< Exodus 12 >
1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
Og Herren talede til Mose og Aron i Ægyptens Land og sagde:
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
Denne Maaned skal være eder Maanedernes Begyndelse, den skal være eder den første iblandt Maanederne i Aaret.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Taler til al Israels Menighed og siger: Paa den tiende Dag i denne Maaned, da skulle de tage sig hver et Lam for hvert Fædrenehus, eet Lam for hvert Hus.
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
Og dersom Huset ikke er talrigt nok til et Lam, da skal han og hans Nabo, som er næst ved hans Hus, tage et, efter Antallet paa Personerne; I skulle regne til et Lam, efter hvad enhver kan æde til.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
Det skal være eder et lydeløst, eet Aar gammelt Vædderlam; I skulle tage det af Faarene eller af Gederne.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
Og det skal være hos eder i Forvaring til den fjortende Dag i denne Maaned; og de skulle slagte det, hele Israels Menigheds Forsamling, imellem de tvende Aftener.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
Og de skulle tage af Blodet og stryge paa begge Dørstolperne og paa det øverste Dørtræ af Husene, i hvilke de æde det.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
Og de skulle æde Kødet den samme Nat, stegt ved Ild, og med usyrede Brød til beske Urter skulle de æde det.
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
I skulle ikke æde noget deraf raat eller kogt i Vand, men stegt ved Ild, med dets Hoved, med dets Skanker og med dets Indvolde.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
Og I skulle ikke levne noget deraf til om Morgenen; men det, som levnes deraf til om Morgenen, skulle I opbrænde med Ild.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
Og saaledes skulle I æde det: Eders Lænder skulle være ombundne, eders Sko paa eders Fødder og eders Kæp i eders Haand; og I skulle æde det med Hast; det er Paaske for Herren.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
Thi jeg vil gaa igennem Ægyptens Land den samme Nat og slaa alle førstefødte i Ægyptens Land, baade af Mennesker og Kvæg, og jeg vil holde Dom over alle Ægypternes Guder; jeg er Herren.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
Og Blodet skal være eder til et Tegn paa Husene, i hvilke I ere, og jeg vil se Blodet og gaa eder forbi; og der skal ingen Plage være iblandt eder til Fordærvelse, naar jeg slaar Ægyptens Land.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Og denne Dag skal være for eder til en Ihukommelse, og den skulle I højtideligholde som Højtid for Herren; hos eders Efterkommere til en evig Skik skulle I højtideligholde den.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
I skulle æde usyrede Brød syv Dage, paa den første Dag skulle I holde op at bruge Surdejg i eders Huse; thi hver den, som æder syret Brød fra den første Dag indtil den syvende Dag, den Sjæl skal udryddes af Israel.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
Og paa den første Dag skal der være for eder en hellig Sammenkaldelse, og paa den syvende Dag en hellig Sammenkaldelse; der skal ikke gøres noget Arbejde paa dem, alene det, som skal ædes af hver Person, det alene maa tilberedes for eder.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Og I skulde holde de usyrede Brøds Højtid; thi paa den selvsamme Dag udførte jeg eders Hære af Ægyptens Land; derfor skulle I holde denne Dag hos eders Efterkommere til en evig Skik.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
I den første Maaned paa den fjortende Dag i Maaneden, om Aftenen skulle I æde usyrede Brød, indtil den een og tyvende Dag i Maaneden om Aftenen.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Syv Dage skal der ikke findes Surdejg i eders Huse; thi hver den, som æder syret Brød, den Sjæl skal udryddes af Israels Menighed, hvad enten han er fremmed eller en indfødt i Landet.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Intet syret skulle I æde, I skulle æde usyrede Brød i alle eders Boliger.
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
Da kaldte Mose ad alle de ældste af Israel og sagde til dem: Henter frem og tager eder smaat Kvæg for eders Slægter og slagter Paaskelammet.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
Og I skulle tage et Knippe Isop og dyppe i Blodet, som er i Bækkenet, og stryge paa det øverste Dørtræ og paa begge Dørstolperne af Blodet, som er i Bækkenet; og ingen af eder skal gaa ud af sit Huses Dør, før om Morgenen.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
Og Herren skal gaa igennem for at slaa Ægypterne, og han skal se Blodet paa det øverste Dørtræ og paa begge Dørstolperne, og Herren skal gaa Døren forbi og ikke tilstede Fordærveren at komme til eders Huse for at slaa.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
Derfor skulle I varetage dette til en Skik for dig og for dine Børn evindeligen.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
Og det skal ske, naar I komme til Landet, som Herren skal give eder, som han har sagt, da skulle I varetage denne Tjeneste.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
Og det skal ske, naar eders Børn sige til eder: Hvad er dette for en Tjeneste, som I have for?
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
da skulle I sige: Det er Paaskeoffer for Herren, som gik Israels Børns Huse forbi i Ægypten, der han slog Ægypterne og friede vore Huse; saa bøjede Folket sig og tilbad.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Og Israels Børn gik hen og gjorde det; efter som Herren havde befalet Mose og Aron, saa gjorde de.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
Og det skete om Midnatten, da slog Herren alle førstefødte i Ægyptens Land, fra den førstefødte for Farao, som sad paa sin Trone, indtil den førstefødte for den fangne, som var i Fængslets Hus, og alle førstefødte af Kvæget.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
Da stod Farao op samme Nat og alle hans Tjenere og alle Ægypterne, og der blev et stort Skrig i Ægypten; thi der var ikke eet Hus, at der jo var en død deri.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
Og han kaldte Mose og Aron om Natten og sagde: Gører eder rede, gaar ud af mit Folks Midte, baade I, saa og Israels Børn, og gaar, tjener Herren, som I have sagt.
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
Tager baade eders Faar og eders Øksne, som I have sagt, og gaar, og I skulle ogsaa velsigne mig.
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
Og Ægypterne trængte haardt paa Folket for hastigen at faa dem ud af Landet; thi de sagde: Vi dø alle.
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
Saa tog Folket sin Dejg op, før den blev syret, deres Dejgtruge, indsvøbte i deres Kapper, paa deres Skuldre.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
Og Israels Børn havde gjort efter Mose Ord og begæret af Ægypterne Sølvkar og Guldkar og Klæder.
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
Og Herren havde givet Folket Naade for Ægypternes Øjne, saa at de lode dem faa dem; og de skilte Ægypterne derved.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Saa rejste Israels Børn fra Raamses til Sukot, henved seks Hundrede Tusinde Mænd til Fods, foruden smaa Børn.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
Ja og en stor Hob af alle Haande Folk drog op med dem, og Faar og Øksne, ja saare meget Kvæg.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
Og de bagte af den Dejg, som de førte fra Ægypten, usyrede Kager, thi den var ikke syret; fordi de vare uddrevne af Ægypten og kunde ikke tøve og havde end ikke beredt sig Tæring.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
Og Israels Børn havde boet udi Ægypten i fire Hundrede Aar og tredive Aar.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Og det skete, der fire Hundrede og tredive Aar vare til Ende, ja det skete lige paa den samme Dag, da udgik alle Herrens Hære af Ægyptens Land.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Denne er en Nat, som toges i Agt af Herren for at udføre dem af Ægyptens Land; den samme Nat skal tages i Agt for Herren af alle Israels Børn hos deres Efterkommere.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
Og Herren sagde til Mose og Aron: Denne er Paaskens Skik: Ingen fremmed skal æde deraf.
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
Men enhver Svend, som hører nogen til, og som er købt for Penge, maa, naar du faar omskaaret ham, æde deraf.
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Ingen Gæst eller Lejesvend skal æde deraf.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
Det skal ædes i eet Hus, du skal ikke udbære af Kødet udenfor Huset; og I skulle ikke bryde Ben derpaa.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Al Israels Menighed skal gøre det.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Og naar nogen fremmed opholder sig hos dig og vil holde Paaske for Herren, da skal alt hans Mandkøn omskæres, og da maa han have Adgang til at holde den og være som en indfødt i Landet; men ingen, som har Forhud, skal æde deraf.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Der skal være een Lov for den indfødte og for den fremmede, som opholder sig midt iblandt eder.
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Og alle Israels Børn gjorde det; som Herren havde befalet Mose og Aron, saa gjorde de.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
Og det skete lige paa den samme Dag, at Herren udførte Israels Børn af Ægyptens Land med deres Hære.