< Exodus 12 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
PAN powiedział jeszcze do Mojżesza i Aarona w ziemi Egiptu:
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
Ten miesiąc [będzie] dla was początkiem miesięcy, będzie dla was pierwszym miesiącem roku.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Powiedzcie całemu zgromadzeniu Izraela: Dziesiątego [dnia] tego miesiąca każdy weźmie sobie baranka dla rodziny, jednego baranka dla domu.
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
A jeśli rodzina jest zbyt mała, aby zjeść baranka, niech dobierze go razem z sąsiadem, który jest najbliższy jej domu, według liczby dusz, naliczywszy [tyle osób], ile mogłoby zjeść baranka.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
Wasz baranek ma być bez skazy, jednoroczny samiec. Weźmiecie go spośród owiec albo kóz.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
Będziecie go strzegli aż do czternastego dnia tego miesiąca, a [wtedy] całe zgromadzenie Izraela zabije go pod wieczór.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
Potem wezmą z jego krwi i pokropią oba węgary i nadproże domu, w którym będą go spożywać.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
I będą jeść tej nocy mięso pieczone przy ogniu i przaśny chleb; będą je jeść [z] gorzkimi [ziołami].
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
Nie jedzcie z niego nic surowego ani ugotowanego w wodzie, lecz [tylko] upieczone przy ogniu, z jego głową, nogami i wnętrznościami.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
Nie zostawicie z niego [niczego] do rana; a jeśliby coś z niego zostało do rana, spalicie to w ogniu.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
Tak oto będziecie go spożywać: Wasze biodra będą przepasane, obuwie na waszych nogach i laska w waszym ręku. Będziecie go jeść pośpiesznie. To Pascha PANA.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
Gdyż tej nocy przejdę przez ziemię Egiptu i zabiję wszystko, co pierworodne w ziemi Egiptu, od człowieka aż do zwierzęcia, a nad wszystkimi bogami Egiptu dokonam sądu, ja, PAN.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
A ta krew będzie dla was znakiem na domach, w których będziecie. Gdy bowiem ujrzę krew, ominę was i nie dotknie was plaga zniszczenia, gdy będę zabijał w ziemi Egiptu.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Ten dzień będzie dla was pamiątką i będziecie go obchodzić jako święto dla PANA po wszystkie pokolenia. Będziecie go obchodzić jako ustawę wieczną.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
Przez siedem dni będziecie jeść przaśny chleb. Już w pierwszym dniu usuniecie zakwas z waszych domów, bo ktokolwiek będzie jadł coś kwaszonego, od pierwszego dnia aż do siódmego, ta dusza zostanie wykluczona z Izraela.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
W tym pierwszym dniu będzie święte zgromadzenie, także siódmego dnia będziecie mieć święte zgromadzenie. W tych dniach nie będziecie wykonywać żadnej pracy. Będzie wam tylko wolno przygotować to, czego każdy potrzebuje do jedzenia.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
I będziecie obchodzić Święto Przaśników, bo w tym właśnie dniu wyprowadziłem wasze zastępy z ziemi Egiptu. Dlatego będziecie obchodzić ten dzień po wszystkie pokolenia jako ustawę wieczną.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
W pierwszym miesiącu, od wieczora czternastego dnia tego miesiąca do wieczora dnia dwudziestego pierwszego tego miesiąca, będziecie jeść przaśny chleb.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Przez siedem dni nie znajdzie się żaden zakwas w waszych domach. Ktokolwiek bowiem będzie jadł coś kwaszonego, ta dusza zostanie wykluczona ze zgromadzenia Izraela, zarówno przybysz, jak i urodzony w tej ziemi.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Nie będziecie jeść nic kwaszonego; we wszystkich waszych domach będziecie jeść przaśne chleby.
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
Wtedy Mojżesz wezwał wszystkich starszych Izraela i powiedział im: Wybierzcie i weźcie sobie baranka dla swych rodzin i zabijcie go jako paschę.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
Weźmiecie też wiązkę hizopu i zanurzycie we krwi, która jest w misie, i pokropicie nadproże i oba węgary tą krwią, która jest w misie. Niech nikt z was nie wychodzi za drzwi swego domu aż do rana.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
PAN bowiem przejdzie, aby zabijać Egipcjan, a gdy ujrzy krew na nadprożu i na obu węgarach, PAN ominie drzwi i nie pozwoli niszczycielowi wejść do waszych domów, aby [was] zabić.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
Będziecie przestrzegać tego jako ustawy dla ciebie i twoich synów aż na wieki.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
Kiedy wejdziecie do ziemi, którą da wam PAN, jak to obiecał, będziecie przestrzegać tego obrzędu.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
A gdy wasi synowie zapytają was: Co oznacza ten wasz obrzęd?
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
Wtedy odpowiecie: To ofiara paschy PANA, który ominął domy synów Izraela w Egipcie, gdy zabijał Egipcjan, a nasze domy ocalił. Potem lud schylił się i oddał pokłon.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
I synowie Izraela odeszli, i uczynili, jak PAN rozkazał Mojżeszowi i Aaronowi, tak właśnie zrobili.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
A o północy PAN zabił wszystko, co pierworodne w ziemi Egiptu, od pierworodnego [syna] faraona, zasiadającego na jego tronie, aż do pierworodnego więźnia, który był w więzieniu, oraz wszystko, co pierworodne z bydła.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
Wstał tej nocy faraon, a z nim wszyscy jego słudzy oraz wszyscy Egipcjanie; i podniósł się w Egipcie wielki krzyk, bo nie było domu, w którym nie byłoby umarłego.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
[Faraon] wezwał Mojżesza i Aarona w nocy i powiedział: Wstańcie, wyjdźcie spośród mego ludu, wy i synowie Izraela. Idźcie i służcie PANU, jak mówiliście.
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
Zabierzcie też swoje trzody i bydła, jak żądaliście, i idźcie. Mnie też błogosławcie.
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
I Egipcjanie przynaglali lud, aby ich jak najszybciej wyprawić z ziemi, bo mówili: Wszyscy pomrzemy.
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
Wziął więc lud swoje ciasto, zanim się zakwasiło, i dzieże owinięte w swoje szaty i [kładli je] na swoje ramiona.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
Synowie Izraela postąpili według nakazu Mojżesza i pożyczyli od Egipcjan srebrne i złote przedmioty oraz szaty.
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
A PAN dał ludowi łaskę w oczach Egipcjan, tak że im pożyczyli. I złupili Egipcjan.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Wyruszyli więc synowie Izraela z Ramzes do Sukkot, około sześciuset tysięcy pieszych mężczyzn, nie licząc dzieci.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
Ale szło z nimi też mnóstwo obcego ludu oraz owce i bydło, bardzo liczny dobytek.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
I popiekli przaśne placki z ciasta, które wynieśli z Egiptu, bo nie było zakwaszone. Ponieważ zostali wygnani z Egiptu, nie mogli zwlekać i nie przygotowali sobie też żadnej żywności.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
A [czas] przebywania synów Izraela, którzy mieszkali w Egipcie, [wynosił] czterysta trzydzieści lat.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
I stało się tak, że po upływie czterystu trzydziestu lat, tego samego dnia, wszystkie zastępy PANA wyszły z ziemi Egiptu.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Ta noc ma być obchodzona dla PANA, dlatego że wyprowadził ich z ziemi Egiptu. Ta noc ma być więc obchodzona dla PANA przez wszystkich synów Izraela po wszystkie ich pokolenia.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
I PAN powiedział do Mojżesza i Aarona: Taka jest ustawa Paschy: Żaden obcy nie będzie z niej spożywał.
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
Każdy jednak wasz sługa nabyty za pieniądze będzie mógł z niej spożywać, jeśli tylko go obrzezacie.
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Cudzoziemiec i najemnik nie będą z niej spożywać.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
W jednym domu będzie spożywany [baranek]. Nie wyniesiesz z domu [nic] z jego mięsa i nie złamiecie jego kości.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Całe zgromadzenie Izraela [tak] z nim postąpi.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
A jeśli jakiś cudzoziemiec będzie twoim gościem i będzie chciał obchodzić Paschę dla PANA, niech [najpierw] zostanie obrzezany każdy mężczyzna jego [domu], a potem niech przystąpi i obchodzi ją. Wtedy będzie jak urodzony w tej ziemi. A ktokolwiek nie jest obrzezany, nie będzie z niej spożywał.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Jedno prawo będzie dla urodzonego w ziemi i dla cudzoziemca, który jest gościem wśród was.
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Wszyscy synowie Izraela uczynili więc, jak PAN rozkazał Mojżeszowi i Aaronowi, tak właśnie uczynili.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
Tego samego dnia PAN wyprowadził synów Izraela z ziemi Egiptu według ich zastępów.

< Exodus 12 >