< Exodus 16 >

1 Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
Eles fizeram sua viagem desde Elim, e toda a congregação dos filhos de Israel veio para o deserto de Sinai, que fica entre Elim e Sinai, no décimo quinto dia do segundo mês após sua partida da terra do Egito.
2 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
Toda a congregação dos filhos de Israel murmurou contra Moisés e contra Arão no deserto;
3 Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
e os filhos de Israel disseram-lhes: “Desejamos ter morrido pela mão de Javé na terra do Egito, quando nos sentamos junto às panelas de carne, quando comemos nossa fartura de pão, pois vocês nos trouxeram a este deserto para matar toda esta assembléia de fome”.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
Então Javé disse a Moisés: “Eis que choverei pão do céu por ti, e o povo sairá e recolherá a porção de um dia todos os dias, para que eu possa testá-los, quer andem ou não na minha lei”.
5 Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
Acontecerá no sexto dia, que prepararão o que trouxerem, e será o dobro da porção que recolherem diariamente”.
6 Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
Moisés e Arão disseram a todos os filhos de Israel: “À noite, vocês saberão que Javé os tirou da terra do Egito”.
7 Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
Pela manhã, vocês verão a glória de Iavé; porque ele ouve seus murmúrios contra Iavé. Quem somos nós, que você murmura contra nós?”.
8 Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
Moisés disse: “Agora Javé lhe dará carne para comer à noite, e de manhã pão para satisfazê-lo, porque Javé ouve suas murmurações que você murmura contra ele”. E quem somos nós? Suas murmurações não são contra nós, mas contra Yahweh”.
9 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
Moisés disse a Arão: “Diga a toda a congregação dos filhos de Israel: 'Aproximai-vos de Javé, pois ele ouviu vossas murmurações'”.
10 Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
Quando Arão falou a toda a congregação dos filhos de Israel, eles olharam para o deserto, e eis que a glória de Javé apareceu na nuvem.
11 Olúwa sọ fún Mose pé,
Javé falou a Moisés, dizendo:
12 “Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
“Ouvi os murmúrios dos filhos de Israel”. Fale com eles, dizendo: “À noite comerão carne, e de manhã se encherão de pão”. Então sabereis que eu sou Yahweh, vosso Deus””.
13 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
À noite, a codorniz surgiu e cobriu o acampamento; e pela manhã o orvalho circundava o acampamento.
14 Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
Quando o orvalho que jazia tinha desaparecido, eis que na superfície do deserto era uma pequena coisa redonda, pequena como a geada no chão.
15 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
Quando as crianças de Israel o viram, disseram umas para as outras: “O que é isso?”. Pois eles não sabiam o que era. Moisés lhes disse: “É o pão que Javé lhes deu para comer”.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
Isto é o que Javé ordenou: “Recolhei dele todos de acordo com sua alimentação; um omer uma cabeça, de acordo com o número de vossas pessoas, tomai-o, cada homem para aqueles que estão em sua tenda””.
17 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
As crianças de Israel o fizeram, e algumas se reuniram mais, outras menos.
18 Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
Quando o mediram com um gômero, aquele que muito reuniu não tinha nada, e aquele que pouco reuniu não tinha falta. Cada um deles se reunia de acordo com sua alimentação.
19 Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
Moisés disse-lhes: “Não deixem ninguém sair dele até de manhã”.
20 Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
Notwithstanding eles não deram ouvidos a Moisés, mas alguns deles saíram dele até de manhã, então ele criou minhocas e se tornou sujo; e Moisés ficou furioso com eles.
21 Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
Eles o reuniram pela manhã, todos de acordo com sua alimentação. Quando o sol ficou quente, ele derreteu.
22 Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
No sexto dia, eles juntaram o dobro do pão, dois presságios para cada um; e todos os governantes da congregação vieram e disseram a Moisés.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
Ele lhes disse: “Isto é o que Javé disse: 'Amanhã é um descanso solene, um sábado santo para Javé'”. Cozinhem o que quiserem cozinhar, e cozam o que quiserem ferver; e tudo o que sobrar, fiquem deitados para serem guardados até a manhã””.
24 Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
Eles o deitaram até a manhã, como Moisés ordenou, e não se tornou sujo, e não havia minhocas nele.
25 Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
Moisés disse: “Comam isso hoje, pois hoje é um sábado para Yahweh. Hoje você não o encontrará no campo”.
26 Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
Seis dias você o reunirá, mas no sétimo dia é o Sábado. Nele não haverá nenhum”.
27 Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
No sétimo dia, algumas das pessoas saíram para se reunir, e não encontraram nenhum.
28 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
Yahweh disse a Moisés: “Por quanto tempo você se recusa a guardar meus mandamentos e minhas leis?
29 Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
Eis que, porque Javé te deu o sábado, por isso ele te dá no sexto dia o pão de dois dias”. Todos ficam em seu lugar. Que ninguém saia de seu lugar no sétimo dia”.
30 Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
Portanto, o povo descansou no sétimo dia.
31 Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
A casa de Israel chamou seu nome de “Maná”, e era como uma semente de coentro, branca; e seu sabor era como hóstias com mel.
32 Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
Moisés disse: “Esta é a coisa que Javé ordenou: 'Que um gérmen cheio dele seja guardado através de vossas gerações, para que vejam o pão com o qual vos alimentei no deserto, quando vos tirei da terra do Egito'”.
33 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
Moisés disse a Aaron: “Pegue uma panela, e ponha nela um caramelo cheio de maná, e coloque-o diante de Yahweh, para ser guardado através de suas gerações”.
34 Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
Como Yahweh ordenou a Moisés, assim Aaron o colocou antes do Testemunho, para ser mantido.
35 Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
Os filhos de Israel comeram o maná durante quarenta anos, até chegarem a uma terra habitada. Eles comeram o maná até chegarem às fronteiras da terra de Canaã.
36 (Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)
Now um omer é um décimo de uma efa.

< Exodus 16 >