< Exodus 12 >
1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
I reèe Gospod Mojsiju i Aronu u zemlji Misirskoj govoreæi:
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
Ovaj mjesec da vam je poèetak mjesecima, da vam je prvi mjesec u godini.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Kažite svemu zboru Izrailjevu i recite: desetoga dana ovoga mjeseca svaki neka uzme jagnje ili jare, po porodicama, po jedno na dom;
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
Ako li je dom mali za jagnje ili jare, neka uzme k sebi susjeda, koji mu je najbliži, s onoliko duša koliko treba da mogu pojesti jagnje ili jare.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
A jagnje ili jare da vam bude zdravo, muško, od godine; izmeðu ovaca ili izmeðu koza uzmite.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
I èuvajte ga do èetrnaestoga dana ovoga mjeseca, a tada savkoliki zbor Izrailjev neka ga zakolje uveèe.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
I neka uzmu krvi od njega i pokrope oba dovratka i gornji prag na kuæama u kojima æe ga jesti.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
I neka jedu meso iste noæi, na vatri peèeno, s hljebom prijesnijem i sa zeljem gorkim neka jedu.
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
Nemojte jesti sirovo ni u vodi kuhano, nego na vatri peèeno, s glavom i s nogama i s drobom.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
I ništa nemojte ostaviti do jutra; ako li bi što ostalo do jutra, spalite na vatri.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
A ovako jedite: opasani, obuæa da vam je na nogu i štap u ruci, i jedite hitno, jer je prolazak Gospodnji.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
Jer æu proæi po zemlji Misirskoj tu noæ, i pobiæu sve prvence u zemlji Misirskoj od èovjeka do živinèeta, i sudiæu svijem bogovima Misirskim, ja Gospod.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
A krv ona biæe vam znak na kuæama, u kojima æete biti; i kad vidim krv, proæi æu vas, te neæe biti meðu vama pomora, kad stanem ubijati po zemlji Misirskoj.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
I taj æe vam dan biti za spomen, i praznovaæete ga Gospodu od koljena do koljena; praznujte ga zakonom vjeènijem.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
Sedam dana jedite hljebove prijesne, i prvoga dana uklonite kvasac iz kuæa svojih; jer ko bi god jeo što s kvascem od prvoga dana do sedmoga, istrijebiæe se ona duša iz Izrailja.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
Prvi dan biæe sveti sabor; tako i sedmi dan imaæete sveti sabor; nikakav posao da se ne radi u te dane, osim što treba za jelo svakoj duši, to æete samo gotoviti.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
I držite dan prijesnijeh hljebova, jer u taj dan izvedoh vojske vaše iz zemlje Misirske; držite taj dan od koljena do koljena zakonom vjeènijem.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
Prvoga mjeseca èetrnaesti dan uveèe poènite jesti prijesne hljebove pa do dvadeset prvoga dana istoga mjeseca uveèe.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Za sedam dana da se ne naðe kvasca u kuæama vašim; jer ko bi god jeo što s kvascem, istrijebiæe se ona duša iz zbora Izrailjeva, bio došljak ili roðen u zemlji.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Ništa s kvascem nemojte jesti, nego jedite hljeb prijesan po svijem stanovima svojim.
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
I sazva Mojsije sve starješine Izrailjske, i reèe im: izberite i uzmite sebi jagnje ili jare po porodicama svojim, i zakoljite pashu.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
I uzmite kitu isopa i zamoèite je u krv, koja æe biti u zdjeli, i pokropite gornji prag i oba dovratka krvlju, koja æe biti u zdjeli, i nijedan od vas da ne izlazi na vrata kuæna do jutra.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
Jer æe zaæi Gospod da bije Misir, pa kad vidi krv na gornjem pragu i na oba dovratka, proæi æe Gospod mimo ona vrata, i neæe dati krvniku da uðe u kuæe vaše da ubija.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
I držite ovo kao zakon tebi i sinovima tvojim dovijeka.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
I kad doðete u zemlju koju æe vam dati Gospod, kao što je kazao, držite ovu službu.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
I kad vam reku sinovi vaši: kakva vam je to služba?
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
Recite: ovo je žrtva za prolazak Gospodnji, kad proðe kuæe sinova Izrailjevih u Misiru ubijajuæi Misirce, a domove naše saèuva. Tada narod savi glavu i pokloni se.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
I otidoše i uèiniše sinovi Izrailjevi, kako zapovjedi Gospod preko Mojsija i Arona, tako uèiniše.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
A oko ponoæi pobi Gospod sve prvence u zemlji Misirskoj od prvenca Faraonova koji šæaše sjedjeti na prijestolu njegovu do prvenca sužnja u tamnici, i što god bješe prvenac od stoke.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
Tada usta Faraon one noæi, on i sve sluge njegove i svi Misirci, i bi vika velika u Misiru, jer ne bješe kuæe u kojoj ne bi mrtvaca.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
I dozva Mojsija i Arona po noæi i reèe: ustajte, idite iz naroda mojega i vi i sinovi Izrailjevi, i otidite, poslužite Gospodu, kao što govoriste.
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
Uzmite i ovce svoje i goveda svoja, kao što govoriste, i idite, pa i mene blagoslovite.
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
I Misirci navaljivahu na narod da brže idu iz zemlje, jer govorahu: izgibosmo svi.
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
I narod uze tijesto svoje još neuskislo, umotavši ga u haljine svoje, na ramena svoja.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
I uèiniše sinovi Izrailjevi po zapovijesti Mojsijevoj, i zaiskaše u Misiraca nakita srebrnijeh i nakita zlatnijeh i haljina.
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
I Gospod uèini, te narod naðe ljubav u Misiraca, te im dadoše; tako oplijeniše Misirce.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
I otidoše sinovi Izrailjevi iz Ramese u Sohot, oko šest stotina tisuæa pješaka, samijeh ljudi osim djece.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
I drugih ljudi mnogo otide s njima, i stoke sitne i krupne vrlo mnogo.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
I od tijesta koje iznesoše iz Misira ispekoše pogaèe prijesne, jer ne bješe uskislo kad ih potjeraše Misirci, te ne mogaše oklijevati, niti spremiše sebi brašnjenice.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
A baviše se sinovi Izrailjevi u Misiru èetiri stotine i trideset godina.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
I kad se navrši èetiri stotine i trideset godina, u isti dan izaðoše sve vojske Gospodnje iz zemlje Misirske.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Ta se noæ svetkuje Gospodu, u koju ih izvede iz Misira; to je noæ Gospodnja, koju treba da svetkuju sinovi Izrailjevi od koljena na koljeno.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
I reèe Gospod Mojsiju i Aronu: ovo neka bude zakon za pashu: nijedan tuðin da je ne jede;
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
A svaki sluga vaš kupljen za novce, kad ga obrežete, onda neka je jede.
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Došljak ili najamnik da je ne jede.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
U istoj kuæi da se jede, da ne iznesete mesa od nje iz kuæe, i kosti da joj ne prelomite.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Sav zbor Izrailjev neka èini tako.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Ako bi kod tebe sjedio tuðin i htio bi svetkovati pashu Gospodnju, neka mu se obreže sve muškinje, pa onda neka pristupi da je svetkuje, i neka bude kao roðen u zemlji; a niko neobrezan da je ne jede.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Zakon jedan da je i roðenome u zemlji i došljaku koji sjedi meðu vama.
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
I uèiniše svi sinovi Izrailjevi kako zapovjedi Gospod Mojsiju i Aronu, tako uèiniše.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
I taj dan izvede Gospod sinove Izrailjeve iz zemlje Misirske u èetama njihovijem.