< Exodus 13 >
RAB Musa'ya, “Bütün ilk doğanları bana adayın” dedi, “İsrailliler arasında insan olsun, hayvan olsun her rahmin ilk ürünü bana aittir.”
2 “Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
3 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
Musa halka, “Mısır'dan, köle olduğunuz ülkeden çıktığınız bugünü anımsayın” dedi, “Çünkü RAB güçlü eliyle sizi oradan çıkardı. Mayalı hiçbir şey yenmeyecek.
4 Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
Bugün Aviv ayında buradan ayrılıyorsunuz.
5 Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
RAB sizi Kenan, Hitit, Amor, Hiv ve Yevus topraklarına, atalarınıza vereceğine ant içtiği süt ve bal akan ülkeye götürdüğü zaman bu ay şu törelere uyacaksınız:
6 Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
Yedi gün mayasız ekmek yiyecek, yedinci gün RAB'be bayram yapacaksınız.
7 Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
O yedi gün içinde yalnız mayasız ekmek yiyeceksiniz. Aranızda ve ülkenizin hiçbir yerinde mayalı bir şey görülmeyecek.
8 Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
O gün oğullarınıza, ‘Mısır'dan çıktığımızda RAB'bin bizim için yaptıklarından dolayı bunları yapıyoruz’ diye anlatacaksınız.
9 Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
Bu elinizde bir belirti ve alnınızda bir anma işareti olacak; öyle ki, RAB'bin yasası hep ağzınızda olsun. Çünkü RAB güçlü eliyle sizi Mısır'dan çıkardı.
10 Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
Siz de her yıl belirlenen tarihte bu kuralı uygulamalısınız.
11 “Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
“RAB size ve atalarınıza ant içerek söz verdiği gibi sizi Kenan topraklarına getirecektir. Orayı size verdiği zaman,
12 ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
ilk doğan erkek çocuklarınızın ve hayvanlarınızın hepsini RAB'be adayacaksınız. Çünkü bunlar RAB'be aittir.
13 Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
İlk doğan her sıpanın bedelini bir kuzuyla ödeyin. Bedelini ödemezseniz, boynunu kırın. Bütün ilk doğan erkek çocuklarınızın bedelini ödemelisiniz.
14 “Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
“İlerde oğullarınız size, ‘Bunun anlamı ne?’ diye sorduklarında, ‘RAB bizi güçlü eliyle Mısır'dan, köle olduğumuz ülkeden çıkardı’ diye yanıtlarsınız,
15 Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
‘Firavun bizi salıvermemekte diretince, RAB Mısır'da insanların ve hayvanların bütün ilk doğanlarını öldürdü. İşte bunun için hayvanların ilk doğan erkek yavrularını RAB'be kurban ediyoruz. İlk doğan erkek çocuklarımızın bedelini ise bir hayvanla ödüyoruz.’
16 Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
Bu uygulama elinizde bir belirti ve alnınızda bir anma işareti olacak; RAB'bin bizi Mısır'dan güçlü eliyle çıkardığını anımsatacak.”
17 Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
Firavun İsrailliler'i salıverdiğinde, Filist yöresi yakın olmasına karşın, Tanrı onları oradan götürmedi. Çünkü, “Halk savaşla karşılaşınca, düşüncelerini değiştirip Mısır'a geri dönebilir” diye düşündü.
18 Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
Halkı çöl yolundan Kamış Denizi'ne doğru dolaştırdı. İsrailliler Mısır'dan silahlı çıkmışlardı.
19 Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
Musa Yusuf'un kemiklerini yanına almıştı. Çünkü Yusuf İsrail'in oğullarına, “Tanrı kesinlikle size yardım edecek, kemiklerimi buradan götüreceksiniz” diye sıkı sıkı ant içirmişti.
20 Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
Sukkot'tan ayrılıp çöl kenarında, Etam'da konakladılar.
21 Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
Gece gündüz ilerlemeleri için, RAB gündüzün bir bulut sütunu içinde yol göstererek, geceleyin bir ateş sütunu içinde ışık vererek onlara öncülük ediyordu.
22 Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.
Gündüz bulut sütunu, gece ateş sütunu halkın önünden eksik olmadı.