< Exodus 14 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya;
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn padà sẹ́yìn, kí wọ́n sì pàgọ́ sí tòsí Pi-Hahirotu láàrín Migdoli òun Òkun, kí wọn kí ó pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun, ní òdìkejì Baali-Ṣefoni.
“Nyis jo-Israel oduogi mondo gibuor machiegni gi Pi Hahiroth mantie e kind Migdol gi nam. Gibiro bworo machiegni gi nam, mochomore gi Baal Zefon.
3 Farao yóò ronú pé àwọn ọmọ Israẹli ń ráre káàkiri ní ìdààmú ni àti wí pé aginjù náà ti sé wọn mọ́.
Farao biro paro kowacho ni, ‘Jo-Israel digni e piny korwenyo e thim.’
4 Èmi yóò sé ọkàn Farao le ti yóò fi lépa wọn. Ṣùgbọ́n èmi yóò gba ògo fún ará mi láti ìpàṣẹ Farao àti ogun rẹ̀, àti pé àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.” Àwọn Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Abiro miyo chuny Farao bedo mapek, mi owuogi kolawo jo-Israel. To abiro yudo duongʼ ne an awuon kuom Farao kaachiel gi jolwenje duto, eka jo-Misri nongʼe ni an Jehova Nyasaye.” Eka jo-Israel notimo kamano.
5 Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba Ejibiti pé àwọn ènìyàn náà ti sálọ, ọkàn Farao àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yí padà sí àwọn ènìyàn, wọ́n sì wí pé, “Kí ni ohun tí àwa ṣe yìí? Àwa ti jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, a sì ti pàdánù ìsìnrú wọn.”
Kane onyis ruodh Misri ni jogo osedhi, Farao gi jodonge noloko pachgi kuom jo-Israel mi giwacho niya, “Angʼo ma wasetimoni? Waseweyo jo-Israel odhi kendo tije ma yande gitiyonwa orumo!”
6 Ó sì di kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀, ó sì kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀,
Eka ne oikne geche mar jolweny, bangʼe nokawo jolweny mage.
7 ó mú ẹgbẹ̀ta ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ tí ó jáfáfá jùlọ àti gbogbo ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ mìíràn ní Ejibiti, olórí sì wà fún olúkúlùkù wọn.
Nokawo geche mia auchiel mabeyo mag lweny, kod geche mamoko mag jo-Misri ka moro ka moro nigi jatend lweny.
8 Olúwa sé ọkàn Farao ọba Ejibiti le, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lépa àwọn ọmọ Israẹli ti ń jáde lọ ní àìbẹ̀rù.
Jehova Nyasaye nomiyo chuny Farao ma ruodh Misri odoko matek, mi nolawo jo-Israel mane wuotho ka gin gi chir.
9 Àwọn ará Ejibiti ń lépa wọn pẹ̀lú gbogbo ẹṣin kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, wọ́n sì lé wọn bá ni ibi tí wọ́n pa àgọ́ sí lẹ́bàá òkun ní ìhà Pi-Hahirotu, ni òdìkejì Baali-Ṣefoni.
Jo-Misri kod farese Farao gi gechegi, gi joidh farese kod jolweny nolawo jo-Israel mi gijukogi ka gibworo e bath nam machiegni gi Pi Hahiroth mochomore gi Baal Zefon.
10 Bí Farao ti súnmọ́ tòsí ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọmọ Israẹli gbé ojú wọn sókè, wọn sì rí àwọn ará Ejibiti tó súnmọ́ wọn. Ẹ̀rù ńlá sì bá àwọn ará Israẹli, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa.
Kane Farao ochopo machiegni kodgi, jo-Israel notingʼo wangʼ-gi mi gineno ka jo-Misri lawogi. Luoro nomakogi mi giywakne Jehova Nyasaye.
11 Wọ́n sọ fún Mose pé, “Ṣe nítorí pé kò sí ibojì ni Ejibiti ní ìwọ ṣe mú wa wá láti kú sínú aginjù? Kí ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa ti ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti wá?
Negiwacho ni Musa niya, “Ne onge kuonde yiko mane inyalo yikwae e piny Misri momiyo ikelowa e thim ka mondo wathoe? En angʼo ma isetimonwani kuom golowa e piny Misri?
12 Ǹjẹ́ èyí kọ́ ni àwa sọ fún ọ ni Ejibiti, ‘Fi wá sílẹ̀, jẹ́ kí àwa máa sin ará Ejibiti’? Nítorí kò bá sàn fún wa kí a sin àwọn ará Ejibiti ju kí a kú sínú aginjù yìí lọ!”
Donge ne wanyisi e piny Misri ni, ‘Wewa, mondo watine jo-Misri?’ Dine bernwa tiyo ni jo-Misri moloyo tho e thim!”
13 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ṣinṣin kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
Musa nodwoko ogandano niya, “Kik ubed maluor. Chungʼuru motegno eka ubiro neno resruok ma Jehova Nyasaye biro kelonu kawuono. Jo-Misri ma uneno kawuononi ok unuchak une kendo.
14 Olúwa yóò jà fún un yín; kí ẹ̀yin kí ó sá à mu sùúrù.”
Jehova Nyasaye biro kedonu; owinjore ubed gi kwe.”
15 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń ké pè mí? Sọ fún àwọn ará Israẹli kí wọn máa tẹ̀síwájú.
Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Angʼo momiyo uywakna? Nyis jo-Israel mondo odhi nyime giwuoth.
16 Ṣùgbọ́n, gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè, kí o sì na ọwọ́ rẹ sí orí omi Òkun, kí ó lè pín ní yà kí àwọn ọmọ Israẹli lè la òkun kọjá ni orí ìyàngbẹ ilẹ̀.
Tingʼ ludhi malo kendo irie badi ewi nam mondo ipog pige eka jo-Israel ongʼad nam kawuotho e lowo motwo.
17 Nígbà náà ni èmi yóò sé ọkàn àwọn ará Ejibiti le, wọn yóò sì máa lépa wọn; Èmi yóò gba ògo fún ara mi lórí Farao; lórí gbogbo ogun rẹ̀, lórí kẹ̀kẹ́ ogun àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Abiro keto chuny jo-Misri doko matek mondo gilaw bangʼ-gi nyaka ei nam. Kendo abiro yudo duongʼ kuom Farao kaachiel gi jolweny gi geche lwenje kod joidh faresene.
18 Àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Farao: lórí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.”
Jo-Misri biro ngʼeyo ni an Jehova Nyasaye ka ayudo duongʼ kuom Farao gi gechene kod joidh faresene.”
19 Nígbà náà ni angẹli Ọlọ́run tó ti ń ṣáájú ogun Israẹli lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.
Eka Malaika mar Nyasaye, mane osebedo kotelo e nyim jolwenj jo-Israel, nodok chien bangʼ jo-Israel. Bor polo bende ne osudo machiegni e nyim jo-Israel mi odok ka ngʼegi,
20 Ó sì wà láàrín àwọn ọmọ-ogun Ejibiti àti Israẹli. Ìkùùkuu sì ṣú òkùnkùn sí àwọn ará Ejibiti ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Israẹli ni òru náà, ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.
ka ochungʼ e kind jolwenj jo-Misri kod jo-Israel. Otienono duto bor polono nokelo mudho ne konchiel to komachielo nokelo ler; omiyo onge oganda mane osudo machiegni gi machielo otienono duto.
21 Nígbà náà ni Mose na ọwọ́ rẹ̀ sí orí Òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,
Eka Musa norieyo bade ewi nam, kendo otienono duto Jehova Nyasaye notugo yamo ma aa yo wuok chiengʼ mopogo pi nyadiriyo mi kanyo olokore lowo motwo. Pige nopogore,
22 àwọn ọmọ Israẹli sì la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.
kendo jo-Israel nongʼado nam kawuotho e lowo motwo, ka pi ogingore e bathgi korachwich gi koracham.
23 Àwọn ará Ejibiti sì ń lépa wọn, gbogbo ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.
Jo-Misri nolawogi kendo farese Farao duto gi gechene kaachiel gi joidh gechene nolawogi nyaka ei nam.
24 Ní ìṣọ́ òwúrọ̀ Olúwa bojú wo ogun àwọn ará Ejibiti láàrín ọ̀wọ̀n iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ-ogun Ejibiti.
Kane piny dwaro yawore Jehova Nyasaye nonenogi gie ligek mach, mine omiyo jolwenj jo-Misri odigni.
25 Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́ ogun náà rìn. Àwọn ará Ejibiti wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àsálà kúrò ní iwájú àwọn ará Israẹli nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”
Nomiyo tiende gechegi owuok mine ok ginyal riembogi. Eka jo-Misri nowacho niya, “Waringuru waa kuom jo-Israel! Jehova Nyasaye ema kedonegi kod jo-Misri.”
26 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Ejibiti, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́ṣin wọn.”
Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Rie badi e nam mondo pi oum jo-Misri gi gechegi kod joidh faresegi.”
27 Mose sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ilẹ̀ mọ́. Àwọn ará Ejibiti ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.
Musa norieyo bade e nam kendo ka piny ne oyawore, to nonwangʼo ka pi osedok e wangʼe. Jo-Misri ne ringo kochomo dier nam, kendo Jehova Nyasaye noywerogi gi pi nyaka ei namno.
28 Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin: àní, gbogbo ọmọ-ogun Farao tiwọn wọ inú òkun tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó yè.
Pi nogingore kadok kare kendo noimo geche gi joidh farese gi jolweny Farao duto mane olawo jo-Israel nyaka e nam. Onge kata achiel kuomgi mane otony.
29 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.
Jo-Israel to nongʼado nam kawuotho e lowo motwo, ka pi ogingore e bathgi korachwich gi koracham.
30 Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Israẹli là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti; Israẹli sì rí òkú àwọn ará Ejibiti ni etí òkun.
Chiengʼno Jehova Nyasaye noreso Israel e lwet jo-Misri, kendo Israel noneno ka jo-Misri otho e dho nam.
31 Nígbà ti àwọn ọmọ Israẹli rí iṣẹ́ ìyanu ńlá ti Olúwa ṣe fún wọn lára àwọn ará Ejibiti, àwọn ènìyàn bẹ̀rù Olúwa, wọ́n sì gba Olúwa àti Mose ìránṣẹ́ rẹ gbọ́.
Bangʼ ka jo-Israel noseneno teko maduongʼ mane Jehova Nyasaye onyiso kokedo gi jo-Misri, oganda noluoro Jehova Nyasaye kendo negiketo genogi kuome kaachiel gi kuom Musa jatichne.

< Exodus 14 >