< Exodus 12 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
Домнул а зис луй Мойсе ши луй Аарон ын цара Еӂиптулуй:
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
„Луна ачаста ва фи пентру вой чя динтый лунэ; еа ва фи пентру вой чя динтый лунэ а анулуй.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Ворбиць ынтреӂий адунэрь а луй Исраел ши спунеци-й: ‘Ын зиуа а зечя а ачестей лунь, фиекаре ом сэ я ун мел де фиекаре фамилие, ун мел де фиекаре касэ.
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
Дакэ сунт пря пуцинь ын касэ пентру ун мел, сэ-л я ку вечинул луй чел май де апроапе, дупэ нумэрул суфлетелор; сэ фачець сокотяла кыт поате мынка фиекаре дин мелул ачеста.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
Сэ фие ун мел фэрэ кусур, де парте бэрбэтяскэ, де ун ан; вець путя сэ луаць ун мел сау ун ед.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
Сэ-л пэстраць пынэ ын зиуа а пайспрезечя а луний ачестея, ши тоатэ адунаря луй Исраел сэ-л ынжунгие сяра.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
Сэ я дин сынӂеле луй ши сэ унгэ амындой стылпий уший ши прагул де сус ал каселор унде ыл вор мынка.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
Карня с-о мэнынче кяр ын ноаптя ачея, фриптэ ла фок, ши ануме с-о мэнынче ку азиме ши ку вердецурь амаре.
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
Сэ ну-л мынкаць круд сау ферт ын апэ, чи сэ фие фрипт ла фок: атыт капул, кыт ши пичоареле ши мэрунтаеле.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
Сэ ну лэсаць нимик дин ел пынэ а доуа зи диминяца; ши дакэ ва рэмыне чева дин ел пе а доуа зи диминяца, сэ-л ардець ын фок.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
Кынд ыл вець мынка, сэ авець мижлокул ынчинс, ынкэлцэминтя ын пичоаре ши тоягул ын мынэ ши сэ-л мынкаць ын грабэ, кэч сунт Паштеле Домнулуй.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
Ын ноаптя ачея, Еу вой трече прин цара Еӂиптулуй ши вой лови пе тоць ынтыий нэскуць дин цара Еӂиптулуй, де ла оамень пынэ ла добитоаче, ши вой фаче жудекатэ ымпотрива тутурор зеилор Еӂиптулуй; Еу, Домнул.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
Сынӂеле вэ ва служи ка семн пе каселе унде вець фи. Еу вой ведя сынӂеле ши вой трече пе лынгэ вой, аша кэ ну вэ ва нимичи ничо урӂие атунч кынд вой лови цара Еӂиптулуй.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Ши помениря ачестей зиле с-о пэстраць ши с-о прэзнуиць принтр-о сэрбэтоаре ын чинстя Домнулуй; с-о прэзнуиць ка о леӂе вешникэ пентру урмаший воштри.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
Тимп де шапте зиле, вець мынка азиме. Дин чя динтый зи, вець скоате алуатул дин каселе воастре, кэч орьчине ва мынка пыне доспитэ дин зиуа ынтый пынэ ын зиуа а шаптя ва фи нимичит дин Исраел.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
Ын зиуа динтый, вець авя о адунаре де сэрбэтоаре сфынтэ; ши ын зиуа а шаптя, вець авя о адунаре де сэрбэтоаре сфынтэ. Сэ ну фачець ничо мункэ ын зилеле ачеля; вець путя нумай сэ прегэтиць мынкаря фиекэруй инс.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Сэ цинець Сэрбэтоаря Азимилор, кэч кяр ын зиуа ачея вой скоате оштиле воастре дин цара Еӂиптулуй; сэ цинець зиуа ачея ка о леӂе вешникэ пентру урмаший воштри.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
Ын луна ынтый, дин а пайспрезечя зи а луний, сяра, сэ мынкаць азиме, пынэ ын сяра зилей а доуэзечь ши уна а луний.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Тимп де шапте зиле, сэ ну се гэсяскэ алуат ын каселе воастре; кэч орьчине ва мынка пыне доспитэ ва фи нимичит дин адунаря луй Исраел, фие стрэин, фие бэштинаш.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Сэ ну мынкаць пыне доспитэ, чи, ын тоате локуинцеле воастре, сэ мынкаць азиме.’”
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
Мойсе а кемат пе тоць бэтрыний луй Исраел ши ле-а зис: „Дучеци-вэ де луаць ун мел пентру фамилииле воастре ши ынжунгияць Паштеле.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
Сэ луаць апой ун мэнункь де исоп, сэ-л ынмуяць ын сынӂеле дин стракинэ ши сэ унӂець прагул де сус ши чей дой стылпь ай уший ку сынӂеле дин стракинэ. Нимень дин вой сэ ну ясэ дин касэ пынэ диминяца.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
Кынд ва трече Домнул ка сэ ловяскэ Еӂиптул ши ва ведя сынӂеле пе прагул де сус ши пе чей дой стылпь ай уший, Домнул ва трече пе лынгэ ушэ ши ну ва ынгэдуи Нимичиторулуй сэ интре ын каселе воастре ка сэ вэ ловяскэ.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
Сэ пэзиць лукрул ачеста ка о леӂе пентру вой ши пентру копиий воштри ын вяк.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
Кынд вець интра ын цара пе каре в-о ва да Домнул, дупэ фэгэдуинца Луй, сэ цинець ачест обичей сфынт.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
Ши кынд вэ вор ынтреба копиий воштри: ‘Че ынсямнэ обичеюл ачеста?’
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
сэ рэспундець: ‘Есте жертфа де Паште ын чинстя Домнулуй, каре а трекут пе лынгэ каселе копиилор луй Исраел ын Еӂипт, кынд а ловит Еӂиптул ши не-а скэпат каселе ноастре.’” Попорул с-а плекат ши с-а ынкинат пынэ ла пэмынт.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Ши копиий луй Исраел ау плекат ши ау фэкут кум порунчисе Домнул луй Мойсе ши луй Аарон; аша ау фэкут.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
Ла мезул нопций, Домнул а ловит пе тоць ынтыий нэскуць дин цара Еӂиптулуй, де ла ынтыюл нэскут ал луй Фараон, каре шедя пе скаунул луй де домние, пынэ ла ынтыюл нэскут ал челуй ынкис ын темницэ ши пынэ ла тоць ынтыий нэскуць ай добитоачелор.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
Фараон с-а скулат ноаптя, ел ши тоць служиторий луй ши тоць еӂиптений, ши ау фост марь ципете ын Еӂипт, кэч ну ера касэ унде сэ ну фие ун морт.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
Ын ачеяшь ноапте, Фараон а кемат пе Мойсе ши пе Аарон ши ле-а зис: „Скулаци-вэ, ешиць дин мижлокул попорулуй меу, вой ши копиий луй Исраел. Дучеци-вэ сэ служиць Домнулуй, кум аць зис.
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
Луаци-вэ ши оиле ши боий, кум аць зис, дучеци-вэ ши бинекувынтаци-мэ.”
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
Еӂиптений зоряу попорул ши се грэбяу сэ-й скоатэ дин царэ, кэч зичяу: „Алтфел, тоць вом пери.”
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
Попорул шь-а луат плэмэдяла (кока) ынаинте де а се доспи. Шь-ау ынвелит постэвиле ку плэмэдяла ын хайне ши ле-ау пус пе умерь.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
Копиий луй Исраел ау фэкут че спусесе Мойсе ши ау черут еӂиптенилор васе де арӂинт, васе де аур ши хайне.
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
Домнул а фэкут ка попорул сэ капете тречере ынаинтя еӂиптенилор, каре ле-ау ымплинит череря. Ши астфел ау жефуит пе еӂиптень.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Копиий луй Исраел ау плекат дин Рамсес спре Сукот, ын нумэр де апроапе шасе суте де мий де оамень каре мерӂяу пе жос, афарэ де копий.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
О мулциме де оамень де тот союл с-ау суит ымпреунэ ку ей; авяу ши турме ынсемнате де ой ши бой.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
Ку плэмэдяла пе каре о луасерэ дин Еӂипт ши каре ну се досписе ынкэ, ау фэкут турте фэрэ алуат, кэч фусесерэ изгониць де еӂиптень фэрэ сэ май поатэ зэбови ши фэрэ сэ-шь я меринде ку ей.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
Шедеря копиилор луй Исраел ын Еӂипт а фост де патру суте трейзечь де ань.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Ши, дупэ патру суте трейзечь де ань, токмай ын зиуа ачея, тоате оштиле Домнулуй ау ешит дин цара Еӂиптулуй.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Ноаптя ачея требуе прэзнуитэ ын чинстя Домнулуй, пентру кэ атунч й-а скос дин цара Еӂиптулуй. Ноаптя ачея требуе прэзнуитэ ын чинстя Домнулуй де тоць копиий луй Исраел ши де урмаший лор.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
Домнул а зис луй Мойсе ши луй Аарон: „Ятэ порунка привитоаре ла Паште: ничун стрэин сэ ну мэнынче дин еле.
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
Сэ тай ымпрежур пе орьче роб кумпэрат ку бань, ши апой сэ мэнынче дин еле.
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Венетикул ши симбриашул сэ ну мэнынче.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
Сэ ну ле мэнынче декыт ынтр-о сингурэ касэ; сэ ну луаць делок карне афарэ дин касэ ши сэ ну здробиць ничун ос.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Тоатэ адунаря луй Исраел сэ факэ Паштеле.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Дакэ ун стрэин каре ва локуи ла тине ва вря сэ факэ Паштеле Домнулуй, орьче парте бэрбэтяскэ дин каса луй ва требуи тэятэ ымпрежур; апой се ва апропия сэ ле факэ, ши ва фи ка ши бэштинашул, дар ничун нетэят ымпрежур сэ ну мэнынче дин еле.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Ачеяшь леӂе ва фи пентру бэштинаш ка ши пентру стрэинул каре ва локуи ын мижлокул востру.”
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Тоць копиий луй Исраел ау фэкут кум порунчисе Домнул луй Мойсе ши луй Аарон; аша ау фэкут.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
Ши кяр ын зиуа ачея, Домнул а скос дин цара Еӂиптулуй пе копиий луй Исраел, дупэ оштиле лор.

< Exodus 12 >