< Exodus 11 >
1 Nísinsin yìí, Olúwa sọ fún Mose pé èmi yóò mú ààrùn kan sí i wá sí orí Farao àti ilẹ̀ Ejibiti. Lẹ́yìn náà yóò jẹ́ kí ẹ̀yin kí ó lọ kúrò níhìn-ín yìí, nígbà tí ó bá sì ṣe bẹ́ẹ̀ yóò lé yín jáde pátápátá.
Og Herren sagde til Mose: Jeg vil endnu lade een Plage komme over Farao og over Ægypten, siden skal han lade eder fare herfra; naar han lader eder fare alle til Hobe, skal han endog drive eder herfra.
2 Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé kí tọkùnrin tobìnrin wọn béèrè fún ohun èlò fàdákà àti wúrà lọ́wọ́ aládùúgbò rẹ̀.
Sig nu for Folkets Øren, at de skulle begære, hver Mand af sin Næste og hver Kvinde af sin Næste, Sølvkar og Guldkar.
3 (Olúwa jẹ́ kí wọn rí ojúrere àwọn ará Ejibiti, pàápàá, Mose fúnra rẹ̀ di ènìyàn pàtàkì ní ilẹ̀ Ejibiti ní iwájú àwọn ìjòyè Farao àti ní iwájú àwọn ènìyàn pẹ̀lú).
Og Herren gav Folket Naade for Ægypternes Øjne, og Manden Mose var saare mægtig i Ægyptens Land for Faraos Tjeneres Øjne og for Folkets Øjne.
4 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Ní ọ̀gànjọ́ òru èmi yóò la ilẹ̀ Ejibiti kọjá.
Og Mose sagde: Saa siger Herren: Ved Midnat vil jeg gaa ud midt igennem Ægypten.
5 Gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni yóò kùú, bẹ̀rẹ̀ lórí àkọ́bí ọkùnrin Farao tí ó jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀, tí ó fi dé orí àkọ́bí ọmọkùnrin ti ẹrúbìnrin tí ń lọ ọlọ àti gbogbo àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
Og alle førstefødte i Ægyptens Land skulle dø, fra den førstefødte for Farao, som sidder paa sin Trone, indtil den førstefødte for Tjenestekvinden, som arbejder ved Kværnen, og alle førstefødte af Kvæg.
6 Igbe ẹkún ńlá yóò sọ jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti. Irú ohun búburú tí kò ṣẹlẹ̀ rí tí kò sí tún ni ṣẹlẹ̀ mọ́.
Og der skal blive et stort Skrig i det hele Ægyptens Land, hvis Lige ikke har været, og hvis Lige ikke skal blive mere.
7 Ṣùgbọ́n láàrín àwọn ará Israẹli ajá lásán kò ní gbó àwọn ènìyàn tàbí àwọn ẹran wọn.’ Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti fi ìyàtọ̀ sáàrín àwọn ará Ejibiti àti Israẹli.
Men hos alle Israels Børn skal ikke en Hund bjæffe med sin Tunge, enten mod Mennesker eller Kvæg, for at I skulle vide, at Herren gør Skilsmisse imellem Ægypterne og imellem Israel.
8 Gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ wọ̀nyí yóò tọ̀ mí wá, wọn yóò wólẹ̀ ni iwájú, mi wọn yóò sì máa wí pé, ‘Lọ àti àwọn ènìyàn tí ó tẹ̀lé ọ!’ Lẹ́yìn náà èmi yóò jáde.” Nígbà náà ni Mose fi ìbínú jáde kúrò ní iwájú Farao.
Da skulle alle disse dine Tjenere komme ned til mig og nedbøje sig for mig og sige: Gak ud, du og alt Folket, som er i Følge med dig, og derefter vil jeg gaa ud; og han gik ud fra Farao med fnysende Vrede.
9 Olúwa ti sọ fún Mose pé, “Farao yóò kọ̀ láti fetísílẹ̀ sí ọ kí iṣẹ́ ìyanu mí le pọ̀ sí ní Ejibiti.”
Og Herren havde sagt til Mose: Farao skal ikke høre eder, paa det mine Vidundere skulle blive mange i Ægyptens Land.
10 Mose àti Aaroni ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí níwájú Farao, ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, òun kò sí jẹ́ kí àwọn Israẹli jáde kúrò ni orílẹ̀-èdè rẹ̀.
Og Mose og Aron gjorde alle disse Vidundere for Farao; men Herren forhærdede Faraos Hjerte, og han lod ikke Israels Børn fare ud af sit Land.