< Exodus 1 >

1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
Och dessa äro namnen på Israels söner, som kommo till Egypten; med Jakob kommo de, var och en med sitt hus:
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Ruben, Simeon, Levi och Juda,
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Isaskar, Sebulon och Benjamin,
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dan och Naftali, Gad och Aser.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
Tillsammans utgjorde de som hade utgått från Jakobs länd sjuttio personer; men Josef var redan förut i Egypten.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
Och Josef dog och alla hans bröder och hela det släktet.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
Men Israels barn voro fruktsamma och växte till och förökade sig och blevo övermåttan talrika, så att landet blev uppfyllt av dem.
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
Då uppstod en ny konung över Egypten, en som icke visste av Josef.
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
Och denne sade till sitt folk: "Se, Israels barns folk är oss för stort och mäktigt.
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
Välan, låt oss då gå klokt till väga med dem; eljest kunde de ännu mer föröka sig; och om ett krig komme på, kunde de förena sig med våra fiender och begynna krig mot oss och sedan draga bort ur landet."
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
Alltså satte man arbetsfogdar över dem och förtryckte dem med trälarbeten. Och de måste bygga åt Farao förrådsstäder, Pitom och Raamses.
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
Men ju mer man förtryckte dem, dess mer förökade de sig, och dess mer utbredde de sig, så att man begynte gruva sig för Israels barn.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
Därför pålade egyptierna Israels barn ytterligare tvångsarbeten
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
och förbittrade deras liv med hårt arbete på murbruk och tegel och med alla slags arbeten på marken korteligen, med tvångsarbeten av alla slag, som de läto dem utföra
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
Och konungen i Egypten talade till de hebreiska kvinnor -- den ena hette Sifra, den andra Pua -- som hjälpte barnaföderskorna,
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
han sade: "När I förlösen de hebreiska kvinnorna, så sen efter, då de föda: om det är ett gossebarn, så döden det; är det ett flickebarn, så må det leva."
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
Men hjälpkvinnorna fruktade Gud och gjorde icke såsom konungen i Egypten hade sagt till dem, utan läto barnen leva.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
Då kallade konungen i Egypten hjälpkvinnorna till sig och sade till dem: "Varför gören I så och låten barnen leva?"
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
Hjälpkvinnorna svarade Farao: "De hebreiska kvinnorna äro icke såsom de egyptiska. De äro kraftigare; förrän hjälpkvinnan kommer till dem, hava de fött."
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
Och Gud lät det gå väl för hjälpkvinnorna; och folket förökade sig och blev mycket talrikt.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
Eftersom hjälpkvinnorna fruktade Gud, lät han deras hus förkovras.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Då bjöd Farao allt sitt folk och sade: "Alla nyfödda gossebarn- skolen I kasta i Nilfloden, men all flickebarn mån I låta leva."

< Exodus 1 >