< Exodus 14 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Forsothe the Lord spak to Moises, and seide, Speke thou to the sones of Israel;
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn padà sẹ́yìn, kí wọ́n sì pàgọ́ sí tòsí Pi-Hahirotu láàrín Migdoli òun Òkun, kí wọn kí ó pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun, ní òdìkejì Baali-Ṣefoni.
turne thei ayen, and sette thei tentis euene ayens Fiayroth, which is bitwixe Magdalum and the see, ayens Beelsefon; in the siyt therof ye schulen sette tentis ouer the see.
3 Farao yóò ronú pé àwọn ọmọ Israẹli ń ráre káàkiri ní ìdààmú ni àti wí pé aginjù náà ti sé wọn mọ́.
And Farao schal seie on the sones of Israel, Thei ben maad streit in the lond, the deseert hath closid hem to gidere.
4 Èmi yóò sé ọkàn Farao le ti yóò fi lépa wọn. Ṣùgbọ́n èmi yóò gba ògo fún ará mi láti ìpàṣẹ Farao àti ogun rẹ̀, àti pé àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.” Àwọn Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀.
And Y schal make hard his herte, and he schal pursue you, and Y schal be glorified in Farao, and in al his oost; and Egipcians schulen wite that Y am the Lord; and thei diden so.
5 Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba Ejibiti pé àwọn ènìyàn náà ti sálọ, ọkàn Farao àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yí padà sí àwọn ènìyàn, wọ́n sì wí pé, “Kí ni ohun tí àwa ṣe yìí? Àwa ti jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, a sì ti pàdánù ìsìnrú wọn.”
And it was teld to the kyng of Egipcians, that the puple hadde fled; and the herte of Farao and of hise seruauntis was chaungid on the puple, and thei seiden, What wolden we do, that we leften Israel, that it schulde not serue us?
6 Ó sì di kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀, ó sì kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀,
Therfor Farao ioynede the chare, and took with him al his puple;
7 ó mú ẹgbẹ̀ta ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ tí ó jáfáfá jùlọ àti gbogbo ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ mìíràn ní Ejibiti, olórí sì wà fún olúkúlùkù wọn.
and he took sixe hundrid chosyn charis, and what euer thing of charis was in Egipt, and duykis of al the oost.
8 Olúwa sé ọkàn Farao ọba Ejibiti le, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lépa àwọn ọmọ Israẹli ti ń jáde lọ ní àìbẹ̀rù.
And the Lord made hard `the herte of Farao, kyng of Egipt, and he pursuede the sones of Israel; and thei weren go out in an hiy hond.
9 Àwọn ará Ejibiti ń lépa wọn pẹ̀lú gbogbo ẹṣin kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, wọ́n sì lé wọn bá ni ibi tí wọ́n pa àgọ́ sí lẹ́bàá òkun ní ìhà Pi-Hahirotu, ni òdìkejì Baali-Ṣefoni.
And whanne Egipcians pursueden the steppis of the sones of Israel bifor goynge, thei founden hem in tentis on the see; al the chyualrye and charis of Farao, and al the oost weren in Fiayroth, ayens Beelsefon.
10 Bí Farao ti súnmọ́ tòsí ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọmọ Israẹli gbé ojú wọn sókè, wọn sì rí àwọn ará Ejibiti tó súnmọ́ wọn. Ẹ̀rù ńlá sì bá àwọn ará Israẹli, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa.
And whanne Farao hadde neiyed the sones of Israel, reisiden her iyen, and thei sien Egipcians bihynde hem, and dredden greetli; and thei crieden to the Lord,
11 Wọ́n sọ fún Mose pé, “Ṣe nítorí pé kò sí ibojì ni Ejibiti ní ìwọ ṣe mú wa wá láti kú sínú aginjù? Kí ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa ti ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti wá?
and seiden to Moises, In hap sepulcris weren not in Egipt, therfor thou hast take vs awei, that we schulen die in wildirnesse? what woldist thou do this, that thou leddist vs out of Egipt?
12 Ǹjẹ́ èyí kọ́ ni àwa sọ fún ọ ni Ejibiti, ‘Fi wá sílẹ̀, jẹ́ kí àwa máa sin ará Ejibiti’? Nítorí kò bá sàn fún wa kí a sin àwọn ará Ejibiti ju kí a kú sínú aginjù yìí lọ!”
Whether this is not the word which we spaken to thee in Egipt, `and seiden, Go awei fro vs, that we serue Egipcians? for it is myche betere to serue hem, than to die in wildirnesse.
13 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ṣinṣin kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
And Moises seide to the puple, Nyle ye drede, stonde ye, and `se ye the grete werkys of God, whiche he schal do to dai; for ye schulen no more se Egipcians, whiche ye seen now, til in to with outen ende;
14 Olúwa yóò jà fún un yín; kí ẹ̀yin kí ó sá à mu sùúrù.”
the Lord schal fiyte for you, and ye schulen be stille.
15 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń ké pè mí? Sọ fún àwọn ará Israẹli kí wọn máa tẹ̀síwájú.
And the Lord seide to Moises, What criest thou to me? Speke thou to the sones of Israel, that thei go forth; forsothe reise thou thi yerde,
16 Ṣùgbọ́n, gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè, kí o sì na ọwọ́ rẹ sí orí omi Òkun, kí ó lè pín ní yà kí àwọn ọmọ Israẹli lè la òkun kọjá ni orí ìyàngbẹ ilẹ̀.
and stretche forth thin hond on the see, and departe thou it, that the sones of Israel go in the myddis of the see, by drie place.
17 Nígbà náà ni èmi yóò sé ọkàn àwọn ará Ejibiti le, wọn yóò sì máa lépa wọn; Èmi yóò gba ògo fún ara mi lórí Farao; lórí gbogbo ogun rẹ̀, lórí kẹ̀kẹ́ ogun àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Forsothe Y schal make hard the herte of Egipcians, that thei pursue you, and Y schal be glorified in Farao, and in al the oost of hym, and in the charis, and in the knyytis of hym;
18 Àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Farao: lórí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.”
and Egipcians schulen wite that Y am the Lord God, whanne Y schal be glorified in Farao, and in the charis, and in the knyytis of hym.
19 Nígbà náà ni angẹli Ọlọ́run tó ti ń ṣáájú ogun Israẹli lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.
And the aungel of the Lord, that yede bifore the castellis of Israel, took hym silf, and yede bihynde hem; and the piler of cloude yede to gidir with hym, and lefte the formere thingis aftir the bak,
20 Ó sì wà láàrín àwọn ọmọ-ogun Ejibiti àti Israẹli. Ìkùùkuu sì ṣú òkùnkùn sí àwọn ará Ejibiti ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Israẹli ni òru náà, ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.
and stood bitwixe the `castels of Egipcians and castels of Israel; and the cloude was derk toward Egipcians, and liytnynge `the nyyt toward `the children of Israel, so that in al the tyme of the niyt thei miyten not neiy togidere to hem silf.
21 Nígbà náà ni Mose na ọwọ́ rẹ̀ sí orí Òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,
And whanne Moises hadde stretchid forth the hond on the see, the Lord took it awei, the while a greet wynde and brennynge blew in al the niyt, and turnede in to dryenesse; and the watir was departid.
22 àwọn ọmọ Israẹli sì la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.
And the sones of Israel entriden by the myddis of the drye see; for the watir was as a wal at the riyt side and left side of hem.
23 Àwọn ará Ejibiti sì ń lépa wọn, gbogbo ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.
And Egipcians pursueden, and entriden aftir hem, al the ridyng of Farao, hise charis, and knyytis, bi the myddis of the see.
24 Ní ìṣọ́ òwúrọ̀ Olúwa bojú wo ogun àwọn ará Ejibiti láàrín ọ̀wọ̀n iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ-ogun Ejibiti.
And the wakyng of the morewtid cam thanne, and lo! the Lord bihelde on the castels of Egipcians, bi a piler of fier, and of cloude, and killide the oost of hem; and he destriede the wheelis of charis,
25 Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́ ogun náà rìn. Àwọn ará Ejibiti wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àsálà kúrò ní iwájú àwọn ará Israẹli nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”
and tho weren borun in to the depthe. Therfor Egipcians seiden, Fle we Israel; for the Lord fiytith for hem ayenus vs.
26 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Ejibiti, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́ṣin wọn.”
And the Lord seide to Moises, Holde forth thin hond on the see, that the watris turne ayen to Egipcians, on the charis, and knyytis of hem.
27 Mose sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ilẹ̀ mọ́. Àwọn ará Ejibiti ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.
And whanne Moises hadde hold forth the hoond ayens the see, it turnede ayen first in the morewtid to the formere place; and whanne Egipcians fledden, the watris camen ayen, and the Lord wlappide hem in the myddis of the floodis.
28 Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin: àní, gbogbo ọmọ-ogun Farao tiwọn wọ inú òkun tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó yè.
And the watris turneden ayen, and hiliden the charis, and knyytis of al the oost of Farao, which sueden, and entriden in to the see; sotheli not oon of hem was alyue.
29 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.
Forsothe the sones of Israel yeden thorouy the myddis of the drye see, and the watris weren to hem as for a wal, on the riyt side and left side.
30 Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Israẹli là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti; Israẹli sì rí òkú àwọn ará Ejibiti ni etí òkun.
And in that dai the Lord delyuerede Israel fro the hond of Egipcians, and thei sien Egipcians deed on the brynke of the see,
31 Nígbà ti àwọn ọmọ Israẹli rí iṣẹ́ ìyanu ńlá ti Olúwa ṣe fún wọn lára àwọn ará Ejibiti, àwọn ènìyàn bẹ̀rù Olúwa, wọ́n sì gba Olúwa àti Mose ìránṣẹ́ rẹ gbọ́.
and thei seiyen the greet hond which the Lord hadde vsid ayens hem; and the puple dredde the Lord, and thei bileueden to the Lord, and to Moises his seruaunt.

< Exodus 14 >