< Exodus 10 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Farao, mo ti ṣé àyà Farao le àti àyà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrín wọn.
Et le Seigneur parla à Moïse, disant: Entre vers le Pharaon, car j'ai endurci son cœur et celui des hommes de sa maison, afin qu'à l'avenir ces signes arrivent sur eux,
2 Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ ọmọ yín; bí mo ti jẹ àwọn ará Ejibiti ní yà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.”
Et que vous racontiez à vos enfants, et aux enfants de vos enfants, comment les Égyptiens m'auront servi de jouet, et les signes que j'aurai faits chez eux; ainsi vous connaîtrez que je suis le Seigneur.
3 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, tiwọn sí wí fún un pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó sìn mi.
Moïse, avec son frère, entra donc chez le Pharaon, et il lui dit: Voici ce que dit le Seigneur Dieu des Hébreux: Jusqu'à quand refuseras-tu de me révérer? Renvoie mon peuple, afin qu'il m'offre un sacrifice.
4 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn lọ, èmi yóò mú eṣú wa sí orílẹ̀-èdè rẹ ní ọ̀la.
Si tu refuses de renvoyer mon peuple, demain, à pareille heure, je ferai venir sur ce territoire une multitude de sauterelles,
5 Wọn yóò bo gbogbo ilẹ̀. Wọn yóò ba ohun gbogbo tí ó kù fún ọ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́, tí ó fi dórí gbogbo igi tí ó ń dàgbà ni ilẹ̀ rẹ.
Qui couvrira la face de la terre; tu ne pourras voir la terre; et tout ce qui sort de terre, tout ce qu'a épargné la grêle, tout arbre qui germe pour vous sur ce territoire sera dévoré.
6 Wọn yóò kún gbogbo ilé rẹ àti ilé àwọn ìjòyè rẹ àti ilé gbogbo àwọn ará Ejibiti. Ohun ti baba rẹ tàbí baba baba rẹ kò tí ì rí láti ìgbà tí wọ́n ti wà ní ilẹ̀ náà títí di àkókò yìí.’” Nígbà náà ni Mose pẹ̀yìndà kúrò níwájú Farao.
Tes demeures en seront remplies, ainsi que les maisons de tes serviteurs et toute habitation en la terre d'Égypte. Jamais vos pères ni vos ancêtres n'ont vu pareilles choses, depuis le jour où ils sont venus en cette contrée jusqu'à aujourd'hui. Et Moïse, s'étant détourné, quitta le Pharaon.
7 Àwọn ìjòyè Farao sọ fún un, “Yóò ti pẹ́ to tí ọkùnrin yìí yóò máa jẹ́ ìkẹ́kùn fún wa? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí lọ, kí wọn kí ó le sìn Olúwa Ọlọ́run wọn. Ṣe ìwọ kò ṣe àkíyèsí síbẹ̀ pé, ilẹ̀ Ejibiti ti parun tán?”
Alors, les serviteurs du Pharaon dirent au roi: Jusqu'à quand subsistera ce scandale? Renvoie ces hommes, afin qu'ils sacrifient à leur Dieu; préfères-tu apprendre que l'Égypte a péri?
8 Nígbà náà ni a mú Aaroni àti Mose padà wá sí iwájú Farao ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sìn Olúwa Ọlọ́run yín. Ṣùgbọ́n àwọn ta ni nínú yín ni yóò ha lọ.”
Ils firent ainsi revenir auprès du Pharaon Moïse et son frère, et le roi leur dit: Allez et sacrifiez à votre Dieu; mais quels sont ceux qui doivent partir?
9 Mose dáhùn ó wí pé, “A ó lọ pẹ̀lú àwọn ọmọdé àti àgbà wa, pẹ̀lú àwọn ọmọ wa ọkùnrin àti ọmọ wa obìnrin pẹ̀lú agbo àgùntàn wa àti agbo màlúù wa nítorí pé a gbọdọ̀ ṣe àjọ fún Olúwa.”
Et Moïse dit: Nous partirons avec nos jeunes hommes et nos vieillards, avec nos fils et nos filles, avec nos brebis et nos bœufs, car c'est la fête du Seigneur.
10 Farao sì wí pé, “Mo fi Olúwa búra pé èmi kí yóò jẹ́ kí ẹ lọ, pẹ̀lú àwọn obìnrin yín àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́, dájúdájú èrò ibi ní ń bẹ nínú yín.
Et il répondit: Que le Seigneur soit avec vous, comme je vous renvoie; laisserai-je donc échapper vos possessions aussi; vous voyez que la malice réside en vous.
11 Rárá! Ọkùnrin yín nìkan ni kí ó lọ, láti lọ sin Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé èyí ni ẹ̀yin ń béèrè fún.” Wọ́n sì lé Mose àti Aaroni kúrò ní iwájú Farao.
Non pas ainsi; mais que les hommes portent ce qu'ils sacrifient au Seigneur, puisque c'est ce que vous demandez. Et on les chassa de la présence du Pharaon.
12 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè lórí Ejibiti kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú bo gbogbo ilẹ̀, kí ó sì ba gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko wọn jẹ́, àní gbogbo ohun tí òjò yìnyín kò bàjẹ́ tan.”
Le Seigneur dit alors à Moïse: Étends la main sur la terre d'Égypte, que des sauterelles montent sur la terre; qu'elles dévorent toutes les herbes de la contrée, et tous les fruits des arbres qu'a épargnés la grêle.
13 Nígbà náà ni Mose na ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ sórí ilẹ̀ Ejibiti, Olúwa sì mú kí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà ni gbogbo ọ̀sán àti ni gbogbo òru ni ọjọ́ náà. Ní òwúrọ̀ afẹ́fẹ́ náà ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú wá;
Moïse leva sa baguette vers le ciel, et le Seigneur envoya sur la terre un vent du midi, tout le jour et toute la nuit suivante; dès que l'aurore parut, le vent du midi amena les sauterelles.
14 wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n wà ní ibi gbogbo ní orí ilẹ̀ ní àìmoye, ṣáájú àkókò yìí kò sí irú ìyọnu eṣú bẹ́ẹ̀ rí, kò sì ní sí irú rẹ mọ́ lẹ́yìn èyí.
Il les répandit sur toute la terre d'Égypte, il les fit tomber en innombrables multitudes sur tout le territoire de l'Égypte. Jamais auparavant il n'était venu pareille nuée de sauterelles, et, après celle-là, jamais il n'en sera de semblable.
15 Wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ tí ilẹ̀ fi di dúdú. Wọ́n ba gbogbo ohun tókù ní orí ilẹ̀ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́; gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ní inú oko àti gbogbo èso tí ó wà lórí igi. Kò sí ewé tí ó kù lórí igi tàbí lórí ohun ọ̀gbìn ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Elle couvrit toute la face de la terre, et la terre en fut dévastée; elle dévora toutes les herbes de la terre, et tous les fruits des arbres que la grêle avait épargnés. Il ne resta rien de vert, ni sur les arbres, ni aux champs, dans toute la terre d'Égypte.
16 Farao yára ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín àti sí i yín pẹ̀lú.
Aussitôt, le Pharaon appela Moïse et son frère, et il leur dit: J'ai péché contre le Seigneur votre Dieu et contre vous.
17 Nísinsin yìí ẹ dáríjì mi lẹ́ẹ̀kan sí i kí ẹ sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín kí ó lè mú ìpọ́njú yìí kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
Remettez-moi encore cette fois mon péché, et priez le Seigneur votre Dieu, pour qu'il me délivre de ce fléau.
18 Nígbà náà ni Mose kúrò ní iwájú Farao ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Moïse quitta le Pharaon, et pria le Seigneur.
19 Olúwa sì yí afẹ́fẹ́ náà padà di afẹ́fẹ́ líle láti apá ìwọ̀-oòrùn wá láti gbá àwọn eṣú náà kúrò ní orí ilẹ̀ Ejibiti lọ sínú Òkun Pupa. Bẹ́ẹ̀ ni ẹyọ eṣú kan kò ṣẹ́kù sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
Et le Seigneur envoya du nord un vent violent qui enleva les sauterelles et les jeta dans la mer Rouge. Il ne resta pas une seule sauterelle en toute l'Égypte.
20 Síbẹ̀ Olúwa ṣe àyà Farao le, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Mais le Seigneur endurcit le cœur du Pharaon, et celui-ci ne congédia pas les fils d'Israël.
21 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run kí òkùnkùn bá à le bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti; àní òkùnkùn biribiri.”
Et le Seigneur dit à Moïse: Étends la main vers le ciel, et que des ténèbres enveloppent la terre d'Égypte, des ténèbres palpables.
22 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run, òkùnkùn biribiri sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti fún ọjọ́ mẹ́ta. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli ní ìmọ́lẹ̀ ní ibi tí wọn ń gbé.
Moïse étendit donc la main vers le ciel, et il vint des ténèbres, un sombre tourbillon, qui enveloppa l’Égypte durant trois jours.
23 Kò sí ẹni tí ó le è ríran rí ẹlòmíràn tàbí kí ó kúrò ní ibi tí ó wà fún ọjọ́ mẹ́ta. Síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ni ìmọ́lẹ̀ ni gbogbo ibi tí wọ́n ń gbé.
Pendant trois jours nul ne vit son frère: ces trois jours durant, nul ne se leva de sa couche; quant aux fils d'Israël, la lumière était en tous les lieux où ils se trouvaient.
24 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose ó sì wí fún un pé, “Lọ sin Olúwa, kódà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé lè lọ pẹ̀lú yín, ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó fi agbo àgùntàn àti agbo màlúù yín sílẹ̀.”
Le Pharaon appela encore Aaron et Moïse, disant: Allez, sacrifiez au Seigneur votre Dieu; quant à vos brebis et vos bœufs, vous les laisserez; mais que vos bagages s'en aillent avec vous.
25 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Ìwọ gbọdọ̀ fún wa láààyè láti rú ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ sísun ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
Et Moïse dit au Pharaon: Tu nous accorderas encore des holocaustes et des victimes que nous offrirons au Seigneur notre Dieu.
26 Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹsẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsin Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sin Olúwa.”
Nos troupeaux doivent partir avec nous et nous n'en laisserons pas une corne, car c'est parmi eux que nous prendrons les victimes pour le Seigneur notre Dieu. Nous ne pouvons savoir ce que nous sacrifierons au Seigneur notre Dieu, avant d'être arrivés là.
27 Ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, kò sì ṣetán láti jẹ́ kí wọn lọ.
Mais le Seigneur endurcit le cœur du Pharaon; et il ne voulut point les laisser partir.
28 Farao sọ fún Mose pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kùú.”
Et le Pharaon dit: Éloigne-toi de ma présence, garde-toi de voir encore mon visage, car le jour où je te verrai, tu mourras.
29 Mose sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”
Et Moïse reprit: Tu l'as dit, je ne paraîtrai plus devant ta face.

< Exodus 10 >