< Exodus 10 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Farao, mo ti ṣé àyà Farao le àti àyà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrín wọn.
Rzekł zatem Pan do Mojżesza: Wnijdź do Faraona; bom Ja obciążył serce jego, i serce sług jego, abym czynił te znaki moje między nimi;
2 Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ ọmọ yín; bí mo ti jẹ àwọn ará Ejibiti ní yà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.”
Ażebyś opowiadał w uszach synów twoich, i wnuków twoich, com uczynił w Egipcie, i znaki moje, którem pokazał na nich, abyście wiedzieli, żem Ja Pan.
3 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, tiwọn sí wí fún un pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó sìn mi.
Wszedł tedy Mojżesz i Aaron do Faraona, i mówili mu: Tak mówi Pan, Bóg Hebrajczyków: Dokądże nie chcesz uniżyć się przede mną? Wypuść lud mój, aby mi służył.
4 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn lọ, èmi yóò mú eṣú wa sí orílẹ̀-èdè rẹ ní ọ̀la.
Bo jeźli nie będziesz chciał wypuścić ludu mego, oto ja przywiodę jutro szarańczę na granicę twoję,
5 Wọn yóò bo gbogbo ilẹ̀. Wọn yóò ba ohun gbogbo tí ó kù fún ọ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́, tí ó fi dórí gbogbo igi tí ó ń dàgbà ni ilẹ̀ rẹ.
Która okryje wierzch ziemi, że jej widać nie będzie, i zje ostatek pozostały, który wam został po gradzie, i pogryzie każde drzewo rodzące na polu.
6 Wọn yóò kún gbogbo ilé rẹ àti ilé àwọn ìjòyè rẹ àti ilé gbogbo àwọn ará Ejibiti. Ohun ti baba rẹ tàbí baba baba rẹ kò tí ì rí láti ìgbà tí wọ́n ti wà ní ilẹ̀ náà títí di àkókò yìí.’” Nígbà náà ni Mose pẹ̀yìndà kúrò níwájú Farao.
I na pełni domy twoje, i domy wszystkich sług twoich, i domy wszystkiego Egiptu, czego nie widzieli ojcowie twoi, i ojcowie ojców twoich od początku bytu swego na ziemi aż do tego dnia. A odwróciwszy się, wyszedł od Faraona.
7 Àwọn ìjòyè Farao sọ fún un, “Yóò ti pẹ́ to tí ọkùnrin yìí yóò máa jẹ́ ìkẹ́kùn fún wa? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí lọ, kí wọn kí ó le sìn Olúwa Ọlọ́run wọn. Ṣe ìwọ kò ṣe àkíyèsí síbẹ̀ pé, ilẹ̀ Ejibiti ti parun tán?”
Tedy rzekli słudzy Faraonowi do niego: Długoż będzie nam ten ku zgorszeniu? Wypuść te męże, aby służyli Panu Bogu swemu; zaż jeszcze nie wiesz, że zniszczył Egipt?
8 Nígbà náà ni a mú Aaroni àti Mose padà wá sí iwájú Farao ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sìn Olúwa Ọlọ́run yín. Ṣùgbọ́n àwọn ta ni nínú yín ni yóò ha lọ.”
I zawołano zaś Mojżesza z Aaronem do Faraona, i rzekł do nich: Idźcie, służcie Panu Bogu waszemu; którzyż to są, co pójdą?
9 Mose dáhùn ó wí pé, “A ó lọ pẹ̀lú àwọn ọmọdé àti àgbà wa, pẹ̀lú àwọn ọmọ wa ọkùnrin àti ọmọ wa obìnrin pẹ̀lú agbo àgùntàn wa àti agbo màlúù wa nítorí pé a gbọdọ̀ ṣe àjọ fún Olúwa.”
I odpowiedział Mojżesz: Z dziećmi naszemi i z starcami naszymi pójdziemy, z synami naszymi, i z córkami naszemi, z trzodami naszemi, i z bydłem naszem pójdziemy; bo święto Panu obchodzić mamy.
10 Farao sì wí pé, “Mo fi Olúwa búra pé èmi kí yóò jẹ́ kí ẹ lọ, pẹ̀lú àwọn obìnrin yín àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́, dájúdájú èrò ibi ní ń bẹ nínú yín.
Tedy im on rzekł: Niech tak będzie Pan z wami, i jako ja was puszczę, i dzieci wasze; patrzcie, że coś złego przed sobą macie.
11 Rárá! Ọkùnrin yín nìkan ni kí ó lọ, láti lọ sin Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé èyí ni ẹ̀yin ń béèrè fún.” Wọ́n sì lé Mose àti Aaroni kúrò ní iwájú Farao.
Nie tak; ale idźcie sami mężowie, a służcie Panu, ponieważ wy tego szukacie. I wygnał je od siebie Farao.
12 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè lórí Ejibiti kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú bo gbogbo ilẹ̀, kí ó sì ba gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko wọn jẹ́, àní gbogbo ohun tí òjò yìnyín kò bàjẹ́ tan.”
Potem Pan rzekł do Mojżesza: Wyciągnij rękę twą na ziemię Egipską dla szarańczy, aby przyszła na ziemię Egipską, a pożarła wszystko ziele na ziemi, wszystko, co zostało po gradzie.
13 Nígbà náà ni Mose na ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ sórí ilẹ̀ Ejibiti, Olúwa sì mú kí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà ni gbogbo ọ̀sán àti ni gbogbo òru ni ọjọ́ náà. Ní òwúrọ̀ afẹ́fẹ́ náà ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú wá;
I wyciągnął Mojżesz laskę swoję na ziemię Egipską, a Pan przywiódł wiatr wschodni na ziemię przez cały on dzień, i przez całą noc; a gdy było rano, wiatr wschodni przyniósł szarańczę.
14 wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n wà ní ibi gbogbo ní orí ilẹ̀ ní àìmoye, ṣáájú àkókò yìí kò sí irú ìyọnu eṣú bẹ́ẹ̀ rí, kò sì ní sí irú rẹ mọ́ lẹ́yìn èyí.
I przyszła szarańcza na wszystkę ziemię Egipską, i przypadła na wszystkie granice Egipskie bardzo ciężka; przedtem nie było tej podobnej szarańczy, i po niej nie będzie takowej.
15 Wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ tí ilẹ̀ fi di dúdú. Wọ́n ba gbogbo ohun tókù ní orí ilẹ̀ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́; gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ní inú oko àti gbogbo èso tí ó wà lórí igi. Kò sí ewé tí ó kù lórí igi tàbí lórí ohun ọ̀gbìn ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
I okryła wierzch wszystkiej ziemi, tak, iż ziemi znać nie było; a pożarła wszystkę trawę ziemi, i wszystek owoc drzewa, który został po gradzie, a nie zostało żadnej zieloności na drzewie i na trawie polnej we wszystkiej ziemi Egipskiej.
16 Farao yára ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín àti sí i yín pẹ̀lú.
Przetoż co rychlej Farao wezwał Mojżesza i Aarona, i rzekł: Zgrzeszyłem przeciwko Panu Bogu waszemu, i przeciwko wam.
17 Nísinsin yìí ẹ dáríjì mi lẹ́ẹ̀kan sí i kí ẹ sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín kí ó lè mú ìpọ́njú yìí kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
A teraz odpuść proszę grzech mój aby ten raz, a módlcie się Panu Bogu waszemu, aby oddalił ode mnie tylko tę śmierć.
18 Nígbà náà ni Mose kúrò ní iwájú Farao ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
I wyszedłszy Mojżesz od Faraona, modlił się Panu.
19 Olúwa sì yí afẹ́fẹ́ náà padà di afẹ́fẹ́ líle láti apá ìwọ̀-oòrùn wá láti gbá àwọn eṣú náà kúrò ní orí ilẹ̀ Ejibiti lọ sínú Òkun Pupa. Bẹ́ẹ̀ ni ẹyọ eṣú kan kò ṣẹ́kù sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
A obróciwszy Pan wiatr zachodni mocny bardzo, porwał szarańczę, i wrzucił ją do morza czerwonego, i nie została ani jedna szarańcza we wszystkich granicach Egipskich.
20 Síbẹ̀ Olúwa ṣe àyà Farao le, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli lọ.
I zatwardził Pan serce Faraonowe, i nie wypuścił synów Izraelskich.
21 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run kí òkùnkùn bá à le bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti; àní òkùnkùn biribiri.”
Tedy rzekł Pan do Mojżesza: Wyciągnij rękę twą ku niebu, a będą ciemności po ziemi Egipskiej, i macać ich będą.
22 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run, òkùnkùn biribiri sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti fún ọjọ́ mẹ́ta. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli ní ìmọ́lẹ̀ ní ibi tí wọn ń gbé.
I wyciągnął Mojżesz rękę swą ku niebu, i były ciemności gęste po wszystkiej ziemi Egipskiej przez trzy dni.
23 Kò sí ẹni tí ó le è ríran rí ẹlòmíràn tàbí kí ó kúrò ní ibi tí ó wà fún ọjọ́ mẹ́ta. Síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ni ìmọ́lẹ̀ ni gbogbo ibi tí wọ́n ń gbé.
Nie widział jeden drugiego, ani się kto ruszył z miejsca swego przez one trzy dni; lecz u wszystkich synów Izraelskich była światłość w mieszkaniach ich.
24 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose ó sì wí fún un pé, “Lọ sin Olúwa, kódà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé lè lọ pẹ̀lú yín, ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó fi agbo àgùntàn àti agbo màlúù yín sílẹ̀.”
A wezwawszy Farao Mojżesza, rzekł: Idźcie, służcie Panu; tylko trzody wasze, i bydła wasze niech zostaną, i dzieci wasze niech idą z wami.
25 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Ìwọ gbọdọ̀ fún wa láààyè láti rú ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ sísun ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
I odpowiedział Mojżesz: Owszem ty dasz do rąk naszych ofiary i całopalenia, które ofiarować będziemy Panu, Bogu naszemu.
26 Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹsẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsin Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sin Olúwa.”
Przetoż i dobytek nasz pójdzie z nami, a nie zostanie i kopyto; albowiem z tego weźmiemy do służby Panu, Bogu naszemu; bo my nie wiemy, czem służyć mamy Panu, aż tam przyjdziemy.
27 Ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, kò sì ṣetán láti jẹ́ kí wọn lọ.
I zatwardził Pan serce Faraonowe, i nie chciał ich puścić.
28 Farao sọ fún Mose pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kùú.”
I rzekł Farao do Mojżesza: Idź ode mnie, a strzeż się, abyś więcej nie widział oblicza mego; bo dnia, którego ujrzysz oblicze moje, umrzesz.
29 Mose sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”
I odpowiedział Mojżesz: Dobrześ powiedział; nie ujrzę więcej oblicza twego.

< Exodus 10 >