< Exodus 16 >
1 Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
És elvonultak Élimből és elérkezett Izrael fiainak egész községe Szin pusztájába, mely Élim és Szináj között van, tizenötödik napján a második hónapnak, hogy Egyiptom országából kivonultak.
2 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
És zúgolódott Izrael fiainak egész községe Mózes és Áron ellen a pusztában;
3 Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
és mondták nekik Izrael fiai: Vajha meghaltunk volna az Örökkévaló keze által Egyiptom országában, midőn ültünk a húsos fazék mellett, midőn ehettünk kenyeret a jóllakásig; mert ti kihoztatok bennünket a pusztába, hogy megöljétek ezt az egész gyülekezetet éhség által.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
És mondta az Örökkévaló Mózesnek: Íme, én hullatok nektek kenyeret az égből; menjen ki a nép és szedje a napravalót a maga napján, hogy megkísértsem, vajon jár-e tanom értelmében, vagy sem?
5 Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
És lesz a hetedik napon, akkor készítsék el amit bevisznek és lesz kétszerese annak, amit naponként szednek.
6 Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
És mondta Mózes meg Áron Izrael minden fiainak: Este majd megtudjátok, hogy az Örökkévaló vezetett ki benneteket Egyiptom országából;
7 Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
reggel pedig majd látjátok az Örökkévaló dicsőségét, mivelhogy meghallotta zúgolódásotokat az Örökkévaló ellen; mi pedig mik vagyunk, hogy ellenünk zúgolódtok?
8 Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
És mondta Mózes: Azáltal, hogy ad az Örökkévaló nektek este húst, hogy egyetek és kenyeret reggel, hogy jóllakjatok; mivelhogy hallotta az Örökkévaló zúgolódásotokat, mellyel zúgolódtok ellene, mi pedig, mik vagyunk? Nem ellenünk van a ti zúgolódásotok, hanem az Örökkévaló ellen.
9 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
És mondta Mózes Áronnak: Mondd Izrael fiai egész községének: Lépjetek oda az Örökkévaló színe elé, mert meghallotta zúgolódásotokat.
10 Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
És volt, midőn, Áron szólt Izrael fiai egész községéhez, a puszta felé fordultak; és íme, az Örökkévaló dicsősége megjelent a felhőben.
És szólt az Örökkévaló Mózeshez, mondván:
12 “Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Hallottam Izrael fiai zúgolódását; szólj hozzájuk, mondván: Estefelé esztek majd húst és reggel jóllaktok majd kenyérrel, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló, a ti Istenetek.
13 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
És volt este, fölszállt a fürj és elborította a tábort; reggel pedig volt harmatréteg a tábor körül.
14 Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
Midőn fölszállt a harmatréteg, íme, a puszta színén valami apró szemcsés, apró, mint a dér a földön.
15 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
Midőn látták Izrael fiai, mondták egymásnak: Mi ez? Mert nem tudták, hogy mi az. És mondta nekik Mózes: Ez a kenyér, melyet az Örökkévaló adott nektek eledelül.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
Ez az a dolog, amit parancsolt az Örökkévaló: Szedjetek belőle, kiki étke szerint, egy ómert fejenként, lelkeitek száma szerint, kiki a sátrában levők számára vegyetek.
17 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
És így cselekedtek Izrael fiai és szedtek, ki többet, ki kevesebbet.
18 Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
És megmérték az ómerrel és nem volt fölöslege annak, ki többet szedett, aki pedig kevesebbet szedett, annak nem volt fogyatkozása; kiki az ő étke szerint szedett.
19 Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
És mondta nekik Mózes: Senki se hagyjon meg belőle reggelig.
20 Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
De nem hallgattak Mózesre és meghagytak némelyek belőle reggelig, de megférgesedett és megbűzhödött; és haragudott rájuk Mózes,
21 Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
Így szedték azt minden reggel, kiki az ő étke szerint; midőn pedig melegen sütött a nap, elolvadt.
22 Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
És volt a hatodik napon, szedtek kétszeres kenyeret, két ómert egynek; és eljöttek a község minden fejedelmei és tudtára adták Mózesnek.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
És ő mondta nekik: Ez az, amit szólt az Örökkévaló: Nyugalom, szent szombat lesz az Örökkévalónak holnap; amit sütni akartok, süssétek meg és amit főzni akartok, főzzétek meg, az egész fölösleget pedig tegyétek el magatoknak megőrzésre, reggelre.
24 Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
És eltették azt reggelre, amint parancsolta Mózes és nem bűzhödött meg és féreg sem volt benne.
25 Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
És mondta Mózes: Egyétek meg ma, mert szombat van ma az Örökkévalónak; ma nem találjátok azt a mezőn.
26 Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
Hat napon át szedjétek azt, de a hetedik napon szombat van; nem lesz azon.
27 Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
És volt a hetedik napon, kimentek a nép közül, hogy szedjenek, de nem találtak.
28 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
És mondta az Örökkévaló Mózesnek: Meddig vonakodtok még megőrizni parancsolataimat és tanaimat!
29 Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
Lássátok, hogy az Örökkévaló adta nektek a szombatot, azért ad nektek a hetedik napon két napi kenyeret; maradjatok kiki a helyén, ne menjen ki senki az ő helyéből a hetedik napon.
30 Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
És nyugodott a nép a hetedik napon.
31 Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
És elnevezte Izrael háza mannának; az pedig olyan volt, mint a koriandrum magva, fehér és íze olyan, mint a mézeskalácsé.
32 Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
És mondta Mózes: Ez a dolog, amit parancsolt az Örökkévaló: Egy tele ómerrel legyen belőle megőrzésre nemzedékeiteknek, hogy lássák a kenyeret, melyet enni adtam nektek a pusztában, midőn kivezetlek benneteket Egyiptom országából.
33 Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
És mondta Mózes Áronnak: Vegyél egy palackot és tegyél bele egy tele ómerrel mannát, és tedd azt az Örökkévaló színe elé megőrzésre nemzedékeiteknek.
34 Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
Amint megparancsolta az Örökkévaló Mózesnek, odatette Áron a bizonyság elé megőrzésre.
35 Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
Izrael fiai pedig ették a mannát negyven évig, amíg elérkeztek lakott földre; a mannát ették, amíg elérkeztek Kanaán országának határára.
36 (Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)
Az ómer pedig egy tized éfó volt.