< Exodus 15 >

1 Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa, Èmi yóò kọrin sí Olúwa, nítorí òun pọ̀ ní ògo. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún ni ó ti sọ sínú Òkun.
Atunci Moise și copiii lui Israel au cântat această cântare DOMNULUI și au spus, zicând: Voi cânta DOMNULUI, pentru că a triumfat glorios; calul și călărețul lui i-a aruncat în mare.
2 Olúwa ni agbára àti orin mi; òun ti di Olùgbàlà mi, òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín, Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.
DOMNUL este tăria și cântarea mea și el a devenit salvarea mea; el este Dumnezeul meu și îi voi pregăti o locuință; Dumnezeul tatălui meu și îl voi înălța.
3 Ológun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,
DOMNUL este un bărbat de război; DOMNUL este numele său.
4 kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀ ni ó mú wọ inú Òkun. Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáfáfá jùlọ ni ó rì sínú Òkun Pupa.
Carele lui Faraon și oștirea lui le-a aruncat în mare; aleșii lui căpetenii de asemenea sunt înecați în Marea Roșie.
5 Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀; wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
Adâncurile i-au acoperit; s-au scufundat în adâncuri ca o piatră.
6 “Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, pọ̀ ní agbára. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, fọ́ àwọn ọ̀tá túútúú.
Dreapta ta, DOAMNE, a devenit glorioasă în putere; dreapta ta, DOAMNE, a zdrobit în bucăți dușmanul.
7 “Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi ìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú. Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ; tí ó run wọ́n bí àgémọ́lẹ̀ ìdí koríko.
Și în măreția maiestății tale ai doborât pe cei ce s-au ridicat împotriva ta; ai trimis înainte furia ta, care i-a mistuit ca pe miriște.
8 Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ń wọ́jọ pọ̀. Ìṣàn omi dìde dúró bí odi; ibú omi sì dìpọ̀ láàrín Òkun.
Și cu pufnirea suflării nărilor tale apele s-au adunat, potopurile au stat drept ca o movilă și adâncurile s-au închegat în inima mării.
9 Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé, ‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn. èmi ó pín ìkógun; èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn. Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
Dușmanul a spus: Voi urmări, voi ajunge, voi împărți prada; îmi voi sătura pofta cu ei; îmi voi trage sabia, mâna mea îi va nimici.
10 Ìwọ fẹ́ èémí rẹ, òkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n rì bí òjé ni àárín omi ńlá.
Tu ai suflat cu suflarea ta, marea i-a acoperit; s-au scufundat ca plumb în apele puternice.
11 Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa? Ta ló dàbí rẹ: ní títóbi, ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìn, tí ń ṣe ohun ìyanu?
Cine este asemenea ție, DOAMNE, printre dumnezei? Cine este asemenea ție, glorios în sfințenie, înspăimântător în laude, făcând minuni?
12 “Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ, ilẹ̀ si gbé wọn mì.
Tu ai întins mâna ta dreaptă, pământul i-a înghițit.
13 Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn náà tí Ìwọ ti rà padà. Nínú agbára rẹ Ìwọ yóò tọ́ wọn, lọ sí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
În mila ta ai condus poporul pe care l-ai răscumpărat; i-ai călăuzit în puterea ta la sfânta ta locuință.
14 Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì. Ìkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn Filistia.
Poporul va auzi și se va înspăimânta; întristare îi va apuca pe locuitorii Palestinei.
15 Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu, àwọn olórí Moabu yóò wárìrì. Àwọn ènìyàn Kenaani yóò sì yọ́ dànù.
Atunci conducătorii Edomului vor fi uimiți; bărbații tari ai Moabului, tremurând îi vor apuca; toți locuitorii din Canaan se vor topi.
16 Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí nína títóbi apá rẹ̀ wọn yóò dúró jẹ́ẹ́ láì mira bí i òkúta, títí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi rékọjá, Olúwa, títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi rékọjá.
Spaimă și groază va cădea asupra lor; prin măreția brațului tău vor fi muți ca o piatră, până când trece poporul tău, DOAMNE, până când trece poporul, pe care tu l-ai cumpărat.
17 Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n ni orí òkè ti ìwọ jogún, ní ibi ti ìwọ ṣe fún ara rẹ, Olúwa. Láti máa gbé ibi mímọ́ ti ìwọ fi ọwọ́ rẹ gbé kalẹ̀, Olúwa.
Tu îi vei aduce înăuntru și îi vei sădi în muntele moștenirii tale, în locul, DOAMNE, pe care l-ai făcut pentru tine pentru a locui în el, în Sanctuar, DOAMNE, pe care mâinile tale l-au întemeiat.
18 “Olúwa yóò jẹ ọba láé àti láéláé.”
DOMNUL va domni pentru totdeauna și întotdeauna.
19 Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.
Căci calul lui Faraon a intrat cu carele lui și cu călăreții lui în mare și DOMNUL a adus înapoi apele mării peste ei; dar copiii lui Israel au mers pe pământ uscat în mijlocul mării.
20 Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.
Și Miriam, profetesa, sora lui Aaron, a luat o tamburină în mâna ei; și toate femeile au ieșit după ea cu tamburine și cu dansuri.
21 Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé, “Ẹ kọrin sí Olúwa, nítorí òun ni ológo jùlọ. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún, ni òun bi ṣubú sínú Òkun.”
Și Miriam le-a răspuns: Cântați DOMNULUI, pentru că el a triumfat glorios; calul și călărețul lui i-a aruncat în mare.
22 Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.
Astfel Moise a adus pe Israel de la Marea Roșie și au ieșit în pustia Șur; și au mers trei zile în pustie și nu au găsit apă.
23 Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)
Și când au ajuns la Mara, nu puteau bea din apele din Mara, fiindcă erau amare; de aceea i s-a pus numele Mara.
24 Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”
Și poporul a cârtit împotriva lui Moise, spunând: Ce vom bea?
25 Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn. Níbẹ̀ ni Olúwa ti gbé ìlànà àti òfin kalẹ̀ fún wọn, níbẹ̀ ni ó sì ti dán wọn wò.
Și el a strigat către DOMNUL; și DOMNUL i-a arătat un pom, pe care, când l-a aruncat în ape, apele s-au făcut dulci; acolo le-a făcut un statut și o rânduială și acolo i-a încercat,
26 Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”
Și a spus: Dacă vei da ascultare cu toată atenția la vocea DOMNULUI Dumnezeul tău și vei face ceea ce este drept înaintea ochilor lui și vei deschide urechea la poruncile lui și vei ține toate statutele lui, nu voi pune peste tine niciuna din aceste boli pe care le-am adus peste egipteni; căci eu sunt DOMNUL care te vindecă.
27 Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.
Și au ajuns la Elim, unde erau douăsprezece fântâni de apă și șaptezeci de palmieri; și au așezat tabăra acolo lângă ape.

< Exodus 15 >