< Exodus 15 >
1 Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa, Èmi yóò kọrin sí Olúwa, nítorí òun pọ̀ ní ògo. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún ni ó ti sọ sínú Òkun.
Then Moses [Drawn out] and the children of Israel [God prevails] sang this song to Adonai, and said, “I will sing to Adonai, for he has triumphed gloriously. The horse and his rider he has thrown into the sea.
2 Olúwa ni agbára àti orin mi; òun ti di Olùgbàlà mi, òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín, Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.
Yah is my strength and song. He has become my yishu'ah ·salvation·. This is my God, and I will praise him; my father’s God, and I will exalt him.
3 Ológun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,
Adonai is a man of war. Yahweh [He sustains breathing] is his name.
4 kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀ ni ó mú wọ inú Òkun. Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáfáfá jùlọ ni ó rì sínú Òkun Pupa.
He has cast Pharaoh’s chariots and his army into the sea. His chosen captains are sunk in the Sea of Suf [Reed Sea].
5 Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀; wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
The deeps cover them. They went down into the depths like a stone.
6 “Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, pọ̀ ní agbára. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, fọ́ àwọn ọ̀tá túútúú.
Your right hand, Adonai, is glorious in power. Your right hand, Adonai, dashes the enemy in pieces.
7 “Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi ìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú. Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ; tí ó run wọ́n bí àgémọ́lẹ̀ ìdí koríko.
In the greatness of your excellency, you overthrow those who rise up against you. You send out your wrath. It consumes them as stubble.
8 Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ń wọ́jọ pọ̀. Ìṣàn omi dìde dúró bí odi; ibú omi sì dìpọ̀ láàrín Òkun.
With the blast of your nostrils, the waters piled up! The floods stood upright as a heap. The deeps were congealed in the heart of the sea.
9 Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé, ‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn. èmi ó pín ìkógun; èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn. Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
The enemy said, ‘I will pursue. I will overtake. I will divide the plunder. My desire shall be satisfied on them. I will draw my sword, my hand shall destroy them.’
10 Ìwọ fẹ́ èémí rẹ, òkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n rì bí òjé ni àárín omi ńlá.
You blew with your wind. The sea covered them. They sank like lead in the mighty waters.
11 Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa? Ta ló dàbí rẹ: ní títóbi, ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìn, tí ń ṣe ohun ìyanu?
Who is like you, Adonai, among the deities? Who is like you, glorious in holiness, fearful in tehilah ·praise song·, doing wonders?
12 “Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ, ilẹ̀ si gbé wọn mì.
You stretched out your right hand. The earth swallowed them.
13 Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn náà tí Ìwọ ti rà padà. Nínú agbára rẹ Ìwọ yóò tọ́ wọn, lọ sí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
“You, in your chesed ·loving-kindness·, have led the people that you have redeemed. You have guided them in your strength to your holy habitation.
14 Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì. Ìkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn Filistia.
The peoples have sh'ma ·heard obeyed·. They tremble. Pangs have taken hold on the inhabitants of Philistia.
15 Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu, àwọn olórí Moabu yóò wárìrì. Àwọn ènìyàn Kenaani yóò sì yọ́ dànù.
Then the chiefs of Edom [Red] were dismayed. Trembling takes hold of the mighty men of Moab [From father]. All the inhabitants of Canaan [Humbled] have melted away.
16 Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí nína títóbi apá rẹ̀ wọn yóò dúró jẹ́ẹ́ láì mira bí i òkúta, títí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi rékọjá, Olúwa, títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi rékọjá.
Terror and dread falls on them. By the greatness of your arm they are as still as a stone— until your people pass over, Adonai, until the people pass over who you have purchased.
17 Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n ni orí òkè ti ìwọ jogún, ní ibi ti ìwọ ṣe fún ara rẹ, Olúwa. Láti máa gbé ibi mímọ́ ti ìwọ fi ọwọ́ rẹ gbé kalẹ̀, Olúwa.
You shall bring them in, and plant them in the mountain of your inheritance, the place, Adonai, which you have made for yourself to dwell in; the sanctuary, Lord, which your hands have established.
18 “Olúwa yóò jẹ ọba láé àti láéláé.”
Adonai shall reign forever and ever.”
19 Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.
For the horses of Pharaoh went in with his chariots and with his horsemen into the sea, and Adonai brought back the waters of the sea on them; but the children of Israel [God prevails] walked on dry land in the middle of the sea.
20 Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.
Miriam [Rebellion] the prophetess, the sister of Aaron [Light-bringer], took a tambourine in her hand; and all the women went out after her with tambourines and with dances.
21 Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé, “Ẹ kọrin sí Olúwa, nítorí òun ni ológo jùlọ. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún, ni òun bi ṣubú sínú Òkun.”
Miriam [Rebellion] answered them, “Sing to Adonai, for he has triumphed. The horse and his rider he has thrown into the sea.”
22 Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.
Moses [Drawn out] led Israel [God prevails] onward from the Sea of Suf [Reed Sea], and they went out into the wilderness of Shur; and they went three days in the wilderness, and found no water.
23 Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)
When they came to Marah [Bitter], they couldn’t drink from the waters of Marah [Bitter], for they were bitter. Therefore its name was called Marah [Bitter].
24 Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”
The people murmured against Moses [Drawn out], saying, “What shall we drink?”
25 Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn. Níbẹ̀ ni Olúwa ti gbé ìlànà àti òfin kalẹ̀ fún wọn, níbẹ̀ ni ó sì ti dán wọn wò.
Then he cried to Adonai. Adonai showed him a tree, and he threw it into the waters, and the waters were made sweet. There he made a statute and a judgement for them, and there he tested them;
26 Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”
and he said, “If you will sh'ma ·hear obey· sh'ma ·hear obey· Adonai your God’s voice, and will do that which is right in his eyes, and will pay attention to his mitzvot ·instructions·, and keep all his statutes, I will put none of the diseases on you, which I have put on the Egyptians [people from Abode of slavery]; for I am I am Yahweh Rafa' [Yahweh your Physician, Yahweh your Healer].”
27 Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.
They came to Elim, where there were twelve springs of water, and seventy palm trees: and they encamped there by the waters.