< Exodus 10 >
1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Farao, mo ti ṣé àyà Farao le àti àyà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrín wọn.
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Intră la Faraon, pentru că i-am împietrit inima și inima servitorilor săi, ca să pot arăta aceste semne ale mele înaintea lui;
2 Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ ọmọ yín; bí mo ti jẹ àwọn ará Ejibiti ní yà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.”
Și ca să spui în urechile fiului tău și a fiului fiului tău, ce lucruri am lucrat în Egipt și semnele mele pe care le-am făcut printre ei, ca ei să știe că eu sunt DOMNUL.
3 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, tiwọn sí wí fún un pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó sìn mi.
Și Moise și Aaron au intrat la Faraon și i-au spus: Astfel vorbește DOMNUL Dumnezeul evreilor: Până când vei refuza să te umilești înaintea mea? Lasă poporul meu să plece, ca să îmi servească.
4 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn lọ, èmi yóò mú eṣú wa sí orílẹ̀-èdè rẹ ní ọ̀la.
Altfel, dacă refuzi să lași poporul meu să plece, iată, mâine voi aduce lăcustele în cuprinsul tău;
5 Wọn yóò bo gbogbo ilẹ̀. Wọn yóò ba ohun gbogbo tí ó kù fún ọ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́, tí ó fi dórí gbogbo igi tí ó ń dàgbà ni ilẹ̀ rẹ.
Și ele vor acoperi fața pământului, ca nimeni să nu poată vedea pământul; și ele vor mânca rămășița a ceea ce a scăpat, care ți-a rămas de la grindină, și vor mânca fiecare copac care crește pentru tine din câmp;
6 Wọn yóò kún gbogbo ilé rẹ àti ilé àwọn ìjòyè rẹ àti ilé gbogbo àwọn ará Ejibiti. Ohun ti baba rẹ tàbí baba baba rẹ kò tí ì rí láti ìgbà tí wọ́n ti wà ní ilẹ̀ náà títí di àkókò yìí.’” Nígbà náà ni Mose pẹ̀yìndà kúrò níwájú Farao.
Și ele vor umple casele tale și casele tuturor servitorilor tăi și casele tuturor egiptenilor, ceea ce nici părinții tăi, nici părinții părinților tăi nu au văzut, din ziua de când au fost pe pământ până în această zi. Și s-a întors și a ieșit de la Faraon.
7 Àwọn ìjòyè Farao sọ fún un, “Yóò ti pẹ́ to tí ọkùnrin yìí yóò máa jẹ́ ìkẹ́kùn fún wa? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí lọ, kí wọn kí ó le sìn Olúwa Ọlọ́run wọn. Ṣe ìwọ kò ṣe àkíyèsí síbẹ̀ pé, ilẹ̀ Ejibiti ti parun tán?”
Și servitorii lui Faraon i-au spus: Până când acest om va fi o cursă pentru noi? Lasă bărbații să plece, ca să servească pe DOMNUL Dumnezeul lor; încă nu știi că Egiptul este distrus?
8 Nígbà náà ni a mú Aaroni àti Mose padà wá sí iwájú Farao ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sìn Olúwa Ọlọ́run yín. Ṣùgbọ́n àwọn ta ni nínú yín ni yóò ha lọ.”
Și Moise și Aaron au fost aduși din nou la Faraon; iar el le-a spus: Mergeți, serviți DOMNULUI Dumnezeul vostru; dar cine sunt cei ce vor merge?
9 Mose dáhùn ó wí pé, “A ó lọ pẹ̀lú àwọn ọmọdé àti àgbà wa, pẹ̀lú àwọn ọmọ wa ọkùnrin àti ọmọ wa obìnrin pẹ̀lú agbo àgùntàn wa àti agbo màlúù wa nítorí pé a gbọdọ̀ ṣe àjọ fún Olúwa.”
Și Moise a spus: Vom merge cu tinerii noștri și cu bătrânii noștri, cu fiii noștri și cu fiicele noastre, cu turmele noastre și cu cirezile noastre vom merge, pentru că trebuie să ținem o sărbătoare DOMNULUI.
10 Farao sì wí pé, “Mo fi Olúwa búra pé èmi kí yóò jẹ́ kí ẹ lọ, pẹ̀lú àwọn obìnrin yín àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́, dájúdájú èrò ibi ní ń bẹ nínú yín.
Iar el le-a spus: DOMNUL să fie astfel cu voi, precum o să vă las să plecați și micuții voștri; vedeți că răul este înaintea voastră.
11 Rárá! Ọkùnrin yín nìkan ni kí ó lọ, láti lọ sin Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé èyí ni ẹ̀yin ń béèrè fún.” Wọ́n sì lé Mose àti Aaroni kúrò ní iwájú Farao.
Nu așa: duceți-vă acum, cei ce sunteți bărbați, și serviți DOMNULUI; căci aceasta ați dorit. Și au fost alungați din prezența lui Faraon.
12 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè lórí Ejibiti kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú bo gbogbo ilẹ̀, kí ó sì ba gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko wọn jẹ́, àní gbogbo ohun tí òjò yìnyín kò bàjẹ́ tan.”
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Întinde-ți mâna peste țara Egiptului pentru lăcuste, pentru ca ele să urce peste țara Egiptului și să mănânce fiecare iarbă a pământului, tot ce grindina a lăsat.
13 Nígbà náà ni Mose na ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ sórí ilẹ̀ Ejibiti, Olúwa sì mú kí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà ni gbogbo ọ̀sán àti ni gbogbo òru ni ọjọ́ náà. Ní òwúrọ̀ afẹ́fẹ́ náà ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú wá;
Și Moise și-a întins toiagul asupra țării Egiptului și DOMNUL a adus un vânt de est peste țară toată ziua aceea și toată noaptea; și când a fost dimineață, vântul de est a adus lăcustele.
14 wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n wà ní ibi gbogbo ní orí ilẹ̀ ní àìmoye, ṣáájú àkókò yìí kò sí irú ìyọnu eṣú bẹ́ẹ̀ rí, kò sì ní sí irú rẹ mọ́ lẹ́yìn èyí.
Și lăcustele au urcat peste toată țara Egiptului și s-au așezat foarte apăsătoare în tot cuprinsul Egiptului; înaintea lor nu au fost astfel de lăcuste ca ele, nici după ele nu vor fi asemenea.
15 Wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ tí ilẹ̀ fi di dúdú. Wọ́n ba gbogbo ohun tókù ní orí ilẹ̀ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́; gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ní inú oko àti gbogbo èso tí ó wà lórí igi. Kò sí ewé tí ó kù lórí igi tàbí lórí ohun ọ̀gbìn ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Căci ele au acoperit fața întregului pământ, așa că țara s-a întunecat; și au mâncat fiecare iarbă a pământului și tot rodul pomilor pe care grindina i-a lăsat; și nu a rămas niciun lucru verde în copaci, sau în ierburile câmpului, prin toată țara Egiptului.
16 Farao yára ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín àti sí i yín pẹ̀lú.
Atunci Faraon a trimis după Moise și Aaron în grabă și a spus: Eu am păcătuit împotriva DOMNULUI Dumnezeul vostru și împotriva voastră.
17 Nísinsin yìí ẹ dáríjì mi lẹ́ẹ̀kan sí i kí ẹ sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín kí ó lè mú ìpọ́njú yìí kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
De aceea acum iartă, te rog, păcatul meu numai de această dată și rugați pe DOMNUL Dumnezeul vostru să îndepărteze de la mine numai această moarte.
18 Nígbà náà ni Mose kúrò ní iwájú Farao ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Și a ieșit de la Faraon și l-a implorat pe DOMNUL.
19 Olúwa sì yí afẹ́fẹ́ náà padà di afẹ́fẹ́ líle láti apá ìwọ̀-oòrùn wá láti gbá àwọn eṣú náà kúrò ní orí ilẹ̀ Ejibiti lọ sínú Òkun Pupa. Bẹ́ẹ̀ ni ẹyọ eṣú kan kò ṣẹ́kù sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Și DOMNUL a întors un vânt foarte puternic din vest, care a îndepărtat lăcustele și le-a aruncat în Marea Roșie; nu a rămas nicio lăcustă în tot cuprinsul Egiptului.
20 Síbẹ̀ Olúwa ṣe àyà Farao le, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Dar DOMNUL a împietrit inima lui Faraon, așa că a refuzat să lase copiii lui Israel să plece.
21 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run kí òkùnkùn bá à le bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti; àní òkùnkùn biribiri.”
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Întinde-ți mâna spre cer, ca să fie întuneric peste țara Egiptului, un întuneric care să poată fi pipăit.
22 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run, òkùnkùn biribiri sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti fún ọjọ́ mẹ́ta. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli ní ìmọ́lẹ̀ ní ibi tí wọn ń gbé.
Și Moise și-a întins mâna spre cer; și a fost întuneric gros în toată țara Egiptului trei zile.
23 Kò sí ẹni tí ó le è ríran rí ẹlòmíràn tàbí kí ó kúrò ní ibi tí ó wà fún ọjọ́ mẹ́ta. Síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ni ìmọ́lẹ̀ ni gbogbo ibi tí wọ́n ń gbé.
Nu s-au văzut unul pe altul, nici nu s-a ridicat vreunul din locul lui pentru trei zile; dar toți copiii lui Israel au avut lumină în locuințele lor.
24 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose ó sì wí fún un pé, “Lọ sin Olúwa, kódà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé lè lọ pẹ̀lú yín, ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó fi agbo àgùntàn àti agbo màlúù yín sílẹ̀.”
Și Faraon a chemat pe Moise și a spus: Mergeți, serviți DOMNULUI; numai turmele voastre și cirezile voastre să rămână aici; micuții voștri să meargă de asemenea cu voi.
25 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Ìwọ gbọdọ̀ fún wa láààyè láti rú ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ sísun ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
Și Moise a spus: Tu trebuie să ne dai de asemenea sacrificii și ofrande arse, ca să sacrificăm DOMNULUI Dumnezeul nostru.
26 Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹsẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsin Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sin Olúwa.”
Vitele noastre de asemenea vor merge cu noi, nicio copită nu va rămâne, pentru că dintre ele trebuie să luăm pentru a servi DOMNULUI Dumnezeul nostru; și nu știm cu ce trebuie să servim pe DOMNUL, până ce nu mergem acolo.
27 Ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, kò sì ṣetán láti jẹ́ kí wọn lọ.
Dar DOMNUL a împietrit inima lui Faraon, iar el a refuzat să îi lase să plece.
28 Farao sọ fún Mose pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kùú.”
Și Faraon i-a spus: Du-te de la mine, ia seama la tine însuți; să nu mai vezi fața mea, pentru că în ziua când vei vedea fața mea vei muri.
29 Mose sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”
Iar Moise a spus: Tu ai vorbit bine, nu voi mai vedea fața ta.