< Esther 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kejìlá, oṣù Addari, tí ó yẹ kí a mú àṣẹ tí ọba pa wá sí ìmúṣẹ. Ní ọjọ́ yìí ni ọ̀tá àwọn Júù rò pé àwọn yóò borí i wọn, ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ti yìí padà, àwọn Júù sì na ọwọ́ agbára tó ga lórí àwọn tí ó kórìíra wọn.
Astfel în a douăsprezecea lună, care este luna Adar, în a treisprezecea zi a ei, când porunca împăratului şi hotărârea lui urmau să se ducă la îndeplinire, în ziua când duşmanii iudeilor au sperat să aibă stăpânire asupra lor (dar s-a întâmplat dimpotrivă, că iudeii au stăpânit asupra celor care i-au urât),
2 Àwọn Júù péjọ ní àwọn ìlú u wọn ní gbogbo agbègbè ọba Ahaswerusi láti kọlu àwọn tó ń wá ìparun wọn. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè dojúkọ wọ́n, nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ìlú tókù ń bẹ̀rù u wọn.
Iudeii s-au adunat în cetăţile lor, în toate provinciile împăratului Ahaşveroş, ca să pună mâna pe cei care căutau vătămarea lor. Şi nimeni nu le putea sta împotrivă, fiindcă teama de ei a căzut asupra tuturor.
3 Gbogbo àwọn ọlọ́lá ìgbèríko, àwọn alákòóso, àwọn baálẹ̀ àti àwọn onídàájọ́ ọba ran àwọn Júù lọ́wọ́, nítorí wọ́n bẹ̀rù u Mordekai.
Şi toţi conducătorii provinciilor şi locotenenţii şi prefecţii şi ofiţerii împăratului, au ajutat pe iudei, pentru că teama de Mardoheu a căzut asupra lor.
4 Mordekai sì jẹ́ ẹni pàtàkì ní ààfin ọba, òkìkí rẹ̀ sì tàn jákèjádò àwọn ìgbèríko, ó sì ní agbára kún agbára.
Fiindcă Mardoheu era mare în casa împăratului, şi faima lui s-a răspândit în toate provinciile, pentru că acest Mardoheu a devenit din ce în ce mai mare.
5 Àwọn Júù sì gé gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n pa wọ́n, wọ́n sì run wọ́n, wọ́n sì ṣe ohun tí ó wù wọ́n sí àwọn tí ó kórìíra wọn.
Astfel iudeii au lovit pe toţi duşmanii lor cu lovitură de sabie, şi măcel şi distrugere şi au făcut ce au dorit celor ce i-au urât.
6 Ní ilé ìṣọ́ ti Susa, àwọn Júù pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọkùnrin run.
Şi în palatul Susa, iudeii au ucis şi au nimicit cinci sute de bărbaţi.
7 Wọ́n sì tún pa Parṣandata, Dalfoni, Aspata,
Şi au ucis pe Parşandata şi pe Dalfon şi pe Aspata,
8 Porata, Adalia, Aridata,
Şi pe Porata şi pe Adalia şi pe Aridata,
9 Parmaṣta, Arisai, Aridai àti Faisata.
Şi pe Parmaşta şi pe Arisai şi pe Aridai şi pe Vajezata,
10 Àwọn ọmọkùnrin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí wọ́n jẹ́ ọmọ Hamani, ọmọ Hammedata, ọ̀tá àwọn Júù. Ṣùgbọ́n wọn kò fi ọwọ́ wọn lé ìkógun un wọn.
Cei zece fii ai lui Haman, fiul lui Hamedata, duşmanul iudeilor, dar nu şi-au pus mâna pe pradă.
11 Ní ọjọ́ náà gan an ni a mú iye àwọn tí a pa ní ilé ìṣọ́ ti Susa wá fún ọba.
În acea zi numărul celor ucişi în palatul Susa a fost adus înaintea împăratului.
12 Ọba sì sọ fún Esteri ayaba pé, “Àwọn Júù ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí i ṣe ọmọ Hamani ní ilé ìṣọ́ Susa run. Kí ni wọ́n ṣe ní gbogbo ìgbèríko ọba tókù? Báyìí kí ni ẹ̀bẹ̀ rẹ? A ó fi fún ọ. Kí ni ìbéèrè rẹ? A ó sì tún fi fún ọ.”
Şi împăratul a spus împărătesei Estera: Iudeii au ucis şi au nimicit cinci sute de bărbaţi în palatul Susa şi pe cei zece fii ai lui Haman. Ce au făcut în celelalte provincii ale împăratului? Acum care este rugămintea ta? Spune şi îţi va fi împlinită. Şi care este cererea ta mai departe? Şi se va face.
13 Esteri sì dáhùn pé, “Bí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, fún àwọn Júù tí ó wà ní Susa ní àṣẹ láti ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní òní kí wọn ṣe bákan náà ní ọ̀la, kí a sì so àwọn ọmọkùnrin Hamani mẹ́wẹ̀ẹ̀wá náà rọ̀ sórí igi.”
Atunci Estera a spus: Dacă face plăcere împăratului, să fie dat iudeilor care sunt în Susa să facă şi mâine conform hotărârii de astăzi şi să spânzure de spânzurătoare pe cei zece fii ai lui Haman.
14 Nítorí náà ọba pàṣẹ pé kí a ṣe bẹ́ẹ̀. A sì gbé àṣẹ kan jáde ní Susa, wọ́n sì so àwọn ọmọkùnrin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá Hamani kọ́.
Şi împăratul a poruncit să se facă astfel. Şi hotărârea s-a dat în Susa. Şi au spânzurat pe cei zece fii ai lui Haman.
15 Àwọn Júù tí ó wà ní Susa sì péjọ ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù Addari, wọ́n sì pa ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ní Susa, ṣùgbọ́n wọn kò fi ọwọ́ wọn lé ìkógun un wọn.
Căci iudeii care erau în Susa s-au adunat şi în ziua a paisprezecea a lunii Adar şi au ucis trei sute de bărbaţi în Susa; dar nu şi-au pus mâna pe pradă.
16 Lákokò yìí, àwọn tókù nínú àwọn Júù tí wọ́n wà ní agbègbè ọba náà tún kó ara wọn jọ láti dáàbò bo ara wọn kí wọn sì sinmi lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a wọn. Wọ́n sì pa ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀rin àwọn tí ó kórìíra wọn ṣùgbọ́n wọn kò fi ọwọ́ wọn lé ìkógun un wọn.
Şi ceilalţi iudei care erau în provinciile împăratului s-au adunat şi şi-au apărat viaţa şi au avut odihnă din partea duşmanilor lor şi au ucis şaptezeci şi cinci de mii dintre duşmanii lor, dar nu şi-au pus mâna pe pradă,
17 Èyí ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù Addari, wọ́n sì sinmi ní ọjọ́ kẹrìnlá, wọ́n sì ṣe ọjọ́ náà ní ọjọ́ àsè àti ayọ̀.
În ziua a treisprezecea a lunii Adar; şi în a paisprezecea zi a ei s-au odihnit şi au făcut-o zi de ospăţ şi veselie.
18 Àwọn Júù tí ó wà ní Susa, kó ara wọn jọ ní ọjọ́ kẹtàlá àti ọjọ́ kẹrìnlá, nígbà tí ó sì di ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún wọ́n sinmi wọ́n sì ṣe ọjọ́ náà ní ọjọ́ àsè àti ayọ̀.
Dar iudeii care erau în Susa s-au adunat în a treisprezecea zi a lunii şi în a paisprezecea zi a ei; şi în a cincisprezecea zi a ei s-au odihnit şi au făcut-o zi de ospăţ şi veselie.
19 Nítorí náà ni àwọn Júù tí wọ́n ń gbé ní ìletò ṣe pa ọjọ́ kẹrìnlá oṣù Addari mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ ayọ̀ àti ọjọ́ àsè, ọjọ́ tí wọ́n ń fún ara wọn ní ẹ̀bùn.
De aceea iudeii din sate, care au locuit în aşezări neîmprejmuite, au făcut din ziua a paisprezecea a lunii Adar o zi de veselie şi de ospăţ şi zi bună şi de trimitere de porţii de mâncare unii altora.
20 Mordekai ṣe àkọsílẹ̀ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí, ó sì kọ ìwé ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn Júù jákèjádò àgbáyé ọba Ahaswerusi, tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó wà ní jìnnà réré,
Şi Mardoheu a scris aceste lucruri şi a trimis scrisori la toţi iudeii care erau în toate provinciile împăratului Ahaşveroş, deopotrivă celor de aproape şi de departe,
21 láti lè máa ṣe àjọyọ̀ ní ọjọ́ kẹrìnlá àti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù Addari ní ọdọọdún.
Pentru a stabili printre ei să ţină ziua a paisprezecea a lunii Adar şi ziua a cincisprezecea a ei, anual,
22 gẹ́gẹ́ bí àkókò tí àwọn Júù gba ìsinmi kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a wọn, àti bí oṣù tí ìbànújẹ́ ẹ wọn yí padà di ayọ̀ àti tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ wọn di ọjọ́ àjọyọ̀. Ó kọ ọ́ sí wọn láti máa pa ọjọ́ náà mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àsè àti ọjọ́ ayọ̀ kí wọn sì máa fi oúnjẹ fún ara wọn, kí wọn sì máa fi ẹ̀bùn fún àwọn aláìní.
Ca zilele în care iudeii s-au odihnit din partea duşmanilor lor şi luna în care li s-a prefăcut întristarea lor în bucurie şi jelirea lor într-o zi bună; ca să le facă zile de ospăţ şi bucurie şi de trimitere de porţii de mâncare unii altora şi de daruri celor săraci.
23 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Júù gbà láti máa ṣe àjọyọ̀ tí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀, wọ́n ń ṣe bí Mordekai ti kọ̀wé sí wọn.
Şi iudeii au acceptat să facă ceea ce au început, şi ceea ce le-a scris Mardoheu.
24 Nítorí Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, ọ̀tá gbogbo àwọn Júù, ti gbèrò sí àwọn Júù láti pa wọ́n run, ó sì ti di puri (èyí tí í ṣe ìbò) fún ìsọdahoro àti ìparun wọn.
Pentru că Haman, fiul lui Hamedata agaghitul, duşmanul tuturor iudeilor, a plănuit împotriva iudeilor ca să îi nimicească şi a aruncat Pur, adică, sorţul, pentru a-i mistui şi pentru a-i nimici.
25 Ṣùgbọ́n nígbà tí Esteri sọ nípa ìṣọ̀tẹ̀ náà fún ọba, ó kọ̀wé àṣẹ kan jáde pé kí ète búburú tí Hamani ti pa sí àwọn Júù kí ó padà sí orí òun fúnra rẹ̀, àti pé kí a gbé òun àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ kọ́ sórí igi.
Dar când Estera a venit înaintea împăratului, el a poruncit prin scrisori ca planul lui rău, pe care l-a plănuit împotriva iudeilor, să se întoarcă asupra capului său, şi el şi fiii lui să fie spânzuraţi pe spânzurătoare;
26 (Nítorí náà a pe àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ní Purimu, láti ara ọ̀rọ̀ puri). Nítorí ohun gbogbo tí a kọ sínú ìwé yìí àti nítorí ohun tí wọ́n ti rí àti ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn,
De aceea au numit aceste zile Purim, după numele Pur. De aceea, datorită tuturor cuvintelor scrisorii acesteia, şi a ceea ce au văzut în acest lucru, şi pentru ceea ce li s-a întâmplat,
27 àwọn Júù fi lélẹ̀, wọ́n sì gbà á gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún ara wọn àti fún irú àwọn ọmọ wọn àti gbogbo àwọn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn, kò sì ní kúrò, wọn yóò sì máa pa àwọn ọjọ́ méjèèjì yìí mọ́ ní gbogbo ọdún, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ àti àkókò tí a yàn.
Iudeii au rânduit şi au luat asupra lor, şi asupra seminţei lor, şi asupra tuturor celor ce li s-au alipit, să nu neglijeze să ţină aceste două zile conform scrierii lor şi conform timpului lor hotărât, în fiecare an;
28 A gbọdọ̀ máa ṣe ìrántí àwọn ọjọ́ wọ̀nyí kí a sì máa pa wọ́n mọ́ ní ìrandíran ní gbogbo ìdílé, àti ní gbogbo ìgbèríko àti ní gbogbo ìlú. A gbọdọ̀ máa ṣe àwọn ọjọ́ Purimu wọ̀nyí ní àárín àwọn Júù, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ di ohun ìgbàgbé láàrín irú àwọn ọmọ wọn.
Şi că aceste zile să fie amintite şi ţinute din generaţie în generaţie, în fiecare familie, în fiecare provincie şi în fiecare cetate. Şi că aceste zile ale Purimului să nu lipsească din mijlocul iudeilor, nici să nu se şteargă amintirea lor din sămânţa lor.
29 Bẹ́ẹ̀ ni Esteri ayaba, ọmọbìnrin Abihaili, pẹ̀lú Mordekai ará a Júù, kọ̀wé pẹ̀lú àṣẹ láti fi ìdí ìwé kejì nípa Purimu yìí múlẹ̀.
Atunci împărăteasa Estera, fiica lui Abihail şi Mardoheu iudeul, au scris cu toată autoritatea, pentru a confirma această a doua scrisoare a Purimului.
30 Mordekai sì kọ ìwé ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn Júù, sí ìgbèríko mẹ́tàdínláàádóje ní ilẹ̀ ọba Ahaswerusi ní ọ̀rọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
Iar el a trimis scrisorile tuturor iudeilor, şi celor o sută douăzeci şi şapte de provincii ale împărăţiei lui Ahaşveroş, cu aceste cuvinte de pace şi adevăr,
31 Láti fi ìdí àwọn ọjọ́ ọ Purimu yìí múlẹ̀ ní àkókò tí wọ́n yàn, gẹ́gẹ́ bí Mordekai ará Juda, àti Esteri ayaba ti pa á láṣẹ fún wọn, àti bí wọ́n ṣe fi lélẹ̀ fún ara wọn àti irú àwọn ọmọ wọn ní ìbámu pẹ̀lú àkókò àwẹ̀ àti ẹkún wọn.
Pentru a confirma aceste zile ale Purimului la timpul lor hotărât, după cum le-a poruncit Mardoheu iudeul şi împărăteasa Estera, şi după cum au hotărât pentru ei şi pentru sămânţa lor, lucrurile posturilor şi a strigătului lor.
32 Àṣẹ Esteri sì fi ìdí ìlànà Purimu wọ̀nyí múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé àkọsílẹ̀.
Şi hotărârea Esterei a confirmat aceste lucruri despre Purim şi a fost scris în carte.

< Esther 9 >