< Exodus 14 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn padà sẹ́yìn, kí wọ́n sì pàgọ́ sí tòsí Pi-Hahirotu láàrín Migdoli òun Òkun, kí wọn kí ó pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun, ní òdìkejì Baali-Ṣefoni.
Parle aux enfants d'Israël, pour qu'ils fassent demi-tour et campent devant Pihahiroth, entre Migdol et la mer, devant Baal Zephon. Vous camperez en face d'elle, près de la mer.
3 Farao yóò ronú pé àwọn ọmọ Israẹli ń ráre káàkiri ní ìdààmú ni àti wí pé aginjù náà ti sé wọn mọ́.
Pharaon dira des enfants d'Israël: « Ils sont empêtrés dans le pays. Le désert les a enfermés.
4 Èmi yóò sé ọkàn Farao le ti yóò fi lépa wọn. Ṣùgbọ́n èmi yóò gba ògo fún ará mi láti ìpàṣẹ Farao àti ogun rẹ̀, àti pé àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.” Àwọn Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀.
J'endurcirai le cœur de Pharaon, et il les suivra; je m'assurerai la gloire sur Pharaon et sur toutes ses armées, et les Égyptiens sauront que je suis Yahvé. » C'est ce qu'ils firent.
5 Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba Ejibiti pé àwọn ènìyàn náà ti sálọ, ọkàn Farao àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yí padà sí àwọn ènìyàn, wọ́n sì wí pé, “Kí ni ohun tí àwa ṣe yìí? Àwa ti jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, a sì ti pàdánù ìsìnrú wọn.”
On apprit au roi d'Égypte que le peuple s'était enfui; le cœur de Pharaon et de ses serviteurs fut changé à l'égard du peuple, et ils dirent: « Qu'avons-nous donc fait, pour laisser Israël s'enfuir loin de nous? »
6 Ó sì di kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀, ó sì kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀,
Il prépara son char et prit avec lui son armée;
7 ó mú ẹgbẹ̀ta ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ tí ó jáfáfá jùlọ àti gbogbo ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ mìíràn ní Ejibiti, olórí sì wà fún olúkúlùkù wọn.
il prit six cents chars d'élite et tous les chars d'Égypte, avec des chefs sur chacun d'eux.
8 Olúwa sé ọkàn Farao ọba Ejibiti le, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lépa àwọn ọmọ Israẹli ti ń jáde lọ ní àìbẹ̀rù.
Yahvé endurcit le cœur de Pharaon, roi d'Égypte, et il poursuivit les enfants d'Israël, car les enfants d'Israël sortaient avec une main levée.
9 Àwọn ará Ejibiti ń lépa wọn pẹ̀lú gbogbo ẹṣin kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, wọ́n sì lé wọn bá ni ibi tí wọ́n pa àgọ́ sí lẹ́bàá òkun ní ìhà Pi-Hahirotu, ni òdìkejì Baali-Ṣefoni.
Les Égyptiens les poursuivirent. Tous les chevaux et les chars de Pharaon, ses cavaliers et son armée les rattrapèrent en campant près de la mer, à côté de Pihahiroth, devant Baal Zephon.
10 Bí Farao ti súnmọ́ tòsí ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọmọ Israẹli gbé ojú wọn sókè, wọn sì rí àwọn ará Ejibiti tó súnmọ́ wọn. Ẹ̀rù ńlá sì bá àwọn ará Israẹli, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa.
Lorsque Pharaon s'approcha, les enfants d'Israël levèrent les yeux, et voici que les Égyptiens marchaient à leur poursuite; ils eurent très peur. Les enfants d'Israël crièrent à Yahvé.
11 Wọ́n sọ fún Mose pé, “Ṣe nítorí pé kò sí ibojì ni Ejibiti ní ìwọ ṣe mú wa wá láti kú sínú aginjù? Kí ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa ti ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti wá?
Ils dirent à Moïse: « Parce qu'il n'y avait pas de tombeaux en Égypte, nous as-tu emmenés mourir dans le désert? Pourquoi nous as-tu traités de la sorte, pour nous faire sortir d'Égypte?
12 Ǹjẹ́ èyí kọ́ ni àwa sọ fún ọ ni Ejibiti, ‘Fi wá sílẹ̀, jẹ́ kí àwa máa sin ará Ejibiti’? Nítorí kò bá sàn fún wa kí a sin àwọn ará Ejibiti ju kí a kú sínú aginjù yìí lọ!”
N'est-ce pas là la parole que nous t'avons adressée en Égypte, en te disant: « Laisse-nous tranquilles, pour que nous servions les Égyptiens »? Car il aurait mieux valu pour nous servir les Égyptiens que de mourir dans le désert. »
13 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ṣinṣin kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
Moïse dit au peuple: « N'ayez pas peur. Restez immobiles et voyez le salut de l'Éternel, qu'il va opérer pour vous aujourd'hui, car vous ne verrez plus jamais les Égyptiens que vous avez vus aujourd'hui.
14 Olúwa yóò jà fún un yín; kí ẹ̀yin kí ó sá à mu sùúrù.”
L'Éternel combattra pour vous, et vous resterez tranquilles. »
15 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń ké pè mí? Sọ fún àwọn ará Israẹli kí wọn máa tẹ̀síwájú.
Yahvé dit à Moïse: « Pourquoi cries-tu vers moi? Parle aux enfants d'Israël, pour qu'ils avancent.
16 Ṣùgbọ́n, gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè, kí o sì na ọwọ́ rẹ sí orí omi Òkun, kí ó lè pín ní yà kí àwọn ọmọ Israẹli lè la òkun kọjá ni orí ìyàngbẹ ilẹ̀.
Lève ta verge, étends ta main sur la mer et divise-la. Les enfants d'Israël entreront à sec au milieu de la mer.
17 Nígbà náà ni èmi yóò sé ọkàn àwọn ará Ejibiti le, wọn yóò sì máa lépa wọn; Èmi yóò gba ògo fún ara mi lórí Farao; lórí gbogbo ogun rẹ̀, lórí kẹ̀kẹ́ ogun àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Voici, je vais moi-même endurcir le cœur des Égyptiens, et ils entreront après eux. Je me rendrai maître de Pharaon et de toutes ses armées, de ses chars et de ses cavaliers.
18 Àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Farao: lórí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.”
Les Égyptiens sauront que je suis Yahvé, quand je me serai acquis la gloire sur Pharaon, sur ses chars et sur ses cavaliers. »
19 Nígbà náà ni angẹli Ọlọ́run tó ti ń ṣáájú ogun Israẹli lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.
L'ange de Dieu, qui marchait devant le camp d'Israël, se déplaça et alla derrière eux; et la colonne de nuée se déplaça de devant eux, et se tint derrière eux.
20 Ó sì wà láàrín àwọn ọmọ-ogun Ejibiti àti Israẹli. Ìkùùkuu sì ṣú òkùnkùn sí àwọn ará Ejibiti ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Israẹli ni òru náà, ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.
Elle se plaça entre le camp d'Égypte et le camp d'Israël. Il y avait la nuée et les ténèbres, et pourtant elle donnait de la lumière pendant la nuit. L'un ne s'approchait pas de l'autre de toute la nuit.
21 Nígbà náà ni Mose na ọwọ́ rẹ̀ sí orí Òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,
Moïse étendit sa main sur la mer, et Yahvé fit reculer la mer par un fort vent d'est toute la nuit; il mit la mer à sec, et les eaux se partagèrent.
22 àwọn ọmọ Israẹli sì la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.
Les enfants d'Israël entrèrent au milieu de la mer à sec, et les eaux formaient pour eux une muraille à droite et à gauche.
23 Àwọn ará Ejibiti sì ń lépa wọn, gbogbo ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.
Les Égyptiens les poursuivirent et entrèrent après eux au milieu de la mer: tous les chevaux de Pharaon, ses chars et ses cavaliers.
24 Ní ìṣọ́ òwúrọ̀ Olúwa bojú wo ogun àwọn ará Ejibiti láàrín ọ̀wọ̀n iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ-ogun Ejibiti.
A la veille du matin, Yahvé regarda l'armée égyptienne à travers la colonne de feu et de nuée, et il confondit l'armée égyptienne.
25 Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́ ogun náà rìn. Àwọn ará Ejibiti wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àsálà kúrò ní iwájú àwọn ará Israẹli nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”
Il enleva les roues de leurs chars et les fit rouler lourdement, si bien que les Égyptiens dirent: « Fuyons devant Israël, car Yahvé combat pour eux contre les Égyptiens! ».
26 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Ejibiti, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́ṣin wọn.”
Yahvé dit à Moïse: « Étends ta main sur la mer, afin que les eaux reviennent sur les Égyptiens, sur leurs chars et sur leurs cavaliers. »
27 Mose sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ilẹ̀ mọ́. Àwọn ará Ejibiti ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.
Moïse étendit sa main sur la mer, et la mer reprit sa force à l'apparition du matin; les Égyptiens s'enfuirent devant elle. Yahvé renversa les Égyptiens au milieu de la mer.
28 Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin: àní, gbogbo ọmọ-ogun Farao tiwọn wọ inú òkun tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó yè.
Les eaux revinrent et couvrirent les chars et les cavaliers, toute l'armée de Pharaon qui entra après eux dans la mer. Il n'en resta pas un seul.
29 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.
Mais les enfants d'Israël marchaient à sec au milieu de la mer, et les eaux leur servaient de muraille à droite et à gauche.
30 Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Israẹli là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti; Israẹli sì rí òkú àwọn ará Ejibiti ni etí òkun.
Ce jour-là, Yahvé sauva Israël de la main des Égyptiens, et Israël vit les Égyptiens morts au bord de la mer.
31 Nígbà ti àwọn ọmọ Israẹli rí iṣẹ́ ìyanu ńlá ti Olúwa ṣe fún wọn lára àwọn ará Ejibiti, àwọn ènìyàn bẹ̀rù Olúwa, wọ́n sì gba Olúwa àti Mose ìránṣẹ́ rẹ gbọ́.
Israël vit la grande œuvre que Yahvé avait faite aux Égyptiens, et le peuple craignit Yahvé; et ils crurent en Yahvé et en son serviteur Moïse.

< Exodus 14 >