< Exodus 12 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
Jehova akĩĩra Musa na Harũni marĩ kũu bũrũri wa Misiri atĩrĩ,
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
“Mweri ũyũ nĩguo ũgũtuĩka mweri wa mbere harĩ inyuĩ, ũtuĩke mweri wa mbere wa mwaka wanyu.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Ĩrai andũ othe a Isiraeli atĩ mũthenya wa ikũmi mweri ũyũ, o mũndũ akanyiitĩra andũ a nyũmba yake gatũrũme; o nyũmba gatũrũme kamwe.
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
Nyũmba ĩngĩgakorwo ĩrĩ nini mũno, ũndũ ĩtangĩniina gatũrũme kamwe-rĩ, nĩmanyiitanĩre gatũrũme kamwe na nyũmba ĩrĩa mahakanĩte nayo, marĩkĩtie gwĩtara mũigana wao meturanĩire. Rorai na mũtue wega nĩ tũtũrũme tũigana tũkabatarania kũringana na mũrĩĩre wa o mũndũ.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
Nyamũ iria mũgũthuura no nginya ikorwo irĩ tũtũrũme twa ũkũrũ wa mwaka ũmwe, na itarĩ na kaũũgũ, na mũgaaciruta kuuma harĩ ngʼondu kana mbũri.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
Cimenyererei nginya mũthenya wa ikũmi na ĩna wa mweri, hĩndĩ ĩrĩa andũ othe a Isiraeli magaacithĩnja hwaĩ-inĩ.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
Hĩndĩ ĩyo makooya thakame ĩmwe ya tũtũrũme tũu, nao mamĩhake hingĩro-inĩ cia igũrũ na cia mĩena ya mũrango wa nyũmba ĩrĩa makaarĩĩra tũtũrũme tũu.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
Ũtukũ o ũcio makaarĩa nyama icio ihĩhĩtio na mwaki, marĩĩanĩrie na nyeni ndũrũ na mĩgate ĩtarĩ mĩĩkĩre ndawa ya kũimbia.
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
Mũtikanarĩe nyama irĩ njĩthĩ kana itherũkĩtio na maaĩ, no ihĩhio na mwaki, mũtwe, na magũrũ o na nyama cia nda.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
Mũtikanatigie imwe ciacio ikinyĩrie rũciinĩ; iria ingĩtigara nginya rũciinĩ, no nginya mũgaacicina.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
Ũũ nĩguo mũkaarĩa nyama icio: mũkorwo mwĩhotorete mĩcibi yanyu njohero, na iraatũ cianyu irĩ magũrũ, na mĩtirima yanyu ĩrĩ moko. Mũgaacirĩa naihenya; ĩyo nĩyo Bathaka ya Jehova.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
“O ũtukũ ũcio nĩngatuĩkanĩria bũrũri wa Misiri, na nĩngooraga marigithathi mothe ma andũ na ma nyamũ, na nĩngatuĩra ngai cia bũrũri wa Misiri ciothe ciira. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
Thakame ĩyo ĩgaatuĩka rũũri rwanyu nyũmba-inĩ iria mũgaakorwo mũrĩ, na rĩrĩa ngoona thakame-rĩ, no kũmũhĩtũka ngaamũhĩtũka. Gũtirĩ mũthiro ũkamũhutia hĩndĩ ĩrĩa ngaahũũra bũrũri wa Misiri.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
“Mũthenya ũcio nĩmũrĩũririkanaga; ũkũngũyagĩrei harĩ njiarwa iria igooka ũrĩ wa gĩathĩ kĩa Jehova, ũrĩ ũndũ wathanĩtwo wa gũtũũra.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
Ihinda rĩa mĩthenya mũgwanja, mũkaarĩĩaga mĩgate ĩtarĩ mĩĩkĩre ndawa ya kũimbia. Mũthenya wa mbere mũkeeheria ndawa ya kũimbia kuuma nyũmba cianyu, nĩgũkorwo mũndũ o wothe ũngĩrĩa kĩndũ kĩrĩ ndawa ya kũimbia kuuma mũthenya wa mbere nginya wa mũgwanja-rĩ, nĩakaingatwo eherio harĩ andũ a Isiraeli.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
Gĩai na kĩũngano gĩtheru mũthenya wa mbere, na mũgĩe na kĩngĩ mũthenya wa mũgwanja. Mũtikanarute wĩra o na ũrĩkũ mĩthenya ĩyo, tiga o wa kũhaarĩria irio cia kũrĩĩo nĩ mũndũ wothe, ũguo noguo mũngĩĩka.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
“Kũngũĩrai Gĩathĩ kĩa Mĩgate Ĩtarĩ Ndawa ya Kũimbia, tondũ nĩ mũthenya ũyũ kĩũmbe ndamũrutire mũrĩ ikundi kuuma bũrũri wa Misiri. Kũngũĩrai mũthenya ũyũ ũrĩ ũndũ wathanĩtwo wa gũtũũra nginya njiarwa iria igooka.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
Mweri wa mbere mũrĩrĩĩaga mĩgate ĩtarĩ na ndawa ya kũimbia, kwambĩrĩria hwaĩ-inĩ wa mũthenya wa ikũmi na ĩna, nginya hwaĩ-inĩ wa mũthenya wa mĩrongo ĩrĩ na ũmwe.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Handũ ha matukũ mũgwanja, gũtikoneke ndawa ya kũimbia mĩgate nyũmba-inĩ cianyu. Na rĩrĩ, mũndũ o wothe ũngĩrĩa kĩndũ kĩrĩ na ndawa ya kũimbia nĩakaingatwo athengio mũingĩ-inĩ wa Isiraeli, arĩ mũgeni, kana aciarĩtwo arĩ Mũisiraeli.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Mũtikanarĩe kĩndũ gĩĩkĩrĩtwo ndawa ya kũimbia. Kũrĩa guothe mũgaatũũra, mũkaarĩĩaga mĩgate ĩtarĩ ndawa ya kũimbia.”
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
Nake Musa agĩĩta athuuri a Isiraeli othe, akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi o narua mũgathuure nyamũ nĩ ũndũ wa nyũmba cianyu na mũthĩnje gatũrũme ka Bathaka.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
Oyai kĩohe kĩa mahuti ma mũthobi, mũgĩtobokie karaĩ-inĩ karĩ na thakame, mũcooke mũmĩhake hingĩro ya igũrũ ya mũrango, o na mĩena yeerĩ ya hingĩro cia mũrango. Gũtikagĩe mũndũ o na ũmwe wanyu ũkuuma nja ya nyũmba yake nginya rũciinĩ.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
Hĩndĩ ĩrĩa Jehova arĩtuĩkania bũrũri nĩguo orage andũ a Misiri-rĩ, nĩarĩona thakame ĩyo ĩrĩ igũrũ na mĩena ya hingĩro cia mĩrango, nake ahĩtũke mũromo wa nyũmba ĩyo, na nĩakagiria mũniinani atoonye nyũmba cianyu amũũrage.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
“Athĩkĩrai ũrutani ũyũ taarĩ watho wa gũtũũra wathĩkagĩrwo nĩ inyuĩ na njiaro cianyu.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
Rĩrĩa mũgaatoonya bũrũri ũrĩa Jehova akaamũhe ta ũrĩa eranĩire-rĩ, mũkaamenyagĩrĩra gĩathĩ gĩkĩ.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
Na rĩrĩa ciana cianyu ikamũũria atĩrĩ, ‘Gĩathĩ gĩkĩ kiugĩte atĩa harĩ inyuĩ?’
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
Mũgaaciĩra atĩrĩ, ‘Nĩ igongona rĩa Bathaka rĩa kũrutĩra Jehova, ũrĩa waagararire nyũmba cia andũ a Isiraeli kũu bũrũri wa Misiri, na akĩhonokia andũ a nyũmba ciitũ hĩndĩ ĩrĩa ooragire andũ a Misiri.’” Nao andũ makĩinamĩrĩria mothiũ mao, makĩhooya.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Andũ a Isiraeli magĩgĩka o ũrĩa Jehova aathire Musa na Harũni.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
O ũtukũ gatagatĩ Jehova akĩũraga marigithathi mothe kũu bũrũri wa Misiri, kwambĩrĩria irigithathi rĩa Firaũni, ũrĩa waikaragĩra gĩtĩ kĩa ũnene, nginya irigithathi rĩa mũndũ muohe ũrĩa warĩ njeera na marigithathi ma mahiũ mothe.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
Firaũni na anene ake othe o na andũ a Misiri othe, magĩũkĩra kũrĩ o ũtukũ, nakuo gũkĩgĩa kĩrĩro kĩnene kũu bũrũri wa Misiri, nĩgũkorwo gũtiarĩ nyũmba ĩtaarĩ na mũndũ wakuĩte.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
O ũtukũ ũcio, Firaũni agĩĩta Musa na Harũni, akĩmeera atĩrĩ, “Ũkĩrai! Ehererai andũ akwa, inyuĩ o na andũ a Isiraeli othe! Thiĩi mũgatungatĩre Jehova o ta ũrĩa mũũrĩtie.
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
Oyai ndũũru cianyu cia mbũri na cia ngʼombe o ta ũrĩa mũroigĩte na mũthiĩ. Na mũndathime o na niĩ.”
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
Nao andũ a Misiri makĩhĩka andũ acio moime bũrũri ũcio na ihenya, nĩgũkorwo moigire atĩrĩ, “Kwaga ũguo, tũgũkua ithuothe!”
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli makĩoya kĩmere kĩao gĩtanekĩrwo ndawa ya kũimbia, na magĩgĩkuua na ciande, nayo mĩharatĩ yoohereirwo nguo-inĩ.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
Nao andũ a Isiraeli magĩĩka o ta ũrĩa meerĩĩtwo nĩ Musa na makĩhooya andũ a Misiri mamahe indo cia betha na cia thahabu, o na nguo.
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
Jehova agĩtũma andũ acio metĩkĩrĩke nĩ andũ a Misiri nao makĩmahe kĩrĩa gĩothe meetirie; nĩ ũndũ ũcio magĩtaha indo cia andũ a Misiri.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Andũ a Isiraeli makĩambĩrĩria rũgendo kuuma Ramesese magĩthiĩ Sukothu. Arũme arĩa metwaraga na magũrũ maarĩ ta 600,000 hategũtarwo atumia na ciana.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
Na andũ angĩ aingĩ nĩmathiire na makĩambatania nao, hamwe na ndũũru nene cia mahiũ ma mbũri na ngʼombe.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
Kĩmere kĩrĩa maarutĩte bũrũri wa Misiri nĩkĩo maatũmĩrire gũthondeka mĩgate ĩtarĩ ndawa ya kũimbia. Kĩmere kĩu gĩtiarĩ na ndawa ya kũimbia tondũ nĩkũingatwo maingatirwo bũrũri wa Misiri, na matiigana kũgĩa na ihinda rĩa kũhaarĩria irio ciao.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
Ihinda rĩrĩa andũ a Isiraeli maatũũrire bũrũri wa Misiri nĩ mĩaka 430.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Harĩa mĩaka ĩyo 430 yathirĩire-rĩ, mũthenya o ro ũcio, nĩguo ikundi ciothe cia andũ a Jehova cioimire bũrũri wa Misiri.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Tondũ ũtukũ ũcio nĩguo Jehova aikarire eiguĩte nĩguo amarute bũrũri wa Misiri-rĩ, na ũtukũ ũyũ nao andũ a Isiraeli othe nĩmarĩikaraga meiguĩte nĩguo matĩĩage Jehova njiarwa-inĩ ciothe iria igooka.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
Jehova akĩĩra Musa na Harũni atĩrĩ, “Maya nĩmo mawatho ma Bathaka: “Gũtirĩ mũgeni ũngĩrĩa Bathaka ĩyo.
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
Ngombo o yothe ũgũrĩte no ĩrĩe Bathaka ĩyo thuutha wa kũmĩruithia,
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
no mũrarĩrĩri kana mũruti wĩra wa mũcaara ndakanamĩrĩe.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
“No nginya ĩrĩĩagĩrwo thĩinĩ wa nyũmba o ĩmwe, mũtikanoimie nyama o na ĩrĩkũ nja ya nyũmba. Mũtikanoine ihĩndĩ o na rĩmwe rĩayo.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Mũingĩ wothe wa Isiraeli no nginya ũkũngũĩre Bathaka.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
“Mũgeni ũtũũrĩte thĩinĩ wanyu na nĩekwenda gũkũngũĩra Bathaka ya Jehova, no nginya aruithie arũme othe a nyũmba yake; thuutha ũcio nĩrĩo angĩkũngũĩra Bathaka ta mũndũ ũciarĩirwo bũrũri-inĩ. Gũtirĩ mũndũ mũrũme ũtarĩ mũruu ũngĩrĩa Bathaka.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Watho o ũcio noguo ũgwatha arĩa maciarĩtwo marĩ a bũrũri, o na ageni arĩa matũũranagia na inyuĩ.”
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Andũ a Isiraeli othe magĩĩka o ũrĩa Jehova aathĩte Musa na Harũni.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
Na mũthenya o ro ũcio, Jehova akĩruta andũ a Isiraeli kuuma bũrũri wa Misiri na ikundi ciao.

< Exodus 12 >