — dep éytqin, dédi.
13 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
Kechqurunda shundaq boldiki, bödüniler uchup kélip, chédirgahni qaplap ketti; etisi etigende, chédirgahning etrapidiki yerlerge shebnem chüshkenidi.
14 Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
Etrapta yatqan shebnem kötürülüp ketkendin kéyin, mana, chöllükning yer yüzide qirawdek népiz, kichik-kichik yumilaq nersiler turatti.
15 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
Israillar uni körgende, uning néme ikenlikini bilmigini üchün: — Bu némidu? — dep sorashti. Musa ulargha jawaben: — Bu Perwerdigar silerge ata qilghan ozuq-tülüktur.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
Perwerdigar shu ishni emr qilip dédiki, «Herbiringlar yeydighininglargha qarap uningdin yighiwélinglar; herbiringlar ailidiki adem sanigha qarap, herbir ademge bir omer miqdarda yighinglar; her adem öz chédiridiki kishiler üchün yighinglar» — dédi.
17 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
Israillar shundaq qilip, bezisi köprek, bezisi azraq yighiwaldi.
18 Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
Ular uni omer miqdari bilen ölchiwidi, köp yighqanlarningkidin éship ketmidi, az yighqanlarningmu kemlik qilmidi; herbir kishi öz yeydighinigha qarap yighqanidi.
19 Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
Musa ulargha: — Héchqandaq adem bulardin héchnémini etige qaldurmisun, dédi.
20 Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
Shundaq bolsimu, ular Musaning sözige qulaq salmidi; beziler uningdin bir qismini etige saqlap qoydi. Emma saqlap qoyghini qurtlap sésip ketti. Bu ish üchün Musa ulargha xapa bolup achchiqlandi.
21 Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
Shu sewebtin ularning herbiri her etigini chiqip öz yeydighinigha qarap yighiwalatti; qalghanliri bolsa aptap chiqqanda érip kétetti.
22 Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
Lékin altinchi küni shundaq boldiki, ular künlük ozuqning ikki hessisini yighdi; démek, herbir kishi üchün ikki omer miqdarda yighiwaldi; andin jamaet emirliri hemmisi kélip buni Musagha éytti.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
Musa ulargha: — Mana Perwerdigarning dégini: — Ete aram küni, Perwerdigargha atalghan muqeddes shabat küni bolidu; pishuridighininglarni pishurup, qaynitidighininglarni qayinitip, éship qalghanning hemmisini etige saqlap qoyunglar, — dédi.
24 Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
Ular Musa buyrughandek, éship qalghanni etisige saqlap qoyuwidi, ular sésip qalmidi, qurutlapmu ketmidi.
25 Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
Musa ulargha: — Buni bügün yenglar; chünki bügün Perwerdigargha atalghan shabat küni bolghini üchün bügün daladin tapalmaysiler.
26 Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
Alte kün siler yighsanglar bolidu; lékin yettinchi küni shabat bolghini üchün u künide héchnéme tépilmaydu, — dédi.
27 Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
Halbuki, yettinchi küni xelqtin birnechchisi ozuq-tülük yighqili chiqiwidi, héchnéme tapalmidi.
28 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
Perwerdigar Musagha: «Siler qachan’ghiche Méning emrlirim we qanun-belgilimilirimni tutushni ret qilisiler?
29 Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
Mana, Perwerdigar silerge shabat künini békitip berdi; shunga yettinchi küni herbiringlarni öz ornida turup, sirtlargha chiqmisun dep, altinchi küni ikki künlük ozuq béridu», — dédi.
30 Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
Shuning bilen xelq yettinchi küni aram aldi.
31 Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
Israillar bu ozuqni «manna» dep atidi; uning [shekli] yumghaqsüt uruqidek, renggi aq bolup, temi heselge milen’gen qoturmachqa oxshaytti.
32 Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
Musa ulargha: — Perwerdigarning emri shuki, — Kéyinki ewladliringlargha Men silerni Misirdin élip chiqqanda, Men silerge chölde yéyishke ata qilghan nanni körsitish üchün, uningdin komzekke bir omer toshquzup, ular üchün saqlap qoyunglar, — dédi.
33 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
Musa Harun’gha: — Kelgüsi ewladliringlargha körsitishke saqlash üchün bir komzekni élip, uninggha bir omer miqdarda manna sélip, Perwerdigarning huzurida qoyup qoyghin, — dédi.
34 Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
[Kéyin, ] Harun Perwerdigar Musagha buyrughandek komzekni saqlash üchün uni höküm-guwahliq sanduqining aldida qoyup qoydi.
35 Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
Shu teriqide Israillar adem olturaqlashqan bir zémin’gha yétip kelgüche qiriq yil «manna» yédi; ular Qanaan zéminining chégralirigha yetküche manna yédi.
36 (Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)
Eyni chaghda bir «omer» «efah»ning ondin birige barawer idi.

< Exodus 16 >