< Esther 8 >

1 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba Ahaswerusi fún Esteri ayaba ní ilé e Hamani, ọ̀tá àwọn Júù. Mordekai sì wá síwájú ọba, nítorí Esteri ti sọ bí ó ṣe jẹ́ sí ọba.
Onegoż dnia dał król Aswerus Esterze królowej dom Hamana, nieprzyjaciela żydowskiego; a Mardocheusz przyszedł przed króla; bo mu była oznajmiła Ester, że był jej pokrewnym.
2 Ọba sì bọ́ òrùka dídán an rẹ̀, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ Hamani ó sì fi fún Mordekai, Esteri sì yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí ilé e Hamani.
Tedy zdjął król pierścień swój, który był wziął od Hamana, i dał go Mardocheuszowi, a Ester postanowiła Mardocheusza nad domem Hamanowym.
3 Esteri sì tún bẹ ọba lórí ìkúnlẹ̀, pẹ̀lú omijé lójú. Ó bẹ̀ ẹ́ kí ó fi òpin sí ètò búburú Hamani ará Agagi, èyí tí ó ti pète fún àwọn Júù.
Potem jeszcze Ester mówiła do króla, upadłszy u nóg jego, i płakała, i prosiła go, aby wniwecz obrócił złość Hamana Agagiejczyka, i zamysł jego, który był wymyślił przeciwko Żydom.
4 Nígbà náà ni ọba na ọ̀pá aládé wúrà sí Esteri ó sì dìde, ó dúró níwájú rẹ̀.
Tedy wyciągnął król na Esterę sceptr złoty, a Estera wstawszy stenęła przed królem.
5 Ó wí pé, “Bí ó bá wu ọba, tí ó bá sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ojúrere tí ó sì rò pé ohun tí ó dára ni láti ṣe, tí ó bá sì ní inú dídùn pẹ̀lú mi, jẹ́ kí a kọ ìwé àṣẹ láti yí ète tí Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, tí ó kọ́ pàṣẹ pé kí a pa àwọn Júù tí wọ́n wà ní gbogbo àgbáyé ìjọba ọba run.
I rzekła: Jeźli się królowi podoba, a jeźlim znalazła łaskę przed obliczem jego, i jeźli się to za słuszne zda być królowi, i jeźlim ja przyjemna w oczach jego, niech napiszą, aby były odwołane listy zamysłów Hamana, syna Hamedata Agagiejczyka, które rozpisał na wytracenie Żydów, którzy są po wszystkich krainach królewskich.
6 Nítorí báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á tí èmi yóò sì rí kí ibi máa ṣubú lu àwọn ènìyàn mi? Báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á, tí èmi yóò sì máa wo ìparun àwọn ìdílé mi?”
Albowiem jakożbym mogła patrzeć na to złe, któreby przyszło na lud mój? albo jakobym mogła widzieć zginienie rodziny mojej?
7 Ọba Ahaswerusi dá Esteri ayaba àti Mordekai ará a Júù náà lóhùn pé, “Nítorí Hamani kọlu àwọn ará a Júù, èmi ti fi ilé e rẹ̀ fún Esteri, wọ́n sì ti ṣo ó kọ́ sórí igi.
I rzekł król Aswerus do Estery królowej, i do Mardocheusza Żyda: Otom dom Hamanowy dał Esterze, a onego powieszono na szubienicy, przeto, iż ściągnął rękę swoję na Żydów.
8 Nísinsin yìí, kọ ìwé àṣẹ mìíràn ní orúkọ ọba bí àwọn Júù ṣe jẹ́ pàtàkì sí ọ, kí o sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì dì í, nítorí kò sí àkọsílẹ̀ tí a bá ti kọ ní orúkọ ọba tí a sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì tí a lè yìí padà.”
Wy tedy piszcie do Żydów, jako się wam podoba, imieniem królewskiem, i zapieczętujcie pierścieniem królewskim; albowiem to, co się pisze imieniem królewskiem, i pieczętuje się pierścieniem królewskim, nie może być odwołane.
9 Lẹ́sẹ̀kan náà àwọn akọ̀wé ọba péjọ ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kẹta, oṣù Sifani. Wọ́n kọ gbogbo àṣẹ Mordekai sí àwọn Júù, àti sí àwọn alákòóso baálẹ̀ àti àwọn ọlọ́lá ìgbèríko mẹ́tàdínláàádóje tí ó lọ láti India títí ó fi dé Kuṣi. Kí a kọ àṣẹ náà ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé àti bí èdè olúkúlùkù àti pẹ̀lú sí àwọn Júù ní ìlànà bí wọ́n ṣe ń kọ̀wé àti èdè e wọn.
A tak zwołano pisarzy królewskich onego czasu, miesiąca trzeciego, (ten jest miesiąc Sywan) dwudziestego i trzeciego dnia tegoż miesiąca, a pisano wszystko, jako rozkazał Mardocheusz, do Żydów i do książąt, i do starostów, i do przełożonych nad krain a mi, którzy są od Indyi aż do Murzyńskiej ziemi nad stem dwudziestą i siedmią krain, do każdej krainy pismem jej, i do każdego narodu językiem jego, i do Żydów pismen ich i językiem ich.
10 Mordekai sì fi àṣẹ ọba Ahaswerusi kọ̀wé, ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀, ó rán an lọ ní kíákíá, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ ayaba, tiwọn yára bí àṣà àwọn tí wọ́n ń gun ẹṣin tí ó yára, ní pàtàkì èyí tí a ń bọ́ fún ọba.
A gdy napisał imieniem króla Aswerusa, i zapieczętował pierścieniem królewskim, rozesłał listy przez posłów, którzy jeżdżali na koniach prędkich, i na mułach młodych:
11 Àṣẹ ọba sì dé ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní gbogbo ìlú láti kó ara wọn jọ kí wọn sì dáàbò bo ara wọn; láti pa, láti run àti láti kọlu ogunkógun orílẹ̀-èdè kórílẹ̀ èdè kankan tàbí ìgbèríko tí ó bá fẹ́ kọlù wọ́n, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn; kí ẹ sì kó gbogbo ohun ìní àwọn ọ̀tá wọn.
Iż król dał wolność Żydom, którzy byli we wszystkich miastach, aby się zgromadzili, a zastawiali się o duszę swoję, a żeby wytracili, wymordowali, i wygubili wszystkie wojska ludu onego, i krain tych, którzyby im gwałt czynili, dziatkom ich, i żon om ich, a łupy ich żeby rozchwycili;
12 Ọjọ́ tí a yàn fún àwọn Júù ní gbogbo agbègbè ọba Ahaswerusi láti ṣe nǹkan yìí ni ọjọ́ kẹtàlá èyí tí í ṣe oṣù kejìlá, oṣù Addari.
A to jednego dnia po wszystkich krainach króla Aswerusa, to jest trzynastego dnia, miesiąca dwunastego, ten jest miesiąc Adar.
13 Ọkàn ìwé àṣẹ náà ni kí a gbé jáde gẹ́gẹ́ bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ẹ sì jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún gbogbo ènìyàn ìlú nítorí àwọn Júù yóò le è múra ní ọjọ́ náà láti gbẹ̀san fún ara wọn lára àwọn ọ̀tá wọn.
Suma tych listów była: Żeby wydano wyrok w każdej krainie, i oznajmiono wszystkim narodom, aby byli Żydzi gotowi na on dzień ku pomście nad nieprzyjaciołmi swymi.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ ayaba tiwọn yára bí àṣà tí wọ́n ń gun ẹṣin ọba, sáré jáde, wọ́n sáré lọ nípa àṣẹ ọba. A sì tún gbé àṣẹ náà jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa.
Tedy posłowie, którzy jeżdżali na koniach prędkich i na mułach, bieżeli jak najprędzej z rozkazaniem królewskiem, a przybity był ten wyrok w Susan na pałacu królewskim.
15 Mordekai sì kúrò níwájú ọba, ó wọ aṣọ aláró àti funfun, ó dé adé e wúrà ńlá pẹ̀lú ìgbànú elése àlùkò dáradára, ìlú Susa sì ṣe àjọyọ̀ ńlá.
A Mardocheusz wyszedł od króla w szacie królewskiej hijacyntowej i białej, i w wielkiej koronie złotej, i w płaszczu bisiorowem, i szarłatnym; a miasto Susan weseliło i radowało się.
16 Àsìkò ìdùnnú àti ayọ̀, inú dídùn àti ọlá ni ó jẹ́ fún àwọn Júù.
A Żydom weszła światłość i wesele, i radość i cześć.
17 Ní gbogbo ìgbèríko àti ní gbogbo ìlú, ní gbogbo ibi tí àṣẹ ọba dé, ni ayọ̀ àti inú dídùn ti wà láàrín àwọn Júù, wọ́n sì ń ṣe àsè àti àjọyọ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tókù sọ ara wọn di Júù nítorí ẹ̀rù àwọn Júù bà wọ́n.
Także w każdej krainie, i w każdem mieście, i na wszelkiem miejscu, gdziekolwiek rozkaz królewski, i wyrok jego doszedł, mieli Żydzi wesele, radość, uczty, i dzień ucieszny; a wiele z narodów onych krain zostawali Żydami; albowiem strach był przypadł od Żydów na nie.

< Esther 8 >