< Exodus 10 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Farao, mo ti ṣé àyà Farao le àti àyà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrín wọn.
OLELO mai la o Iehova ia Mose, E hele aku oe iloko io Parao la, no ke mea, ua hoopaakiki au i kona naau, a me ka naau o kana poe kauwa, i hoike aku ai au i keia mau hoailona o'u iwaena o lakou;
2 Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ ọmọ yín; bí mo ti jẹ àwọn ará Ejibiti ní yà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.”
A i hai aku ai oe maloko o na pepeiao o kau keiki, a o ke keiki a kau keiki i na mea a'u i hana'i ma Aigupita, a me ko'u mau hoailona a'u i hana aku ai ia lakou, i ike ai oukou, owau no Iehova.
3 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, tiwọn sí wí fún un pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó sìn mi.
Hele aku la o Mose laua o Aarona iloko io Parao la, i aku la ia ia, Ke i mai nei o Iehova, ke Akua o na Hebera, penei, Pehea la ka loihi o kou hoohaahaa ole ana ia oe iho imua o'u? E hookuu mai oe i ko'u poe kanaka, i hookauwa mai lakou na'u.
4 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn lọ, èmi yóò mú eṣú wa sí orílẹ̀-èdè rẹ ní ọ̀la.
Aka, ina e hoole oe, aole e hookuu mai i ko'u poe kanaka, aia hoi, i ka la apopo, e halihali mai no wau i na uhini ma kou aina.
5 Wọn yóò bo gbogbo ilẹ̀. Wọn yóò ba ohun gbogbo tí ó kù fún ọ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́, tí ó fi dórí gbogbo igi tí ó ń dàgbà ni ilẹ̀ rẹ.
A e uhi mai auanei lakou maluna o ka aina, aole e ikea ka aina ke nana aku: a e ai iho no lakou i ke koena o na mea i waihoia na oukou e ka huahekili: a e ai iho hoi lakou i na laau a pau e ulu ana no oukou ma ke kula.
6 Wọn yóò kún gbogbo ilé rẹ àti ilé àwọn ìjòyè rẹ àti ilé gbogbo àwọn ará Ejibiti. Ohun ti baba rẹ tàbí baba baba rẹ kò tí ì rí láti ìgbà tí wọ́n ti wà ní ilẹ̀ náà títí di àkókò yìí.’” Nígbà náà ni Mose pẹ̀yìndà kúrò níwájú Farao.
E hoopiha hoi lakou i na hale ou, a me na hale o kau poe kauwa a pau, a me na hale o ko Aigupita a pau: aole i ike kou poe makua i keia mea, aole hoi na makua o kou poe makua, mai ka wa i noho mai ai lakou ma ka honua, a hiki i keia la, Haliu ae la ia, a hele aku la mai o Parao aku.
7 Àwọn ìjòyè Farao sọ fún un, “Yóò ti pẹ́ to tí ọkùnrin yìí yóò máa jẹ́ ìkẹ́kùn fún wa? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí lọ, kí wọn kí ó le sìn Olúwa Ọlọ́run wọn. Ṣe ìwọ kò ṣe àkíyèsí síbẹ̀ pé, ilẹ̀ Ejibiti ti parun tán?”
Olelo aku la na kauwa a Parao ia ia, Pehea la ka loihi o ka hoohihia ana o keia kanaka ia kakou? E hookuu aku i ua poe kanaka la, i hookauwa aku ai lakou na Iehova na ko lakou Akua. Aole anei oe i ike i neia manawa, ua oki loa o Aigupita nei?
8 Nígbà náà ni a mú Aaroni àti Mose padà wá sí iwájú Farao ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sìn Olúwa Ọlọ́run yín. Ṣùgbọ́n àwọn ta ni nínú yín ni yóò ha lọ.”
Ua lawe hou ia aku o Mose laua o Aarona io Parao la, i mai la ia ia laua, E hele oukou, e hookauwa na Iehova na ko oukou Akua. Owai, owai hoi ka poe hele?
9 Mose dáhùn ó wí pé, “A ó lọ pẹ̀lú àwọn ọmọdé àti àgbà wa, pẹ̀lú àwọn ọmọ wa ọkùnrin àti ọmọ wa obìnrin pẹ̀lú agbo àgùntàn wa àti agbo màlúù wa nítorí pé a gbọdọ̀ ṣe àjọ fún Olúwa.”
I aku la o Mose, E hele pu no makou me ko makou poe opiopio a me ko makou poe elemakule, me na keikikane a me na kaikamahine a makou, me ka makou hipa, a me ka makou bipi makou e hele aku ai: no ka mea, he ahaaina ka makou no Iehova.
10 Farao sì wí pé, “Mo fi Olúwa búra pé èmi kí yóò jẹ́ kí ẹ lọ, pẹ̀lú àwọn obìnrin yín àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́, dájúdájú èrò ibi ní ń bẹ nínú yín.
I mai la kela ia laua, o Iehova kekahi pu me oukou, ke hookuu aku au ia oukou, e hele me ka oukou poe keiki. E malama ia olua, no ka mea, aia no ka hewa ma ko olua alo.
11 Rárá! Ọkùnrin yín nìkan ni kí ó lọ, láti lọ sin Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé èyí ni ẹ̀yin ń béèrè fún.” Wọ́n sì lé Mose àti Aaroni kúrò ní iwájú Farao.
Aole pela: o oukou na kanaka ke hele, e hookauwa aku na Iehova; no ka mea, oia ka oukou mea i imi mai nei. A ua kipakuia mai laua, mai ke alo mai o Parao.
12 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè lórí Ejibiti kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú bo gbogbo ilẹ̀, kí ó sì ba gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko wọn jẹ́, àní gbogbo ohun tí òjò yìnyín kò bàjẹ́ tan.”
I mai la o Iehova ia Mose, E o aku kou lima, maluna o ka aina o Aigupita no na uhini, i hele mai ai lakou maluna o ka aina o Aigupita, a e ai iho i na laauikiai a pau o ka aina, i na mea a pau i waihoia e ka huahekili.
13 Nígbà náà ni Mose na ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ sórí ilẹ̀ Ejibiti, Olúwa sì mú kí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà ni gbogbo ọ̀sán àti ni gbogbo òru ni ọjọ́ náà. Ní òwúrọ̀ afẹ́fẹ́ náà ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú wá;
O aku la o Mose i kona kookoo maluna o ka aina o Aigupita, a huai mai la o Iehova i ka makani mai ka hikina mai maluna o ka aina, ia la a po, ia po a ao; a i kakahiaka, hoopuka mai la ua makani hikina la i na uhini.
14 wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n wà ní ibi gbogbo ní orí ilẹ̀ ní àìmoye, ṣáájú àkókò yìí kò sí irú ìyọnu eṣú bẹ́ẹ̀ rí, kò sì ní sí irú rẹ mọ́ lẹ́yìn èyí.
Lele ae la na uhini maluna o ka aina a pau o Aigupita, a kau iho la ma na mokuna a pau o Aigupita: he ino loa; aohe uhini mamua e like ai, aole hoi e hiki mai ana mahope o lakou na mea e like ai.
15 Wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ tí ilẹ̀ fi di dúdú. Wọ́n ba gbogbo ohun tókù ní orí ilẹ̀ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́; gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ní inú oko àti gbogbo èso tí ó wà lórí igi. Kò sí ewé tí ó kù lórí igi tàbí lórí ohun ọ̀gbìn ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
No ka mea, uhi paapu iho la lakou i ka aina a pau, a poeleele hoi ka aina; ai iho la lakou i na laauikiai a pau o ka aina, a me ka hua a pau o na laau, a ka huahekili i waino mai ai; aole i koe kekahi mea uliuli ma na laau, a ma na laauikiai o ke kula, ma ka aina a pau o Aigupita.
16 Farao yára ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín àti sí i yín pẹ̀lú.
Alaila, wikiwiki ae la o Parao e hea mai ia Mose laua o Aarona, i mai la, Ua hana hewa wau ia Iehova i ko oukou Akua, a ia olua no hoi.
17 Nísinsin yìí ẹ dáríjì mi lẹ́ẹ̀kan sí i kí ẹ sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín kí ó lè mú ìpọ́njú yìí kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
Ke noi aku nei au, e kala mai no hoi olua i keia hewa hookahi ana no, a e nonoi aku ia Iehova ike oukou Akua, i lawe aku ai ia i keia make wale no, mai o'u aku nei.
18 Nígbà náà ni Mose kúrò ní iwájú Farao ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Hele aku la ia mai o Parao aku, a nonoi aku la ia Iehova.
19 Olúwa sì yí afẹ́fẹ́ náà padà di afẹ́fẹ́ líle láti apá ìwọ̀-oòrùn wá láti gbá àwọn eṣú náà kúrò ní orí ilẹ̀ Ejibiti lọ sínú Òkun Pupa. Bẹ́ẹ̀ ni ẹyọ eṣú kan kò ṣẹ́kù sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Huai hou mai la o Iehova i makani komohana ikaika, a lawe aku la ia i na uhini, a hoopaa iho la ia lakou iloko o ke Kaiula. Aohe uhini hookahi i koe ma ka aina a pau i Aigupita.
20 Síbẹ̀ Olúwa ṣe àyà Farao le, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Aka, hoopaakiki iho la o Iehova i ko Parao naau, aole ia hookuu aku i na mamo a Iseraela.
21 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run kí òkùnkùn bá à le bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti; àní òkùnkùn biribiri.”
I mai la o Iehova ia Mose, E o aku kou lima i ka lani, i kau mai ka poeleele maluna o ka aina o Aigupita, i aaki ka pouli.
22 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run, òkùnkùn biribiri sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti fún ọjọ́ mẹ́ta. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli ní ìmọ́lẹ̀ ní ibi tí wọn ń gbé.
O aku la no ko Mose lima i ka lani, a pouli loa iho la ka aina a pau o Aigupita i na la ekolu.
23 Kò sí ẹni tí ó le è ríran rí ẹlòmíràn tàbí kí ó kúrò ní ibi tí ó wà fún ọjọ́ mẹ́ta. Síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ni ìmọ́lẹ̀ ni gbogbo ibi tí wọ́n ń gbé.
Aole loa lakou i ike i kekahi i kekahi, aole hoi i ala ae kekahi mai kona wahi ae, i na la ekolu; aka, o na mamo a pau a Iseraela, he malamalama ko lakou iloko o ko lakou mau hale.
24 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose ó sì wí fún un pé, “Lọ sin Olúwa, kódà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé lè lọ pẹ̀lú yín, ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó fi agbo àgùntàn àti agbo màlúù yín sílẹ̀.”
Hea mai la o Parao ia Mose, i mai la, Ou haele oukou, e hookauwa aku na Iehova; aka, o ka oukou hipa, a me ka oukou bipi, e waiho ia lakou: e hele pu no hoi ka oukou poe keiki.
25 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Ìwọ gbọdọ̀ fún wa láààyè láti rú ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ sísun ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
I aku la o Mose, E haawi mai hoi iloko o ko makou mau lima, i na mohai, a me na mohai kuni, i kanmaha aku ai makou na Iehova na ko makou Akua.
26 Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹsẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsin Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sin Olúwa.”
E hele pu no hoi ka makou holoholona, aole e waihoia kekahi maanei; no ka mea, e lawe ana makou i na mea o lakou e malama'i ia Iehova i ko makou Akua: aole nae makou e ike i na mea o lakou ka makou e malama ai ia Iehova, a hiki aku makou ilaila.
27 Ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, kò sì ṣetán láti jẹ́ kí wọn lọ.
Aka, hoopaakiki mai la o Iehova i ka naau o Parao, aole no ia i hookuu ia lakou.
28 Farao sọ fún Mose pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kùú.”
I mai la o Parao ia ia, E hele aku oe pela, mai o'u aku nei, e malama ia oe iho, aole e ike hou mai i ko'u maka, no ka mea, i ka la au e nana hou mai ai i ko'u maka, e make oe.
29 Mose sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”
I aku la o Mose ia ia, Ua olelo pono mai oe; aole au e ike hou aku i kou maka.

< Exodus 10 >