< Exodus 10 >
1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Farao, mo ti ṣé àyà Farao le àti àyà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrín wọn.
Yahvé dit à Moïse: « Va vers Pharaon, car j'ai endurci son cœur et le cœur de ses serviteurs, afin de montrer mes signes au milieu d'eux;
2 Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ ọmọ yín; bí mo ti jẹ àwọn ará Ejibiti ní yà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.”
et afin que tu racontes à ton fils et au fils de ton fils ce que j'ai fait à l'Égypte et les signes que j'ai accomplis au milieu d'eux, pour que tu saches que je suis Yahvé. »
3 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, tiwọn sí wí fún un pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó sìn mi.
Moïse et Aaron allèrent trouver Pharaon et lui dirent: « Voici ce que dit Yahvé, le Dieu des Hébreux: « Jusqu'à quand refuseras-tu de t'humilier devant moi? Laisse partir mon peuple, afin qu'il me serve.
4 Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn lọ, èmi yóò mú eṣú wa sí orílẹ̀-èdè rẹ ní ọ̀la.
Ou bien, si vous refusez de laisser partir mon peuple, voici que demain je ferai venir des sauterelles dans votre pays,
5 Wọn yóò bo gbogbo ilẹ̀. Wọn yóò ba ohun gbogbo tí ó kù fún ọ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́, tí ó fi dórí gbogbo igi tí ó ń dàgbà ni ilẹ̀ rẹ.
et elles couvriront la surface de la terre, de sorte qu'on ne pourra plus voir la terre. Elles mangeront le reste de ce qui s'est échappé, ce qui vous reste de la grêle, et elles mangeront tout arbre qui pousse pour vous dans les champs.
6 Wọn yóò kún gbogbo ilé rẹ àti ilé àwọn ìjòyè rẹ àti ilé gbogbo àwọn ará Ejibiti. Ohun ti baba rẹ tàbí baba baba rẹ kò tí ì rí láti ìgbà tí wọ́n ti wà ní ilẹ̀ náà títí di àkókò yìí.’” Nígbà náà ni Mose pẹ̀yìndà kúrò níwájú Farao.
Tes maisons seront remplies, ainsi que celles de tous tes serviteurs et de tous les Égyptiens, comme n'en ont jamais vu ni tes pères ni les pères de tes pères, depuis le jour où ils ont été sur la terre jusqu'à ce jour.'" Il se retourna, et sortit de chez Pharaon.
7 Àwọn ìjòyè Farao sọ fún un, “Yóò ti pẹ́ to tí ọkùnrin yìí yóò máa jẹ́ ìkẹ́kùn fún wa? Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí lọ, kí wọn kí ó le sìn Olúwa Ọlọ́run wọn. Ṣe ìwọ kò ṣe àkíyèsí síbẹ̀ pé, ilẹ̀ Ejibiti ti parun tán?”
Les serviteurs de Pharaon lui dirent: « Jusqu'à quand cet homme sera-t-il un piège pour nous? Laisse partir ces hommes, afin qu'ils servent Yahvé, leur Dieu. Ne sais-tu pas encore que l'Égypte est détruite? »
8 Nígbà náà ni a mú Aaroni àti Mose padà wá sí iwájú Farao ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sìn Olúwa Ọlọ́run yín. Ṣùgbọ́n àwọn ta ni nínú yín ni yóò ha lọ.”
Moïse et Aaron furent ramenés auprès de Pharaon, qui leur dit: « Allez, servez Yahvé votre Dieu; mais qui sont ceux qui iront? »
9 Mose dáhùn ó wí pé, “A ó lọ pẹ̀lú àwọn ọmọdé àti àgbà wa, pẹ̀lú àwọn ọmọ wa ọkùnrin àti ọmọ wa obìnrin pẹ̀lú agbo àgùntàn wa àti agbo màlúù wa nítorí pé a gbọdọ̀ ṣe àjọ fún Olúwa.”
Moïse dit: « Nous irons avec nos jeunes et nos vieux, nous irons avec nos fils et nos filles, avec nos brebis et nos bœufs. Nous irons avec nos fils et nos filles, avec nos brebis et nos bœufs, car nous devons faire une fête à Yahvé. »
10 Farao sì wí pé, “Mo fi Olúwa búra pé èmi kí yóò jẹ́ kí ẹ lọ, pẹ̀lú àwọn obìnrin yín àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́, dájúdájú èrò ibi ní ń bẹ nínú yín.
Il leur dit: « Que Yahvé soit avec vous si je vous laisse partir avec vos petits enfants! Voyez, le mal est clairement devant vos yeux.
11 Rárá! Ọkùnrin yín nìkan ni kí ó lọ, láti lọ sin Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí ó jẹ́ pé èyí ni ẹ̀yin ń béèrè fún.” Wọ́n sì lé Mose àti Aaroni kúrò ní iwájú Farao.
Mais non! Allez maintenant, vous qui êtes des hommes, et servez Yahvé, car c'est ce que vous voulez! ». Et ils furent chassés de la présence de Pharaon.
12 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè lórí Ejibiti kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú bo gbogbo ilẹ̀, kí ó sì ba gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko wọn jẹ́, àní gbogbo ohun tí òjò yìnyín kò bàjẹ́ tan.”
Yahvé dit à Moïse: « Étends ta main sur le pays d'Égypte pour les sauterelles, afin qu'elles montent sur le pays d'Égypte et mangent toutes les herbes du pays, tout ce que la grêle a laissé. »
13 Nígbà náà ni Mose na ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ sórí ilẹ̀ Ejibiti, Olúwa sì mú kí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn fẹ́ kọjá lórí ilẹ̀ náà ni gbogbo ọ̀sán àti ni gbogbo òru ni ọjọ́ náà. Ní òwúrọ̀ afẹ́fẹ́ náà ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣú wá;
Moïse étendit sa verge sur le pays d'Égypte, et Yahvé fit souffler un vent d'est sur le pays tout ce jour-là et toute la nuit; et au matin, le vent d'est amena les sauterelles.
14 wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n wà ní ibi gbogbo ní orí ilẹ̀ ní àìmoye, ṣáájú àkókò yìí kò sí irú ìyọnu eṣú bẹ́ẹ̀ rí, kò sì ní sí irú rẹ mọ́ lẹ́yìn èyí.
Les sauterelles montèrent sur tout le pays d'Égypte, et se posèrent dans tout le territoire de l'Égypte. Elles étaient très nuisibles. Avant elles, il n'y avait pas eu de sauterelles comme elles, et il n'y en aura plus jamais.
15 Wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ tí ilẹ̀ fi di dúdú. Wọ́n ba gbogbo ohun tókù ní orí ilẹ̀ lẹ́yìn òjò yìnyín jẹ́; gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ní inú oko àti gbogbo èso tí ó wà lórí igi. Kò sí ewé tí ó kù lórí igi tàbí lórí ohun ọ̀gbìn ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Car elles couvrirent toute la surface de la terre, au point d'obscurcir le pays, et elles mangèrent toutes les herbes du pays et tous les fruits des arbres que la grêle avait laissés. Il ne resta rien de vert, ni arbre ni herbe des champs, dans tout le pays d'Égypte.
16 Farao yára ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín àti sí i yín pẹ̀lú.
Pharaon appela en hâte Moïse et Aaron, et dit: « J'ai péché contre Yahvé ton Dieu et contre toi.
17 Nísinsin yìí ẹ dáríjì mi lẹ́ẹ̀kan sí i kí ẹ sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín kí ó lè mú ìpọ́njú yìí kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
Maintenant, pardonne-moi encore mon péché, et prie Yahvé ton Dieu, afin qu'il éloigne de moi cette mort. »
18 Nígbà náà ni Mose kúrò ní iwájú Farao ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Moïse sortit de chez Pharaon et pria l'Éternel.
19 Olúwa sì yí afẹ́fẹ́ náà padà di afẹ́fẹ́ líle láti apá ìwọ̀-oòrùn wá láti gbá àwọn eṣú náà kúrò ní orí ilẹ̀ Ejibiti lọ sínú Òkun Pupa. Bẹ́ẹ̀ ni ẹyọ eṣú kan kò ṣẹ́kù sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
L'Éternel envoya un vent d'ouest très fort, qui emporta les sauterelles et les chassa dans la mer Rouge. Il ne resta pas une seule sauterelle dans tout le territoire de l'Égypte.
20 Síbẹ̀ Olúwa ṣe àyà Farao le, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Mais Yahvé endurcit le cœur de Pharaon, qui ne laissa pas partir les enfants d'Israël.
21 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run kí òkùnkùn bá à le bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti; àní òkùnkùn biribiri.”
Yahvé dit à Moïse: « Étends ta main vers le ciel, afin qu'il y ait des ténèbres sur le pays d'Égypte, des ténèbres qu'on puisse sentir. »
22 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ojú ọ̀run, òkùnkùn biribiri sì bo gbogbo ilẹ̀ Ejibiti fún ọjọ́ mẹ́ta. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli ní ìmọ́lẹ̀ ní ibi tí wọn ń gbé.
Moïse étendit sa main vers le ciel et il y eut une obscurité épaisse dans tout le pays d'Égypte pendant trois jours.
23 Kò sí ẹni tí ó le è ríran rí ẹlòmíràn tàbí kí ó kúrò ní ibi tí ó wà fún ọjọ́ mẹ́ta. Síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ni ìmọ́lẹ̀ ni gbogbo ibi tí wọ́n ń gbé.
On ne se voyait pas les uns les autres, et personne ne se leva de sa place pendant trois jours; mais tous les enfants d'Israël avaient de la lumière dans leurs habitations.
24 Farao sì ránṣẹ́ pe Mose ó sì wí fún un pé, “Lọ sin Olúwa, kódà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé lè lọ pẹ̀lú yín, ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó fi agbo àgùntàn àti agbo màlúù yín sílẹ̀.”
Pharaon appela Moïse et dit: « Va, sers Yahvé. Laisse seulement tes brebis et tes bœufs en arrière. Laisse aussi tes petits enfants aller avec toi. »
25 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Ìwọ gbọdọ̀ fún wa láààyè láti rú ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ sísun ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
Moïse dit: « Tu dois aussi remettre entre nos mains des sacrifices et des holocaustes, afin que nous puissions offrir des sacrifices à Yahvé, notre Dieu.
26 Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹsẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsin Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sin Olúwa.”
Notre bétail aussi partira avec nous. Pas un seul sabot ne sera laissé en arrière, car c'est de lui que nous devons prendre pour servir Yahvé notre Dieu; et nous ne savons pas avec quoi nous devons servir Yahvé, jusqu'à ce que nous y arrivions. »
27 Ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Farao le, kò sì ṣetán láti jẹ́ kí wọn lọ.
Mais Yahvé endurcit le cœur de Pharaon, qui ne voulut pas les laisser partir.
28 Farao sọ fún Mose pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kùú.”
Pharaon lui dit: « Éloigne-toi de moi! Prends garde de ne plus voir mon visage, car le jour où tu verras mon visage, tu mourras! ».
29 Mose sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”
Moïse dit: « Tu as bien parlé. Je ne verrai plus jamais ton visage. »