< Exodus 13 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Also the Lord spak to Moises, and seide,
2 “Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
Halewe thou to me ech firste gendrid thing that openeth the wombe among the sones of Israel, as wel of men as of beestis, for whi alle ben myn.
3 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
And Moises seide to the puple, Haue ye mynde of this dai, in which ye yeden out of Egipt, and of the hows of seruage, for in strong hond the Lord ledde you out of this place, that ye ete not breed diyt with sour dow.
4 Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
To dai ye gon out, in the monethe of new fruytis;
5 Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
and whanne the Lord hath led thee in to the lond of Cananey, and of Ethei, and of Amorrei, and of Euei, and of Jebusei, which lond he swoor to thi fadris, that he schulde yyue to thee, a lond flowynge with mylk and hony, thou schalt halowe this custom of holy thingis in this monethe.
6 Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
In seuene daies thou schalt ete therf looues, and the solempnete of the Lord schal be in the seuenthe dai;
7 Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
ye schulen ete therf looues seuene daies, no thing diyt with sour dow schal appere at thee, nether in alle thi coostis.
8 Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
And thou schalt telle to thi sone in that dai, and schalt seie, This it is that the Lord dide to me, whanne Y yede out of Egipt.
9 Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
And it schal be as a signe in thin hond, and as a memorial before thin iyen, and that the lawe of the Lord be euere in thi mouth; for in a strong hond the Lord ledde thee out of Egipt, and of the hows of seruage.
10 Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
Thou schalt kepe siche a worschipyng in tyme ordeined, `fro daies in to daies.
11 “Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
And whanne the Lord hath brouyt thee in to the lond of Cananey, as he swoor to thee, and to thi fadris, and hath youe it to thee,
12 ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
thou schalt departe to the Lord al the thing that openeth the wombe, and that that is the firste in thi beestis; what euer thing thou hast of male kynde, thou schalt halewe to the Lord.
13 Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
Thou schalt chaunge the firste gendrid of an asse for a scheep, that if thou ayen biest not, thou schalt sle; forsothe thou schalt ayen bie with prijs al the firste gendrid of man of thi sones.
14 “Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
And whanne thi sone schal axe thee to morewe, and seie, What is this? thou schalt answere to hym, In a strong hond the Lord ladde vs out of the lond of Egipt, of the hows of seruage; for whanne Farao was maad hard,
15 Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
and nolde delyuere vs, the Lord killide alle the firste gendrid thing in the lond of Egipt, fro the firste gendrid of man til to the firste gendrid of beestis; therfor Y offre to the Lord al thing of male kynde that openeth the wombe, and Y ayen bie alle the firste gendrid thingis of my sones.
16 Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
Therfor it schal be as a signe in thin hond, and as a thing hangid for mynde bifore thin iyen, for in a strong hond the Lord ledde vs out of Egipt.
17 Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
Therfor whanne Farao hadde sent out the puple, God ledde not hem out bi the weie of `the lond of Filisteis, which is niy; and arettid lest perauenture it wolde repente the puple, if he had seyn batelis rise ayens hym, and `the puple wolde turn ayen in to Egipt;
18 Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
but God ledde aboute by the weie of deseert, which weie is bisidis the reed see. And the sones of Israel weren armed, and stieden fro the lond of Egipte.
19 Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
And Moises took the boonus of Joseph with hym, for he hadde chargid the sones of Israel, and hadde seid, God schal visite you, and bere ye out `fro hennus my boonus with you.
20 Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
And thei yeden forth fro Socoth, and settiden tentis in Etham, in the laste endis of wildirnesse.
21 Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
Forsothe the Lord yede bifore hem to schewe the weie, bi dai in a piler of clowde, and bi nyyt in a piler of fier, that he schulde be ledere of the weie in euer either time;
22 Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.
the piler of clowde failide neuere bi dai, nether the piler of fier bi niyt, bifor the puple.

< Exodus 13 >