< Exodus 12 >
1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
BOEIPA loh Moses neh Aaron te Egypt kho ah a voek.
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
“Tahae hla he nangmih ham hla kungpuei neh kum dongkah hla khuiah khaw nangmih ham lamhma la om ni.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Israel rhaengpuei boeih taengah thui lamtah, 'Tahae kah hla rha dongah tah hlang long he a napa im ham tu pakhat, te pawt atah im pakhat ham tu pakhat tah amamih taengla lo uh saeh.
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
Tu aka om lakah imkhui a vaitah atah a im neh aka yoei a imben taengah lo saeh. Hlang kah hinglu tarhing neh aka ca tarhing ah tu te boesoep pah.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
Boiva te a tal a hmabuet, kum khat aka lo ca te tah tuca khaw maae khaw namamih taengla lo uh.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
Te phoeiah tahae hla hnin hlai li hil tuemkoi la nangmih taengah om vetih kholaeh ah Israel rhaengpuei hlangping boeih loh te te ngawn uh saeh.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
Te phoeiah a thii te lo uh saeh lamtah rhungsut so rhoi neh im kah danglo dongah pae uh saeh. A pum te a khuiah ca uh saeh.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
Maeh te khoyin ah hmai dongkah maehkaeh la ca uh saeh lamtah vaidamding neh ankhaa caak thil uh saeh.
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
A haeng lam khaw, tui neh a thong tih a hmin te lamkhaw ca uh boeh. Tedae a lu neh a kho, a kotak khaw hmai a kaeh ni na caak eh.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
Te te mincang hil paih boeh, mincang hil aka coih pueng te tah hmai neh hoeh uh.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
Te te he tlam he ca uh. Na cinghen yen uh lamtah na khokhom te na kho dongah buenuh. Na conghol te na kut dongah pomuh. BOEIPA kah Yoom he thintawn la ca uh.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
Te khoyin ah Egypt khohmuen long ka pah vetih, Egypt kho kah caming boeih tah hlang lamloh rhamsa hil pataeng ka ngawn ni. Te vaengah BOEIPA kamah loh Egypt pathen boeih soah tholhphu ka thung ni.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
Thii he nangmih ham im dongah miknoek la om ni. Nangmih taengah thii te ka hmuh vaengah nangmih te kang kang vetih Egypt khohmuen ka ngawn vaengah khaw kutcaihnah tlohthae te nangmih ah om mahpawh.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Te phoeiah he khohnin he nangmih ham poekkoepnah la om saeh. Te vaengah BOEIPA taengah khotue neh lam uh. Na lam uh te na cadilcahma ham kumhal khosing la om saeh.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
Hnin rhih khuiah vaidamding ca uh. A cuek hnin ah tolrhu te na im lamloh toeng uh. Tolrhu aka ca boeih tah a hinglu te a cuek hnin lamloh a rhih hnin due Israel lamloh khoe saeh.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
A cuek khohnin kah a cim tingtunnah neh a rhih hnin kah a cim tingtunnah te nangmih ham om ni. Te vaengah bitat boeih he saii boel saeh. Tedae nangmih khuikah hinglu boeih loh a caak nawn te amah loh saii mai saeh.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Te khohnin kuelhuelh ah nangmih caempuei te Egypt kho lamloh kang khuen dongah vaidamding te ngaithuen. Te dongah na cadilcahma kah kumhal khosing dongah khaw he khohnin he ngaithuen uh.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
Lamhma ah hla sae hnin hlai li hlaem vaeng lamloh tekah hla hnin kul hnin khat hlaem duela vaidamding mah ca uh.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Hnin rhih hil na im ah tolrhu hmu boel saeh. tolrhu aka ca boeih tah yinlai khaw, khohmuen mupoe khaw Israel rhaengpuei lamloh hinglu hnawt pah saeh.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Tolrhu aka nuen boeih tah ca uh boel lamtah na tolrhum boeih ah vaidamding mah ca uh,” a ti nah.
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
Te phoeiah Moses loh Israel kah a hamca boeih te a khue tih amih te dangrhoek uh laeh, namah huiko ham boiva te namamih loh lo uh lamtah Yoom maeh te ngawn uh laeh.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
Te phoeiah pumpiding bong at lo uh lamtah baeldung dongkah thii khuiah nuem uh. Baeldung khuikah thii te danglo so neh rhungsut rhoi dongah hluk uh. Nangmih te hlang pakhat khaw mincang hil a im thohka lamloh moe uh boeh.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
Egypt vuek ham BOEIPA loh a pah vaengah danglo dongkah neh rhungsut rhoi dongkah thii te a hmuh vetih a kan ni. Aka vuek te na im thohka la kun ham khaw BOEIPA loh nang te kutcaihnah la n'khueh mahpawh.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
He ol he namah ham neh na ca ham khaw kumhal kah oltlueh la ngaithuen laeh.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
Nangmih taengah a thui vanbangla BOEIPA loh m'paek ham khohmuen la na pawk uh tue om bitni. Te vaengah he kah thothuengnah he ngaithuen uh.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
Na ca rhoek loh nangmih taengah, “Nangmih kah he mebang thothuengnah nim? aka ti khaw om ni.
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
Te vaengah, “He tah BOEIPA kah Yoom hmueih ni. Amah loh Egypt kah Israel ca imkhui te a kan dongah Egypt te a vuek tih mamih imkhui te n'huul,’ ti nah,” a ti nah. Te phoeiah pilnam te buluk tih a bawk uh.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
A caeh uh phoeiah khaw BOEIPA loh Moses neh Aaron a uen a saii rhoi vanbangla Israel ca rhoek long khaw a saii uh.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
Te phoeiah khoyin boengli a pha vaengah BOEIPA loh a ngolkhoel dongah aka ngol Pharaoh caming lamloh tangrhom im kah tamna caming neh rhamsa caming boeih, Egypt khohmuen kah caming boeih te a ngawn.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
Te dongah Pharaoh amah neh a sal boeih neh Egypt boeih tah khoyin ah thoo uh. Te vaengah aka duek pawh imkhui a om pawt dongah Egypt ah pangngawlnah muep om.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
Amah khoyin ah Moses neh Aaron te a khue tih, “Thoo lamtah ka pilnam lakli lamloh namah neh Israel ca rhoek khaw nong uh laeh. Na thui bangla cet uh lamtah Yahweh te thothueng uh.
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
Na boiva khaw, na saelhung khaw na thui uh bangla khuen uh. Cet uh lamtah kai khaw yoethen m'pae uh,” a ti nah.
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
Egypt loh, “Kaimih boeih ka duek uh coeng,” a ti uh. Te dongah amih te khohmuen lamloh tueih paitok ham te pilnam te a cahawh.
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
Te dongah pilnam loh a vaidambael dongkah tol a phul hlan a vaidamtlam te a himbai neh a boep uh tih a laengpang dongah a koh uh.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
Israel ca rhoek long khaw Moses ol bangla a saii tih Egypt rhoek taengah cak hnopai neh sui hnopai neh himbai te a hoe uh.
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
BOEIPA loh pilnam te Egypt mikhmuh ah mikdaithen la a khueh coeng dongah a hoe uh bangla Egypt kah te a huul pauh.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Te vaengah Sukkoth Raamses lamloh Israel ca rhoek aka cet te camoe a hoep phoeiah tongpa rhalkap thawng ya rhuk tluk louh.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
Namcom khaw amih taengah muep cet uh tih boiva neh saelhung boiva neh bahoeng yet uh.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
Egypt lamloh a khuen vaidamtlam te tol a phul pawt dongah vaidamding buh la a kaeng uh. Egypt lamloh a haek uh vaengah uelh ham a coeng pawt dongah amamih ham lampu khaw a saii uh moenih.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
Israel ca rhoek loh a tolrhum nah tih Egypt ah kho a sak uh te kum ya li neh kum sawmthum lo coeng.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Kum ya li neh kum sawmthum a bawtnah te a pha coeng. Te khohnin kuelhuelh te a pha vaengah tah BOEIPA kah caempuei boeih te Egypt kho lamloh khoe uh.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Tekah haknah hlaem ah BOEIPA loh amih te Egypt kho lamkah a khuen. He khoyin he Israel ca boeih a cadilcahma ham BOEIPA taengkah haknah la om.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
Te phoeiah BOEIPA loh Moses neh Aaron te, “Yoom kah khosing he tah, kholong ca boeih long tah te te ca boel saeh.
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
Tedae sal boeih khaw tangka neh a lai hlang te na rhet pah coeng atah tah te te ca saeh.
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Lampah neh kutloh long khaw te te ca boel saeh.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
Im pakhat ah ca saeh. Maeh te imkhui lamloh tol la khuen boel saeh. A rhuh khaw a khuiah paep sak boeh.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Israel rhaengpuei boeih loh te te saii saeh.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Na taengah yinlai bakuep tih BOEIPA taengkah Yoom ka saii eh a ti atah tongpa boeih te rhet pah saeh. Te daengah ni te te a saii vaengah nuen van vetih khohmuen mupoe bangla a om eh. Tedae pumdul boeih tah te te ca boel saeh.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Olkhueng he mupoe taeng neh nangmih lakli kah aka bakuep yinlai taengah pakhat la om saeh.
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
Te dongah BOEIPA loh a uen tih Moses neh Aaron loh a saii bangla Israel ca rhoek loh boeih a saii uh.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
Te khohnin kuelhuelh ah ni BOEIPA loh Israel ca rhoek te Egypt kho lamloh a caempuei neh a khuen.