< Exodus 15 >

1 Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa, Èmi yóò kọrin sí Olúwa, nítorí òun pọ̀ ní ògo. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún ni ó ti sọ sínú Òkun.
Thanne Moises song, and the sones of Israel, this song to the Lord; and thei seiden, Synge we to the Lord, for he is magnefied gloriousli; he castide doun the hors and the stiere in to the see.
2 Olúwa ni agbára àti orin mi; òun ti di Olùgbàlà mi, òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín, Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.
My strengthe and my preisyng is the Lord; and he is maad to me in to heelthe. This is my God, and Y schal glorifie hym; the God of my fadir, and Y schal enhaunse hym.
3 Ológun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,
The Lord is as a man fiyter, his name is Almiyti;
4 kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀ ni ó mú wọ inú Òkun. Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáfáfá jùlọ ni ó rì sínú Òkun Pupa.
he castide doun in to the see the charis of Farao, and his oost. Hise chosun princis weren drenchid in the reed see;
5 Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀; wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
the depe watris hiliden hem; thei yeden doun in to the depthe as a stoon.
6 “Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, pọ̀ ní agbára. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, fọ́ àwọn ọ̀tá túútúú.
Lord, thi riythond is magnyfied in strengthe; Lord, thi riythond smoot the enemye.
7 “Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi ìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú. Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ; tí ó run wọ́n bí àgémọ́lẹ̀ ìdí koríko.
And in the mychilnesse of thi glorie thou hast put doun alle myn aduersaries; thou sentist thin ire, that deuouride hem as stobil.
8 Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ń wọ́jọ pọ̀. Ìṣàn omi dìde dúró bí odi; ibú omi sì dìpọ̀ láàrín Òkun.
And watris weren gaderid in the spirit of thi woodnesse; flowinge watir stood, depe watris weren gaderid in the middis of the see.
9 Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé, ‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn. èmi ó pín ìkógun; èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn. Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
The enemy seide, Y schal pursue, and Y schal take; Y schal departe spuylis, my soule schal be fillid. I schal drawe out my swerde; myn hond schal sle hem.
10 Ìwọ fẹ́ èémí rẹ, òkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n rì bí òjé ni àárín omi ńlá.
Thi spirit blew, and the see hilide hem; thei weren drenchid as leed in grete watris.
11 Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa? Ta ló dàbí rẹ: ní títóbi, ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìn, tí ń ṣe ohun ìyanu?
Lord, who is lijk thee in stronge men, who is lijk thee? thou art greet doere in hoolynesse; ferdful, and preisable, and doynge myraclis.
12 “Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ, ilẹ̀ si gbé wọn mì.
Thou heldist forth thin hond, and the erthe deuouride hem;
13 Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn náà tí Ìwọ ti rà padà. Nínú agbára rẹ Ìwọ yóò tọ́ wọn, lọ sí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
thou were ledere in thi merci to thy puple, which thou ayen bouytist; and thou hast bore hym in thi strengthe to thin holi dwellyng place.
14 Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì. Ìkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn Filistia.
Puplis stieden, and weren wroothe; sorewis helden the dwelleris of Filistiym.
15 Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu, àwọn olórí Moabu yóò wárìrì. Àwọn ènìyàn Kenaani yóò sì yọ́ dànù.
Thanne the pryncis of Edom weren disturblid; tremblyng held the stronge men of Moab.
16 Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí nína títóbi apá rẹ̀ wọn yóò dúró jẹ́ẹ́ láì mira bí i òkúta, títí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi rékọjá, Olúwa, títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi rékọjá.
Alle the dwelleris of Canaan `weren starke; inward drede falle on hem, and outward drede in the greetnesse of thin arm. Be thei maad vnmouable as a stoon, til thi puple passe, Lord; til this thi puple passe, whom thou weldidist.
17 Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n ni orí òkè ti ìwọ jogún, ní ibi ti ìwọ ṣe fún ara rẹ, Olúwa. Láti máa gbé ibi mímọ́ ti ìwọ fi ọwọ́ rẹ gbé kalẹ̀, Olúwa.
Thou schalt brynge hem in, and thou schalt plaunte in the hil of thin eritage; in the moost stidefast dwellyng place which thou hast wrouyt, Lord; Lord, thi seyntuarie, which thin hondis made stidefast.
18 “Olúwa yóò jẹ ọba láé àti láéláé.”
The Lord schal `regne in to the world and ferthere.
19 Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.
Forsothe Farao, `a ridere, entride with his charis and knyytis in to the see, and the Lord brouyte the watris of the se on hem; sotheli the sones of Israel yeden bi the drie place, in the myddis of the see.
20 Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.
Therfore Marie, profetesse, the `sistir of Aaron, took a tympan in hir hond, and alle the wymmen yeden out aftir hyr with tympans and cumpanyes;
21 Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé, “Ẹ kọrin sí Olúwa, nítorí òun ni ológo jùlọ. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún, ni òun bi ṣubú sínú Òkun.”
to whiche sche song bifore, and seide, Synge we to the Lord, for he is magnyfied gloriousli; he castide doun in to the see the hors and the stiere of hym.
22 Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.
Forsothe Moises took Israel fro the reed see, and thei yeden out in to the deseert of Sur, and thei yeden thre daies bi the wildirnesse, and thei founden not watir.
23 Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)
And thei camen in to Marath, and thei miyten not drynk the watris of Marath, for tho weren bittere; wherfor and he puttide a couenable name to the place, and clepide it Mara, that is, bitternesse.
24 Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”
And the puple grutchide ayens Moises, and seide, What schulen we drynke?
25 Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn. Níbẹ̀ ni Olúwa ti gbé ìlànà àti òfin kalẹ̀ fún wọn, níbẹ̀ ni ó sì ti dán wọn wò.
And Moises criede to the Lord, which schewide to hym a tre; and whanne he hadde put that tre in to watris, tho weren turned in to swetnesse. There the Lord ordeynede comaundementis and domes to the puple, and there he asayede the puple,
26 Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”
and seide, If thou schalt here the vois of thi Lord God, and schalt do that that is riytful byfore hym, and schalt obeie to his comaundementis, and schalt kepe alle hise heestis, Y schal not brynge yn on thee al the syknesse, which Y puttide in Egipt, for Y am thi Lord Sauyour.
27 Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.
Forsothe the sones of Israel camen in to Helym, where weren twelue wellis of watris, and seuenti palm trees, and thei settiden tentis bisidis the watris.

< Exodus 15 >