< Exodus 1 >
1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
És ezek a nevei Izrael fiainak, akik Egyiptomba jöttek; Jákobbal, kiki az ő házával, jöttek ők.
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Rúben, Simon, Lévi és Júda;
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Isszáchár, Zebúlun és Benjámin;
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dán, Náftáli, Gád és Ásér.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
És volt összes lélekszáma a Jákob ágyékából származóknak: hetven lélek; József pedig Egyiptomban volt.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
És meghalt József, meg mind a testvérei és az az egész nemzedék.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
Izrael fiai pedig szaporodtak és nyüzsögtek, megsokasodtak és elhatalmasodtak igen nagyon, és megtelt az ország velük.
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
És új király támadt Egyiptom fölött, aki nem ismerte Józsefet.
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
és mondta az ő népének: Íme, Izrael fiainak népe több és hatalmasabb nálunknál.
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
Nosza, legyünk okosak vele szemben, hogy el ne sokasodjék, mert lesz, ha háború támadna, ő is csatlakoznék ellenségeinkhez, harcolna ellenünk és felmenne az országból.
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
És rendeltek feléje robotfelügyelőket, hogy sanyargassák őt rabmunkáikkal; és épített (Izrael) eleséggyűjtő városokat Fáraónak: Pítómot és Raámszészt.
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
De amint sanyargatták őt, úgy sokasodott és terjeszkedett; úgy, hogy irtóztak Izrael fiaitól.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
És az egyiptomiak dolgoztattak Izrael fiaival szigorúsággal.
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
Megkeserítették az életüket kemény munkával agyagkeveréssel és téglavetéssel és minden munkával a mezőn; minden munkájukat, amelyet velük dolgoztattak, szigorúsággal (végeztették).
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
És mondta Egyiptom királya a héber szülésznőknek, akik közül az egyiknek neve Sifró és a másiknak neve Púó,
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
és mondta: Midőn szülésnél segédkeztek a héber nőknek, tekintsetek a szülőszékre: ha fiú az, öljétek meg őt, ha pedig leány, maradjon életben.
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
De a szülésznők félték Istent és nem tettek úgy, amint szólt hozzájuk Egyiptom királya, és életben hagyták a fiúgyermekeket.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
És hivatta Egyiptom királya a szülésznőket és mondta nekik: Miért tettétek ezt a dolgot, hogy életben hagytátok a fiúgyermekeket?
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
És mondták a szülésznők Fáraónak: Mert nem olyanok a héber nők, mint az egyiptomi nők, hanem életrevalók; mielőtt jön hozzájuk a szülésznő, már szültek.
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
És jót tett Isten a szülésznőkkel; a nép pedig sokasodott és nagyon elhatalmasodott.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
És volt, minthogy félték a szülésznők Istent, szerzett nekik házakat.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Fáraó pedig megparancsolta egész népének, mondván: Minden fiút, aki születik, a folyamba vessetek és minden leányt hagyjátok életben.