< Exodus 13 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
2 “Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
« Sanctifie-moi tout premier-né, tout ce qui ouvre le ventre des enfants d'Israël, tant des hommes que des animaux. Il est à moi. »
3 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
Moïse dit au peuple: « Souvenez-vous de ce jour où vous êtes sortis d'Égypte, de la maison de servitude, car c'est par la force de sa main que Yahvé vous a fait sortir de ce lieu. On ne mangera pas de pain levé.
4 Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
Aujourd'hui, vous sortez au mois d'Abib.
5 Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
Lorsque Yahvé vous fera entrer dans le pays des Cananéens, des Héthiens, des Amoréens, des Héviens et des Jébusiens, qu'il a juré à vos pères de vous donner, un pays où coulent le lait et le miel, vous célébrerez cet office pendant ce mois.
6 Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
Pendant sept jours, vous mangerez des pains sans levain, et le septième jour, vous ferez une fête en l'honneur de l'Éternel.
7 Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
On mangera des pains sans levain pendant les sept jours; on ne verra pas avec vous de pain levé. On ne verra pas de levure avec vous, dans tout votre territoire.
8 Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
En ce jour-là, tu diras à ton fils: « C'est à cause de ce que Yahvé a fait pour moi, quand je suis sorti d'Égypte ».
9 Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
Ce sera pour toi un signe sur ta main et un souvenir entre tes yeux, afin que la loi de l'Éternel soit dans ta bouche; car c'est d'une main forte que l'Éternel t'a fait sortir d'Égypte.
10 Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
Tu observeras donc cette ordonnance en son temps, d'année en année.
11 “Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
« Lorsque Yahvé vous fera entrer dans le pays des Cananéens, comme il l'a juré à vous et à vos pères, et qu'il vous le donnera,
12 ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
vous réserverez à Yahvé tout ce qui ouvre le ventre et tout premier-né d'un animal que vous avez. Les mâles appartiendront à Yahvé.
13 Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
Tout premier-né d'un âne, tu le rachèteras avec un agneau; si tu ne le rachètes pas, tu lui briseras le cou; et tu rachèteras tous les premiers-nés de l'homme parmi tes fils.
14 “Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
Lorsque ton fils te demandera un jour: « Qu'est-ce que cela? », tu lui diras: « C'est par la force de sa main que Yahvé nous a fait sortir d'Égypte, de la maison de servitude.
15 Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
Lorsque Pharaon s'est obstiné à ne pas nous laisser partir, Yahvé a tué tous les premiers-nés du pays d'Égypte, aussi bien les premiers-nés des hommes que ceux du bétail. C'est pourquoi je sacrifie à Yahvé tout ce qui ouvre les entrailles, c'est-à-dire les mâles; mais je rachète tous les premiers-nés de mes fils'.
16 Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
Ce sera un signe sur ta main et des symboles entre tes yeux, car c'est par la force de la main que Yahvé nous a fait sortir d'Égypte. »
17 Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
Lorsque Pharaon eut laissé partir le peuple, Dieu ne le conduisit pas par le chemin du pays des Philistins, qui était pourtant tout proche, car Dieu dit: « De peur que le peuple ne change d'avis en voyant la guerre, et qu'il ne retourne en Égypte »;
18 Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
mais Dieu conduisit le peuple par le chemin du désert, près de la mer Rouge; et les enfants d'Israël montèrent armés hors du pays d'Égypte.
19 Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
Moïse prit avec lui les ossements de Joseph, car il avait fait jurer les enfants d'Israël en disant: « Dieu vous visitera et vous emporterez avec vous mes ossements loin d'ici. »
20 Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
Ils partirent de Succoth et campèrent à Étham, à l'extrémité du désert.
21 Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
L'Éternel marchait devant eux, le jour dans une colonne de nuée, pour les conduire sur leur chemin, et la nuit dans une colonne de feu, pour les éclairer, afin qu'ils pussent marcher de jour et de nuit.
22 Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.
La colonne de nuée, le jour, et la colonne de feu, la nuit, ne s'écartaient pas de devant le peuple.

< Exodus 13 >