< Exodus 12 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
Тогава Господ говори на Моисея и Аарона в Египетската земя, казвайки:
2 “Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
Тоя месец ще ви бъде началният месец; ще ви бъде първият месец на годината.
3 Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
Говорете на цялото Израилево общество, като им кажете да си вземат, на десетия ден от тоя месец, всеки по едно агне, според бащините си домове, по едно агне за всеки дом.
4 Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
Но ако домашните са малцина, за агнето, тогава домакинът и най-ближният до къщата му съсед нека вземат, според числото на човеците в тях; смятайте за агнето според онова, което всеки може да изяде.
5 Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
Агнето или ярето ви нека бъде без недостатък, едногодишно мъжко; от овците или от козите да го вземете.
6 Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
И да го пазите до четиринадесетия ден от същия месец; тогава цялото общество на израилтяните, събрани в домовете си да го заколят привечер.
7 Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
После нека вземат от кръвта и турят на двата стълба и на горния праг на вратата на къщите, гдето ще го ядат.
8 Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
През същата нощ нека ядат месото, печено на огън; с безквасен хляб и с горчиви треви да го ядат.
9 Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
Да не ядат от него сурово нито варено във вода, но изпечено на огън, с главата му, краката му и дреболиите му.
10 Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
И да не оставите нищо от него до утринта; ако остане нещо до утринта, изгорете го в огън.
11 Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
И така да го ядете; препасани през кръста си, с обущата на нозете си и тоягите в ръцете си; и да го ядете набързо, понеже е време на Господното минаване.
12 “Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
Защото в оная нощ ще мина през Египетската земя, и ще поразя всяко първородно в Египетската земя, и човек и животно; и ще извърша съдби против всичките египетски богове; Аз съм Иеова.
13 Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
И кръвта на къщите, гдето сте, ще ви служи за белег, така че, като видя кръвта, ще ви отмина, и когато поразя Египетската земя, няма да нападна върху вас, погубителна язва.
14 “Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Оня ден ще ви бъде за спомен, и ще го пазите като празник на Господа във всичките си поколения; вечен закон ще ви бъде, да го празнувате.
15 Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
Седем дни да ядете безквасен хляб; още на първия ден ще дигнете кваса от къщите си; защото, който яде квасно от първия ден до седмия ден, оня човек ще се изтреби от Израиля.
16 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
На първия ден ще имате свет събор, и на седмия ден свет събор; никаква работа да не се върши в тях, освен около онова, което е нужно за ядене на всеки; само това може да вършите.
17 “Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
Да пазите, прочее, празника на безквасните, защото в същия тоя ден изведох войнствата ви из Египетската земя; заради което ще ви бъде вечен закон да пазите тоя ден във всичките си поколения.
18 Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
От вечерта на четиринадесетия ден от първия месец до вечерта на двадесет и първия ден от месеца ще ядете безквасни хлябове.
19 Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
Седем дена да се не намира квас в къщите ви; защото който яде квасно, оня човек ще се изтреби отсред обществото на израилтяните, бил той пришелец или туземец.
20 Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
Нищо квасно да не ядете; във всичките си жилища безквасни хлябове да ядете.
21 Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
Тогава на четиринадесетия ден от месеца, Моисей повика всичките Израилеви старейшини и рече им: Идете та си вземете по едно агне според челядите си и заколете пасхата.
22 Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
После да вземете китка от исоп и да я потопите в кръвта, която ще приемете в леген, и с кръвта, що е в легена, да ударите по горния праг и двата стълба на къщната врата; и никой от вас да не излиза от къщната си врата до утринта.
23 Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
Защото Господ ще мине, за да порази египтяните, и когато види кръвта на горния праг и на двата стълба на вратата, Господ ще отмини вратата, и не ще остави погубителят да влезе в къщите ви, за да ви порази.
24 “Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
И ще пазите това като вечен закон за себе си и за синовете си.
25 Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
Когато влезете в земята, която Господ ще ви даде според обещанието си, ще пазите тая служба.
26 Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
И когато чадата ви попитат: Какво искате да кажете с тая служба?
27 Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
Ще отговорите: Това е жертва в спомен на минаването на Господа, който отмина къщите на израилтяните в Египет, когато поразяваше египтяните, а избави нашите къщи. Тогава людете се наведоха и се поклониха.
28 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
И израилтяните отидоха та сториха, според както Господ заповяда на Моисея и Аарона; така направиха.
29 Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
И по среднощ Господ порази всяко първородно в Египетската земя, от първородния на Фараона, който седеше на престола си, до първородния на пленника, който бе в затвора, както и всяко първородно от добитък.
30 Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
И Фараон стана през нощта, той и всичките му слуги, и всичките египтяни; и нададе се голям писък в Египет, защото нямаше къща без мъртвец.
31 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
И повика Моисея и Аарона още през нощта та рече: Станете и вие и израилтяните, излезте, изсред людете ми и идете, послужете на Иеова, както рекохте;
32 Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
подкарайте и овците си и стадата си, както рекохте, та идете; па благословете и мене.
33 Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
Тоже египтяните принуждаваха людете, за да ги отпратят по-скоро от земята си, защото си рекоха: Ние всички измираме.
34 Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
И людете дигнаха тестото си преди да вкисне, като носеха на рамена нощвите обвити в дрехите си.
35 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
А израилтяните бяха постъпили както Моисей беше казал, като бяха поискали от египтяните сребърни и златни вещи и дрехи;
36 Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
и Господ беше дал на людете да придобият благоволението на египтяните, тъй щото те бяха им дали колкото искаха. Така те обраха египтяните.
37 Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
Прочее, израилтяните се дигнаха от Рамесий за Сокхот, на брой около шестстотин хиляди мъже пешаци, освен челядите.
38 Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
Още с тях излезе и голямо разноплеменно множество, както и твърде много добитък - овци и говеда.
39 Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
А от тестото, което носеха из Египет, изпекоха безквасни пити; защото не беше вкиснало, понеже ги изпъдиха из Египет, и те не можаха да се бавят, нито да си приготвят ястие.
40 Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
А времето, което израилтяните прекараха като пришълци в Египет, беше четиристотин и тридесет години.
41 Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
И в края на четиристотин и тридесетте години, дори в същия ден, всички войнства Господни излязоха из Египетската земя.
42 Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
Това е нощ, която е за особено опазване за Господа, загдето ги изведе из Египетската земя; това е оная нощ, която всичките израилтяни, във всичките си поколения, трябва особено да пазят за Господа.
43 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
И Господ рече на Моисея и Аарона: Ето законът за пасхата: никой чужденец да не яде от нея;
44 Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
обаче всеки роб купен с пари да яде от нея тогава, когато се обреже.
45 ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
Никой пришелец или наемник да не яде от нея.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
В една къща да се изяде; от месото да не изнасяте вън от къщи и кост от нея да не строшите.
47 Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
Цялото общество израилтяни ще я пазят.
48 “Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
И ако би някой чужденец да живее като пришелец между тебе и да иска да пази пасхата Господу, нека се обрежат всичките му мъжки, и тогава нека да пристъпи да я пази; той ще бъде като туземец. Но никой необрязан не бива да яде от нея.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
Един закон ще има за туземеца и за чужденеца, който е пришелец между вас.
50 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
И всичките израилтяни сториха според както Господ заповяда на Моисея и Аарона; така направиха.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.
И тъй, в същия оня ден Господ изведе израилтяните из Египетската земя според устроените им войнства.

< Exodus 12 >