< Exodus 11 >

1 Nísinsin yìí, Olúwa sọ fún Mose pé èmi yóò mú ààrùn kan sí i wá sí orí Farao àti ilẹ̀ Ejibiti. Lẹ́yìn náà yóò jẹ́ kí ẹ̀yin kí ó lọ kúrò níhìn-ín yìí, nígbà tí ó bá sì ṣe bẹ́ẹ̀ yóò lé yín jáde pátápátá.
Yahvé dit à Moïse: « Je vais encore faire venir une plaie sur Pharaon et sur l'Égypte; ensuite, il vous laissera partir. Quand il vous laissera partir, il vous chassera tout à fait.
2 Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé kí tọkùnrin tobìnrin wọn béèrè fún ohun èlò fàdákà àti wúrà lọ́wọ́ aládùúgbò rẹ̀.
Parle maintenant aux oreilles du peuple, et que chaque homme demande à son voisin, et chaque femme à sa voisine, des bijoux d'argent et des bijoux d'or. »
3 (Olúwa jẹ́ kí wọn rí ojúrere àwọn ará Ejibiti, pàápàá, Mose fúnra rẹ̀ di ènìyàn pàtàkì ní ilẹ̀ Ejibiti ní iwájú àwọn ìjòyè Farao àti ní iwájú àwọn ènìyàn pẹ̀lú).
Yahvé accorda au peuple une faveur aux yeux des Égyptiens. D'ailleurs, l'homme Moïse était très grand au pays d'Égypte, aux yeux des serviteurs de Pharaon et aux yeux du peuple.
4 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Ní ọ̀gànjọ́ òru èmi yóò la ilẹ̀ Ejibiti kọjá.
Moïse répondit: « Voici ce que dit Yahvé: Vers minuit, je sortirai au milieu de l'Égypte,
5 Gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni yóò kùú, bẹ̀rẹ̀ lórí àkọ́bí ọkùnrin Farao tí ó jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀, tí ó fi dé orí àkọ́bí ọmọkùnrin ti ẹrúbìnrin tí ń lọ ọlọ àti gbogbo àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
et tous les premiers-nés du pays d'Égypte mourront, depuis le premier-né de Pharaon assis sur son trône jusqu'au premier-né de la servante qui est derrière le moulin, et tous les premiers-nés du bétail.
6 Igbe ẹkún ńlá yóò sọ jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti. Irú ohun búburú tí kò ṣẹlẹ̀ rí tí kò sí tún ni ṣẹlẹ̀ mọ́.
Il y aura dans tout le pays d'Égypte un grand cri, tel qu'il n'y en a jamais eu et qu'il n'y en aura plus.
7 Ṣùgbọ́n láàrín àwọn ará Israẹli ajá lásán kò ní gbó àwọn ènìyàn tàbí àwọn ẹran wọn.’ Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti fi ìyàtọ̀ sáàrín àwọn ará Ejibiti àti Israẹli.
Mais contre l'un des enfants d'Israël, un chien n'aboiera même pas et ne bougera pas la langue, ni contre un homme ni contre un animal, afin que vous sachiez que Yahvé fait une distinction entre les Égyptiens et Israël.
8 Gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ wọ̀nyí yóò tọ̀ mí wá, wọn yóò wólẹ̀ ni iwájú, mi wọn yóò sì máa wí pé, ‘Lọ àti àwọn ènìyàn tí ó tẹ̀lé ọ!’ Lẹ́yìn náà èmi yóò jáde.” Nígbà náà ni Mose fi ìbínú jáde kúrò ní iwájú Farao.
Tous tes serviteurs descendront vers moi et se prosterneront devant moi en disant: « Sors, avec tout le peuple qui te suit »; et après cela, je sortirai.'" Il sortit de chez Pharaon dans une colère ardente.
9 Olúwa ti sọ fún Mose pé, “Farao yóò kọ̀ láti fetísílẹ̀ sí ọ kí iṣẹ́ ìyanu mí le pọ̀ sí ní Ejibiti.”
Yahvé dit à Moïse: « Pharaon ne vous écoutera pas, afin que mes prodiges se multiplient dans le pays d'Égypte. »
10 Mose àti Aaroni ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí níwájú Farao, ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, òun kò sí jẹ́ kí àwọn Israẹli jáde kúrò ni orílẹ̀-èdè rẹ̀.
Moïse et Aaron firent tous ces prodiges devant Pharaon, mais Yahvé endurcit le cœur de Pharaon, qui ne laissa pas sortir les enfants d'Israël de son pays.

< Exodus 11 >