< Exodus 13 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Og HERREN talede til Moses og sagde:
2 “Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
"Du skal hellige mig alt det førstefødte, alt, hvad der åbner Moders Liv hos Israeliterne både af Mennesker og Kvæg; det skal tilhøre mig!"
3 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
Og Moses sagde til Folket: "Kom denne Dag i Hu, på hvilken I vandrer ud af Ægypten, af Trællehuset, thi med stærk Hånd førte HERREN eder ud derfra! Og der må ikke spises syret Brød.
4 Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
I Dag vandrer I ud, i Abib Måned.
5 Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
Når nu HERREN fører dig til Kana'anæernes, Hetiternes, Amoriternes, Hivviternes og Jebusiternes Land, som han tilsvor dine Fædre at ville give dig, et Land, der flyder med Mælk og Honning, så skal du overholde denne Skik i denne Måned.
6 Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
I syv Dage skal du spise usyret Brød, og på den syvende Dag skal der være Højtid for HERREN.
7 Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
I disse syv Dage skal der spises usyret Brød, og der må hverken findes syret Brød eller Surdejg hos dig nogetsteds inden dine Landemærker.
8 Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
Og du skal på den Dag fortælle din Søn, at dette sker i Anledning af, hvad HERREN gjorde for dig, da du vandrede ud af Ægypten!
9 Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
Det skal være dig som et Tegn på din Hånd og et Erindringsmærke på din Pande, for at HERRENs Lov må være i din Mund, thi med stærk Hånd førte HERREN dig ud af Ægypten.
10 Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
Og du skal holde dig denne Anordning efterrettelig til den fastsatte Tid, År efter År.
11 “Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
Og når HERREN fører dig til Kana'anæernes Land, således som han tilsvor dig og dine Fædre, og giver dig det,
12 ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
da skal du overlade HERREN alt, hvad der åbner Moders Liv; alt det førstefødte, som falder efter dit Kvæg, for så vidt det er et Handyr, skal tilhøre HERREN.
13 Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
Men alt det førstefødte af Æslerne skal du udløse med et Stykke Småkvæg, og hvis du ikke udløser det, skal du sønderbryde dets Hals; og alt det førstefødte af Mennesker blandt dine Sønner skal du udløse.
14 “Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
Og når din Søn i Fremtiden spørger dig: Hvad betyder dette? skal du svare ham: Med stærk Hånd førte HERREN os ud af Ægypten, af Trællehuset;
15 Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
og fordi Farao gjorde sig hård og ikke vilde lade os drage bort, ihjelslog HERREN alt det førstefødte i Ægypten både af Folk og Fæ; derfor ofrer vi HERREN alt, hvad der åbner Moders Liv, for så vidt det er et Handyr, og alt det førstefødte blandt vore Sønner udløser vi!
16 Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
Og det skal være dig som et Tegn på din Hånd og et Erindringsmærke på din Pande, thi med stærk Hånd førte HERREN os ud af Ægypten."
17 Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
Da Farao lod Folket drage bort, førte Gud dem ikke ad Vejen til Filisterlandet, som havde været den nærmeste, thi Gud sagde: "Folket kunde komme til at fortryde det, når de ser, der bliver Krig, og vende tilbage til Ægypten."
18 Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
Men Gud lod Folket gøre en Omvej til Ørkenen i Retning af det røde Hav. Israeliterne drog nu væbnede ud af Ægypten.
19 Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
Og Moses tog Josefs Ben med sig, thi denne havde taget Israels Sønner i Ed og sagt: "Når Gud ser til eder, skal I føre mine Ben med eder herfra!"
20 Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
De brød op fra Sukkot og lejrede sig i Etam ved Randen af Ørkenen.
21 Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
Men HERREN vandrede foran dem, om dagen i en Skystøtte for at vise dem Vej og om Natten i en Ildstøtte for at lyse for dem; så kunde de rejse både Dag og Nat.
22 Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.
Og Skystøtten veg ikke fra Folket om Dagen, ej heller Ildstøtten om Natten.

< Exodus 13 >